سورة الغاشية

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة الغاشية باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ nípa ohun t’ó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
آية رقم 2
Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 3
Oníṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni wọ́n nílé ayé).
آية رقم 4
Wọ́n máa wọ inú Iná t’ó gbóná janjan (ní ọ̀run).
آية رقم 5
Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi gbígbóná mu.
آية رقم 6
Kò sí oúnjẹ kan fún wọn àyàfi igi ẹlẹ́gùn-ún gbígbẹ.
آية رقم 7
Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.
آية رقم 8
Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn
آية رقم 9
nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.
آية رقم 10
(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
آية رقم 11
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.
آية رقم 12
Omi ìṣẹ́lẹ̀rú t’ó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.
آية رقم 13
Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,
آية رقم 14
àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),
آية رقم 15
àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,
آية رقم 16
àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.
آية رقم 17
Nítorí náà, ṣé wọn kò wo ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;
آية رقم 18
àti sánmọ̀, bí A ti ṣe gbé e sókè;
آية رقم 19
àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);
آية رقم 20
àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ ní gban̄sasa?
آية رقم 21
Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.
آية رقم 22
Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn
آية رقم 23
àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.
آية رقم 24
Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà t’ó tóbi jùlọ.
آية رقم 25
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.
آية رقم 26
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.
تقدم القراءة