سورة التكوير

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة التكوير باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Nígbà tí Wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,
آية رقم 2
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
آية رقم 3
àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),
آية رقم 4
àti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,
آية رقم 5
àti nígbà tí Wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,
آية رقم 6
àti nígbà tí Wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,
آية رقم 7
àti nígbà tí Wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)
آية رقم 8
àti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé
آية رقم 9
ẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,
آية رقم 10
àti nígbà tí Wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,
آية رقم 11
àti nígbà tí Wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,
آية رقم 12
àti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,
آية رقم 13
àti nígbà tí Wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),
آية رقم 14
(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).
آية رقم 15
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwọn ìràwọ̀ t’ó ń yọ ní alẹ́, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán,
آية رقم 16
(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ t’ó ń rìn lọ rìn bọ̀, t’ó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.
آية رقم 17
Mo tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.
آية رقم 18
Mo tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀.
آية رقم 19
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,
Wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Hāƙƙọh; 69:40.
آية رقم 20
alágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,
آية رقم 21
ẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.
آية رقم 22
Àti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad s.a.w.) kì í ṣe wèrè.
آية رقم 23
Ó kúkú rí i nínú òfurufú kedere.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Najm; 53:13.
آية رقم 24
Àti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).
آية رقم 25
Al-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Èṣù, ẹni ẹ̀kọ̀.
آية رقم 26
Nítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?
آية رقم 27
Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 28
(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.
آية رقم 29
Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
تقدم القراءة