ترجمة معاني سورة العلق باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮕﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.
آية رقم 2
ﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.
آية رقم 3
ﮠﮡﮢ
ﮣ
Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.
آية رقم 4
ﮤﮥﮦ
ﮧ
Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.
آية رقم 5
ﮨﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Ó fi ìmọ̀ tí ènìyàn kò mọ̀ mọ̀ ọ́n.
آية رقم 6
ﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-àlà
آية رقم 7
ﯔﯕﯖ
ﯗ
nítorí pé ó ríra rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.
آية رقم 8
ﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.
آية رقم 9
ﯝﯞﯟ
ﯠ
Sọ fún mi nípa ẹni t’ó ń kọ̀
آية رقم 10
ﯡﯢﯣ
ﯤ
fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!
آية رقم 11
ﯥﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)
آية رقم 12
ﯫﯬﯭ
ﯮ
tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!
آية رقم 13
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?
آية رقم 14
ﭖﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)
آية رقم 15
ﭜﭝﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Bẹ́ẹ̀ ni (Allāhu ń rí i.) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí i lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);
آية رقم 16
ﭣﭤﭥ
ﭦ
àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 17
ﭧﭨ
ﭩ
Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.
آية رقم 18
ﭪﭫ
ﭬ
Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.
آية رقم 19
ﭭﭮﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
Rárá o, má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o súnmọ́ (Allāhu).
تقدم القراءة