سورة المرسلات

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة المرسلات باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé.
آية رقم 2
Ó búra pẹ̀lú àwọn ìjì atẹ́gùn t’ó ń jà.
آية رقم 3
Ó búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń tú èṣújò ká.
آية رقم 4
Ó búra pẹ̀lú àwọn t’ó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́.
آية رقم 5
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́).
آية رقم 6
(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.
آية رقم 7
Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fun yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.
آية رقم 8
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,
آية رقم 9
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,
آية رقم 10
àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,
آية رقم 11
àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ, (Àkókò náà ti dé nìyẹn).
آية رقم 12
Ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?
آية رقم 13
Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.
آية رقم 14
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?
آية رقم 15
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 16
Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?
آية رقم 17
Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).
آية رقم 18
Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 19
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 20
Ṣé A ò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?
آية رقم 21
Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)
آية رقم 22
títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).
آية رقم 23
A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀). (Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá t’ó dára.
آية رقم 24
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 25
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun t’ó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;
آية رقم 26
(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?
آية رقم 27
A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fun yín ní omi dídùn mu.
آية رقم 28
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 31
Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.
آية رقم 32
Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè t’ó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.
آية رقم 33
(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.
آية رقم 34
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 35
Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.
آية رقم 36
A ò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.
آية رقم 37
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 38
Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.
آية رقم 39
Tí ẹ bá ní ète kan lọ́wọ́, ẹ déte sí Mi wò.
آية رقم 40
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 41
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,
آية رقم 42
àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.
آية رقم 43
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
آية رقم 44
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
آية رقم 45
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 46
Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.
آية رقم 47
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 48
Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.
آية رقم 49
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
آية رقم 50
Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:185.
تقدم القراءة