سورة القيامة

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة القيامة باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú Ọjọ́ Àjíǹde.
آية رقم 2
Mo tún ń búra pẹ̀lú ẹ̀mí t’ó máa dára rẹ̀ lẹ́bi.
آية رقم 3
Ṣé ènìyàn lérò pé A ò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
آية رقم 5
Ṣùgbọ́n ènìyàn gbèrò láti pe (Ọjọ́ Àjíǹde) t’ó ń bẹ níwájú rẹ̀ nírọ́.
آية رقم 6
Ó ń bèèrè pé: "Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?"
آية رقم 7
Nígbà tí ojú bá kọ mọ̀nà,
آية رقم 8
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
آية رقم 9
àti (nígbà) tí A bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn,
آية رقم 10
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: "Níbo ni ibùsásí wà?"
آية رقم 12
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 13
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun t’ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun t’ó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
آية رقم 15
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
آية رقم 17
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
آية رقم 18
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
آية رقم 19
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
آية رقم 20
Ẹ gbọ́! Ńṣe l’ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé.
آية رقم 21
Ẹ sì ń pa ọ̀run tì.
آية رقم 22
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
آية رقم 23
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
آية رقم 24
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
آية رقم 25
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé Wọ́n máa fi aburú kan òhun.
آية رقم 26
Ẹ gbọ́! Nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
آية رقم 27
A sì máa sọ pé: "Ǹjẹ́ ọlọ́fọ̀ pípè kan wà bí (tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
آية رقم 28
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
آية رقم 29
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
آية رقم 30
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 31
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
آية رقم 32
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo nírọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
آية رقم 33
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
آية رقم 34
Ègbé ni fún ọ, ègbé ni sẹ́.
آية رقم 35
Lẹ́yìn náà, ègbé ni fún ọ, ègbé sì sẹ́.
آية رقم 36
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
آية رقم 37
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
آية رقم 38
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é t’ó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
آية رقم 39
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti inú rẹ̀, akọ àti abo.
آية رقم 40
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
تقدم القراءة