سورة البلد

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة البلد باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Èmi (Allāhu) búra pẹ̀lú ìlú yìí.
Ìbúra Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) àti ìbúra ẹ̀dá: Nígbà tí ọ̀rọ̀ tàbí ìṣe kan bá jẹ́ kìkìdá òdodo àti àmọ̀dájú, ìbura lórí rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà kan pàtàkì tí a lè gba ṣe àfihàn ìdánilójú rẹ̀ fún ẹlòmíìràn nítorí kí ó lè bi iyèméjì àti rújúrújú wó lulẹ̀ nínú ọkàn rẹ̀. Níwọ̀n ìgbà tí ọ̀rọ̀ àti ìṣe Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì ti dájú pé iṣẹ́ Ọwọ́ Rẹ̀ ni níti òdodo àti àmọ̀dàjù, ẹ̀tọ́ ni fún Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) láti fi èyíkéyìí nínú wọn búra. Ṣebí iṣẹ́ ọwọ́ Allāhu ni gbogbo bíbẹ. Àmọ́, ẹ̀dá kan kò gbọdọ̀ fi ẹ̀dá mìíràn búra nítorí pé, ẹ̀dá kan kì í ṣe iṣẹ́ ọwọ́ ẹ̀dá mìíràn. Allāhu nìkan ni òdodo àti àmọ̀dájú fún ẹ̀dá láti fi búra nítorí pé, fífi Allāhu nìkan ṣoṣo búra ni ẹ̀sìn gbà wá láyè mọ láti fi búra. Bíbá Allāhu wá akẹgbẹ́ (ẹbọ ṣíṣe) sì ni fífi n̄ǹkan mìíràn búra lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā).
آية رقم 2
Ìwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).
Ẹ̀tọ́ tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fún Ànábì Rẹ̀ (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ni kíkógun ja ìlú Mọkkah lásìkò ogun Ìṣí Mọkkah “Fat-hu Mọkkah”. Ṣíwájú àsìkò yìí àti lẹ́yìn rẹ̀, kò lẹ́tọ̀ọ́ fún ẹnikẹ́ni mọ́ láti jagun nínú Mọkkah alápọ̀n-ọ́nlé.
آية رقم 3
(Mo tún) búra pẹ̀lú òbí àti ohun t’ó bí.
آية رقم 4
Dájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.
آية رقم 5
Ṣé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?
آية رقم 6
Ó (sì) ń wí pé: "Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì s.a.w.)"
آية رقم 9
Àti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?
آية رقم 10
A sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.
آية رقم 11
Kò sì mú àkàbà ìgbàlà gùn!
آية رقم 12
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ àkàbà ìgbàlà?
آية رقم 13
(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.
آية رقم 15
(Ó lè jẹ́) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,
آية رقم 16
tàbí mẹ́kùnnú, ẹni ilẹ̀ẹ́lẹ̀.
Lẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.
آية رقم 18
Àwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.
آية رقم 19
Àwọn t’ó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:7.
آية رقم 20
A máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.
تقدم القراءة