سورة الليل

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة الليل باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
(Allāhu) búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú.
آية رقم 2
Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n.
آية رقم 3
Ó tún búra pẹ̀lú Ẹni tí Ó dá akọ àti abo.
Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni Ẹni tí Ó dá akọ àti abo. Ó sì ń fi ara Rẹ̀ búra.
آية رقم 4
Dájúdájú iṣẹ́ yín, ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni.
آية رقم 5
Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),
آية رقم 6
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní òdodo,
آية رقم 7
A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.
آية رقم 8
Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni t’ó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,
آية رقم 9
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní irọ́,
آية رقم 10
A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.
آية رقم 11
Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá já bọ́ (sínú Iná).
آية رقم 12
Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.
آية رقم 13
Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.
آية رقم 14
Nítorí náà, Mo ti fi Iná eléjò fòfò kìlọ̀ fun yín.
آية رقم 15
Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,
آية رقم 16
ẹni tí ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.
آية رقم 17
Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),
آية رقم 18
ẹni t’ó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).
آية رقم 19
Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,
آية رقم 20
bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.
آية رقم 21
Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rẹ̀).
تقدم القراءة