ترجمة معاني سورة الليل باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
آية رقم 1
ﮡﮢﮣ
ﮤ
(Allāhu) búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú.
آية رقم 2
ﮥﮦﮧ
ﮨ
Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n.
آية رقم 3
ﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Ó tún búra pẹ̀lú Ẹni tí Ó dá akọ àti abo.
Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni Ẹni tí Ó dá akọ àti abo. Ó sì ń fi ara Rẹ̀ búra.
آية رقم 4
ﮮﮯﮰ
ﮱ
Dájúdájú iṣẹ́ yín, ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni.
آية رقم 5
ﯓﯔﯕﯖ
ﯗ
Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),
آية رقم 6
ﯘﯙ
ﯚ
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní òdodo,
آية رقم 7
ﯛﯜ
ﯝ
A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.
آية رقم 8
ﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni t’ó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,
آية رقم 9
ﯣﯤ
ﯥ
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní irọ́,
آية رقم 10
ﭑﭒ
ﭓ
A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.
آية رقم 11
ﭔﭕﭖﭗﭘﭙ
ﭚ
Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá já bọ́ (sínú Iná).
آية رقم 12
ﭛﭜﭝ
ﭞ
Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.
آية رقم 13
ﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.
آية رقم 14
ﭤﭥﭦ
ﭧ
Nítorí náà, Mo ti fi Iná eléjò fòfò kìlọ̀ fun yín.
آية رقم 15
ﭨﭩﭪﭫ
ﭬ
Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,
آية رقم 16
ﭭﭮﭯ
ﭰ
ẹni tí ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.
آية رقم 17
ﭱﭲ
ﭳ
Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),
آية رقم 18
ﭴﭵﭶﭷ
ﭸ
ẹni t’ó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).
آية رقم 19
ﭹﭺﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,
آية رقم 20
ﮀﮁﮂﮃﮄ
ﮅ
bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.
آية رقم 21
ﮆﮇ
ﮈ
Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rẹ̀).
تقدم القراءة