Ìtumọ̀ Sura العاديات ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮱﯓ
ﯔ
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn ẹṣin t’ó ń sáré t’ó ń mí hẹlẹhẹlẹ ní ojú-ogun.
Verse 2
ﯕﯖ
ﯗ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí pátákò ẹsẹ̀ wọn ń ṣáná (níbi eré sísá).
Verse 3
ﯘﯙ
ﯚ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn ẹṣin t’ó ń kọlu ọ̀tá ẹ̀sìn ní òwúrọ̀ kùtùkùtù.
Verse 4
ﯛﯜﯝ
ﯞ
Wọ́n sì fi (pátákò ẹsẹ̀ wọn) tu eruku (ilẹ̀ ọ̀tá) sókè.
Verse 5
ﯟﯠﯡ
ﯢ
Wọ́n tún bẹ́ gìjà papọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ sáààrin àkójọ ọ̀tá.
Verse 6
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Dájúdájú ènìyàn ni aláìmoore sí Olúwa rẹ̀.
Verse 7
ﭖﭗﭘﭙ
ﭚ
Dájúdájú Allāhu sì ń jẹ́ Ẹlẹ́rìí lórí ìyẹn.
Verse 8
ﭛﭜﭝﭞ
ﭟ
Àti pé dájúdájú ènìyàn le gan-an níbi ìfẹ́ oore ayé.
Verse 9
Ṣé kò mọ̀ pé nígbà tí wọ́n bá tú ohun t’ó wà nínú sàréè jáde (fún àjíǹde),
Verse 10
ﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
tí wọ́n sì tú ohun t’ó wà nínú igbá-àyà ẹ̀dá síta pátápátá,
Verse 11
ﭮﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
dájúdájú Olúwa wọn ni Alámọ̀tán nípa wọn ní Ọjọ́ yẹn?
تقدم القراءة