Àti nítorí ọ̀rọ̀ wọn (yìí): “Dájúdájú àwa pa Mọsīh, ‘Īsā ọmọ Mọryam, Òjíṣẹ́ Allāhu.” Wọn kò pa á, wọn kò sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni. Dájúdájú àwọn t’ó yapa-ẹnu nípa rẹ̀, kúkú wà nínú iyèméjì nínú rẹ̀; kò sí ìmọ̀ kan fún wọn nípa rẹ̀ àfi títẹ̀lé èròkérò. Wọn kò pa á ní àmọ̀dájú.
____________________
Kíyè sí ìyàtọ̀ pàtàkì t’ó wà láààrin awẹ́ gbólóhùn méjì yìí: ìkíní “وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْۚ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنْ أُلْقِيَ شَبَهُهُ عَلَى غَيْرِهِ” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” Òye ìdí èyí sì ni pé, nítorí kí àwọn ọ̀tá Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), tí wọ́n déte láti kàn án mọ́ igi àgbélébùú lè mú ẹni tí àwòrán rẹ̀ jọ Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Onítọ̀ún ni wọ́n sì kàn mọ́ igi àgbélébùú, kì í ṣe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Èyí sì ni ète ti Allāhu tí Ó fi gba Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìdí sì nìyí tí àwọn ọ̀tá rẹ̀ fi wà nínú iyèméjì nípa ta gan-an ni wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú nítorí pé, ẹni tí wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú jọ àwòrán Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni, kò jọ ọ́ ní ohùn rárá. Síwájú sí i, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (ìyẹn ‘ilmu-ssọrf) fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” t’ó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “lām” nínú awẹ́ gbólóhùn
“وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْ ۚ” jẹ́ “شَبَهٌ” (ṣabahun / ṣabah) tàbí “شِبْهٌ” (ṣibhun / ṣibh) – ìtúmọ̀ “ìjọra / àfijọ / àwòrán kan náà”. Àti pé àkòónú “شَبَهٌ”/ “شِبْهٌ” (ṣabahun / ṣibhun) nígbà náà ni pé, wọ́n ń lò ó fún n̄ǹkan méjì t’ó jẹ́ oríṣìí méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àmọ́ tí wọ́n jọra wọn ní àwòrán. Ìtúmọ̀ yìí sì ni gbogbo ọ̀rọ̀ t’ó pilẹ̀ lórí àwọn háràfí mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí “ش ب ه” ní nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Ẹ wo àwọn àyè náà; sūrah al-Baƙọrah; 2:25, sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:7, sūrah al-’Ani‘ām; 6: 99 àti 141, àti sūrah as-Zumọr; 39:23. Bákàn náà, awẹ́ gbólóhùn kejì “وَلَكِنْ شُبِّهَ عَلَيْهِمْ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنِ اشْتُبِهَ عَلَيْهِمْ ” “ṣùgbọ́n a fi rú wọn lójú / ṣùgbọ́n a dà á rú mọ́ wọn lójú”. Ìyẹn sì kọ́ ni al-Ƙur’ān sọ. Wòóore, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (‘ilmu-ssọrf) tún fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” t'ó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “ ‘alā” nínú gbólóhùn yìí jẹ́ “شُبْهَةٌ” (ṣubhatun / ṣubhah) – ìtúmọ̀: “ìrújú / rújúrújú”. Àmọ́ sá, “ìjọra” máa ń yọrí sí “ìrújú” nígbà tí kò bá sí “àmọ̀dájú”. Àkíyèsí kejì: Gbogbo tírà tafsīr t’ó sọ̀rọ̀ lórí
“وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْ” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” l’ó mú ọ̀rọ̀ wá lórí bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe gbé àwòrán ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) wọ ẹnì kan nínú àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀. Kódà wọ́n gba ọ̀rọ̀ náà wá ni láti ọ̀dọ̀ Ọmọ ‘Abbās (r.ahmọ), gẹ́gẹ́ bí a ṣe lè rí i kà nínú tafsīr Zādu-l-Mọsīr. Ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ nípa ipò Ọmọ ‘Abbās (r.ahmọ) nínú ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ al-Ƙur’ān tàbí ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ hadīth l’ó lè pe ìtàn náà ní ìtàn ’Isrọ̄’īliyāt.
____________________
Kíyè sí ìyàtọ̀ pàtàkì t’ó wà láààrin awẹ́ gbólóhùn méjì yìí: ìkíní “وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْۚ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنْ أُلْقِيَ شَبَهُهُ عَلَى غَيْرِهِ” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” Òye ìdí èyí sì ni pé, nítorí kí àwọn ọ̀tá Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), tí wọ́n déte láti kàn án mọ́ igi àgbélébùú lè mú ẹni tí àwòrán rẹ̀ jọ Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Onítọ̀ún ni wọ́n sì kàn mọ́ igi àgbélébùú, kì í ṣe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Èyí sì ni ète ti Allāhu tí Ó fi gba Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìdí sì nìyí tí àwọn ọ̀tá rẹ̀ fi wà nínú iyèméjì nípa ta gan-an ni wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú nítorí pé, ẹni tí wọ́n kàn mọ́ igi àgbélébùú jọ àwòrán Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni, kò jọ ọ́ ní ohùn rárá. Síwájú sí i, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (ìyẹn ‘ilmu-ssọrf) fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” t’ó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “lām” nínú awẹ́ gbólóhùn
“وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْ ۚ” jẹ́ “شَبَهٌ” (ṣabahun / ṣabah) tàbí “شِبْهٌ” (ṣibhun / ṣibh) – ìtúmọ̀ “ìjọra / àfijọ / àwòrán kan náà”. Àti pé àkòónú “شَبَهٌ”/ “شِبْهٌ” (ṣabahun / ṣibhun) nígbà náà ni pé, wọ́n ń lò ó fún n̄ǹkan méjì t’ó jẹ́ oríṣìí méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àmọ́ tí wọ́n jọra wọn ní àwòrán. Ìtúmọ̀ yìí sì ni gbogbo ọ̀rọ̀ t’ó pilẹ̀ lórí àwọn háràfí mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí “ش ب ه” ní nínú al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. Ẹ wo àwọn àyè náà; sūrah al-Baƙọrah; 2:25, sūrah āli ‘Imrọ̄n; 3:7, sūrah al-’Ani‘ām; 6: 99 àti 141, àti sūrah as-Zumọr; 39:23. Bákàn náà, awẹ́ gbólóhùn kejì “وَلَكِنْ شُبِّهَ عَلَيْهِمْ” ìtúmọ̀ rẹ̀ ni “وَلَكِنِ اشْتُبِهَ عَلَيْهِمْ ” “ṣùgbọ́n a fi rú wọn lójú / ṣùgbọ́n a dà á rú mọ́ wọn lójú”. Ìyẹn sì kọ́ ni al-Ƙur’ān sọ. Wòóore, ẹ̀kọ́ nípa mọfọ́lọ́jì èdè Lárúbáwá (‘ilmu-ssọrf) tún fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ọ̀rọ̀-orúkọ fún “شُبِّهَ” t'ó jẹyọ pẹ̀lú háràfí “ ‘alā” nínú gbólóhùn yìí jẹ́ “شُبْهَةٌ” (ṣubhatun / ṣubhah) – ìtúmọ̀: “ìrújú / rújúrújú”. Àmọ́ sá, “ìjọra” máa ń yọrí sí “ìrújú” nígbà tí kò bá sí “àmọ̀dájú”. Àkíyèsí kejì: Gbogbo tírà tafsīr t’ó sọ̀rọ̀ lórí
“وَلَٰكِن شُبِّهَ لَهُمْ” “ṣùgbọ́n A gbé àwòrán rẹ̀ wọ ẹlòmíìràn fún wọn ni.” l’ó mú ọ̀rọ̀ wá lórí bí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe gbé àwòrán ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) wọ ẹnì kan nínú àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀. Kódà wọ́n gba ọ̀rọ̀ náà wá ni láti ọ̀dọ̀ Ọmọ ‘Abbās (r.ahmọ), gẹ́gẹ́ bí a ṣe lè rí i kà nínú tafsīr Zādu-l-Mọsīr. Ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ nípa ipò Ọmọ ‘Abbās (r.ahmọ) nínú ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ al-Ƙur’ān tàbí ẹni tí kò bá ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ hadīth l’ó lè pe ìtàn náà ní ìtàn ’Isrọ̄’īliyāt.
الترجمة اليورباوية