Ìtumọ̀ Sura النازعات ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮢﮣ
ﮤ
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́.
Verse 2
ﮥﮦ
ﮧ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 3
ﮨﮩ
ﮪ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀.
Verse 4
ﮫﮬ
ﮭ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà.
Verse 5
ﮮﮯ
ﮰ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń ṣètò ilé ayé.
Verse 6
ﮱﯓﯔ
ﯕ
Ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa mi gbogbo ayé tìtì pẹ̀lú ohùn igbe.
Verse 7
ﯖﯗ
ﯘ
Ìfọn kejì fún Àjíǹde sì máa tèlé e.
Verse 8
ﯙﯚﯛ
ﯜ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Verse 9
ﯝﯞ
ﯟ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Verse 10
ﯠﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Wọn yóò wí pé: "Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Verse 11
ﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun t’ó kẹfun tán?"
Verse 12
ﯫﯬﯭﯮﯯ
ﯰ
Wọ́n wí pé: "Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni t’ó pè é nírọ́.)"
Verse 13
ﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
Verse 14
ﯶﯷﯸ
ﯹ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Verse 15
ﯺﯻﯼﯽ
ﯾ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Verse 16
ﯿﰀﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonífojì mímọ́, Tuwā.
Verse 17
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-àlà.
Verse 18
ﭗﭘﭙﭚﭛﭜ
ﭝ
Kí o sì sọ pé: "Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Verse 19
ﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, kí o páyà (Rẹ̀)."
Verse 20
ﭣﭤﭥ
ﭦ
Ó sì fi àmì t’ó tóbi hàn án.
Verse 21
ﭧﭨ
ﭩ
(Àmọ́) ó pè é lópùrọ́. Ó sì yapa rẹ̀.
Verse 22
ﭪﭫﭬ
ﭭ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Verse 23
ﭮﭯ
ﭰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Verse 24
ﭱﭲﭳﭴ
ﭵ
Ó sì wí pé: "Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ."
Verse 25
ﭶﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).
____________________
Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: "Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!" Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
____________________
Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: "Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!" Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
Verse 26
ﭼﭽﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni t’ó ń páyà (Allāhu).
Verse 27
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Verse 28
ﮋﮌﮍ
ﮎ
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé t’ó gún régé.
Verse 29
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Verse 30
ﮔﮕﮖﮗ
ﮘ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
Verse 31
ﮙﮚﮛﮜ
ﮝ
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Verse 32
ﮞﮟ
ﮠ
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Verse 33
ﮡﮢﮣ
ﮤ
Ìgbádùn ni fun yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Verse 34
ﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
Verse 35
ﮪﮫﮬﮭﮮ
ﮯ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
Verse 36
ﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni t’ó ríran.
Verse 37
ﯖﯗﯘ
ﯙ
Nítorí náà, ní ti ẹni t’ó bá tayọ ẹnu-àlà,
Verse 38
ﯚﯛﯜ
ﯝ
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
Verse 39
ﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Verse 40
Ní ti ẹni tí ó bá páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
Verse 41
ﯭﯮﯯﯰ
ﯱ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Verse 42
ﯲﯳﯴﯵﯶ
ﯷ
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: "Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?"
Verse 43
ﯸﯹﯺﯻ
ﯼ
Ọ̀nà wo ni ìwọ lè fi ní (ìmọ̀) ìrántí rẹ̀ ná?
Verse 44
ﯽﯾﯿ
ﰀ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Verse 45
ﰁﰂﰃﰄﰅ
ﰆ
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni t’ó ń páyà rẹ̀.
Verse 46
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò lò tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan lọ (nílé ayé).
تقدم القراءة