ترجمة معاني سورة المرسلات باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮑﮒ
ﮓ
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé.
آية رقم 2
ﮔﮕ
ﮖ
Ó búra pẹ̀lú àwọn ìjì atẹ́gùn t’ó ń jà.
آية رقم 3
ﮗﮘ
ﮙ
Ó búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń tú èṣújò ká.
آية رقم 4
ﮚﮛ
ﮜ
Ó búra pẹ̀lú àwọn t’ó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́.
آية رقم 5
ﮝﮞ
ﮟ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́).
آية رقم 6
ﮠﮡﮢ
ﮣ
(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.
آية رقم 7
ﮤﮥﮦ
ﮧ
Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fun yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.
آية رقم 8
ﮨﮩﮪ
ﮫ
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,
آية رقم 9
ﮬﮭﮮ
ﮯ
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,
آية رقم 10
ﮰﮱﯓ
ﯔ
àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,
آية رقم 11
ﯕﯖﯗ
ﯘ
àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ, (Àkókò náà ti dé nìyẹn).
آية رقم 12
ﯙﯚﯛ
ﯜ
Ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?
آية رقم 13
ﯝﯞ
ﯟ
Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.
آية رقم 14
ﯠﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?
آية رقم 15
ﯦﯧﯨ
ﯩ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 16
ﯪﯫﯬ
ﯭ
Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?
آية رقم 17
ﯮﯯﯰ
ﯱ
Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).
آية رقم 18
ﯲﯳﯴ
ﯵ
Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 19
ﯶﯷﯸ
ﯹ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 20
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Ṣé A ò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?
آية رقم 21
ﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)
آية رقم 22
ﭜﭝﭞ
ﭟ
títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).
آية رقم 23
ﭠﭡﭢ
ﭣ
A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀). (Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá t’ó dára.
آية رقم 24
ﭤﭥﭦ
ﭧ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 25
ﭨﭩﭪﭫ
ﭬ
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun t’ó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;
آية رقم 26
ﭭﭮ
ﭯ
(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?
آية رقم 27
A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fun yín ní omi dídùn mu.
آية رقم 28
ﭸﭹﭺ
ﭻ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 29
ﭼﭽﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Ẹ máa lọ sí ibi tí ẹ̀ ń pè nírọ́.
آية رقم 30
ﮃﮄﮅﮆﮇﮈ
ﮉ
Ẹ máa lọ sí ibi èéfín ẹlẹ́ka mẹ́ta.
آية رقم 31
ﮊﮋﮌﮍﮎﮏ
ﮐ
Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.
آية رقم 32
ﮑﮒﮓﮔ
ﮕ
Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè t’ó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.
آية رقم 33
ﮖﮗﮘ
ﮙ
(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.
آية رقم 34
ﮚﮛﮜ
ﮝ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 35
ﮞﮟﮠﮡ
ﮢ
Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.
آية رقم 36
ﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
A ò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.
آية رقم 37
ﮨﮩﮪ
ﮫ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 38
ﮬﮭﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.
آية رقم 39
ﯔﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
Tí ẹ bá ní ète kan lọ́wọ́, ẹ déte sí Mi wò.
آية رقم 40
ﯚﯛﯜ
ﯝ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 41
ﯞﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,
آية رقم 42
ﯤﯥﯦ
ﯧ
àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.
آية رقم 43
ﯨﯩﯪﯫﯬﯭ
ﯮ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
آية رقم 44
ﯯﯰﯱﯲ
ﯳ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
آية رقم 45
ﯴﯵﯶ
ﯷ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 46
ﯸﯹﯺﯻﯼ
ﯽ
Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.
آية رقم 47
ﯾﯿﰀ
ﰁ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 48
ﰂﰃﰄﰅﰆﰇ
ﰈ
Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.
آية رقم 49
ﰉﰊﰋ
ﰌ
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 50
ﰍﰎﰏﰐ
ﰑ
Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:185.
تقدم القراءة