ترجمة معاني سورة الفجر باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﭤ
ﭥ
Allāhu búra pẹ̀lú àfẹ̀mọ́júmọ́.
آية رقم 2
ﭦﭧ
ﭨ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn òru mẹ́wàá kan.
آية رقم 3
ﭩﭪ
ﭫ
Ó tún búra pẹ̀lú méjì àti ẹyọ.
آية رقم 4
ﭬﭭﭮ
ﭯ
Ó tún búra pẹ̀lú òru nígbà tí ó bá lọ (tí ó bá dé).
آية رقم 5
ﭰﭱﭲﭳﭴﭵ
ﭶ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
آية رقم 6
ﭷﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
Ṣé o ò rí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
آية رقم 7
ﭾﭿﮀ
ﮁ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
آية رقم 8
ﮂﮃﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
àwọn tí A ò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
آية رقم 9
ﮉﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonífojì,
آية رقم 10
ﮏﮐﮑ
ﮒ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
آية رقم 11
ﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn t’ó tayọ ẹnu-àlà nínú ìlú.
آية رقم 12
ﮘﮙﮚ
ﮛ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
آية رقم 13
ﮜﮝﮞﮟﮠ
ﮡ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
آية رقم 14
ﮢﮣﮤ
ﮥ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
آية رقم 15
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti pọ́n mi lé."
آية رقم 16
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi."
آية رقم 17
ﯞﯟﯠﯡﯢﯣ
ﯤ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀. Àmọ́, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
آية رقم 18
ﯥﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
آية رقم 19
ﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
آية رقم 20
ﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
آية رقم 21
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (t’ó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
آية رقم 22
ﯽﯾﯿﰀﰁ
ﰂ
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
آية رقم 23
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
آية رقم 24
ﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Ó máa wí pé: "Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi."
آية رقم 25
ﭡﭢﭣﭤﭥ
ﭦ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
آية رقم 26
ﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
آية رقم 27
ﭬﭭﭮ
ﭯ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
آية رقم 28
ﭰﭱﭲﭳﭴ
ﭵ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
آية رقم 29
ﭶﭷﭸ
ﭹ
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
آية رقم 30
ﭺﭻ
ﭼ
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
تقدم القراءة