ترجمة معاني سورة القيامة باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú Ọjọ́ Àjíǹde.
آية رقم 2
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Mo tún ń búra pẹ̀lú ẹ̀mí t’ó máa dára rẹ̀ lẹ́bi.
آية رقم 3
ﮔﮕﮖﮗﮘ
ﮙ
Ṣé ènìyàn lérò pé A ò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
آية رقم 4
ﮚﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
Rárá o. A lágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
آية رقم 5
ﮡﮢﮣﮤﮥ
ﮦ
Ṣùgbọ́n ènìyàn gbèrò láti pe (Ọjọ́ Àjíǹde) t’ó ń bẹ níwájú rẹ̀ nírọ́.
آية رقم 6
ﮧﮨﮩﮪ
ﮫ
Ó ń bèèrè pé: "Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?"
آية رقم 7
ﮬﮭﮮ
ﮯ
Nígbà tí ojú bá kọ mọ̀nà,
آية رقم 8
ﮰﮱ
ﯓ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
آية رقم 9
ﯔﯕﯖ
ﯗ
àti (nígbà) tí A bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn,
آية رقم 10
ﯘﯙﯚﯛﯜ
ﯝ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: "Níbo ni ibùsásí wà?"
آية رقم 11
ﯞﯟﯠ
ﯡ
Rárá, kò sí ibùsásí.
آية رقم 12
ﯢﯣﯤﯥ
ﯦ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 13
ﯧﯨﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun t’ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun t’ó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
آية رقم 14
ﯮﯯﯰﯱﯲ
ﯳ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
آية رقم 15
ﯴﯵﯶ
ﯷ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
آية رقم 16
ﯸﯹﯺﯻﯼﯽ
ﯾ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
آية رقم 17
ﯿﰀﰁﰂ
ﰃ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
آية رقم 18
ﰄﰅﰆﰇ
ﰈ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
آية رقم 19
ﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
آية رقم 20
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Ẹ gbọ́! Ńṣe l’ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé.
آية رقم 21
ﭖﭗ
ﭘ
Ẹ sì ń pa ọ̀run tì.
آية رقم 22
ﭙﭚﭛ
ﭜ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
آية رقم 23
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
آية رقم 24
ﭡﭢﭣ
ﭤ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
آية رقم 25
ﭥﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé Wọ́n máa fi aburú kan òhun.
آية رقم 26
ﭫﭬﭭﭮ
ﭯ
Ẹ gbọ́! Nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
آية رقم 27
ﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
A sì máa sọ pé: "Ǹjẹ́ ọlọ́fọ̀ pípè kan wà bí (tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
آية رقم 28
ﭵﭶﭷ
ﭸ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
آية رقم 29
ﭹﭺﭻ
ﭼ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
آية رقم 30
ﭽﭾﭿﮀ
ﮁ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 31
ﮂﮃﮄﮅ
ﮆ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
آية رقم 32
ﮇﮈﮉ
ﮊ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo nírọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
آية رقم 33
ﮋﮌﮍﮎﮏ
ﮐ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
آية رقم 34
ﮑﮒﮓ
ﮔ
Ègbé ni fún ọ, ègbé ni sẹ́.
آية رقم 35
ﮕﮖﮗﮘ
ﮙ
Lẹ́yìn náà, ègbé ni fún ọ, ègbé sì sẹ́.
آية رقم 36
ﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
آية رقم 37
ﮠﮡﮢﮣﮤﮥ
ﮦ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
آية رقم 38
ﮧﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é t’ó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
آية رقم 39
ﮭﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti inú rẹ̀, akọ àti abo.
آية رقم 40
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
تقدم القراءة