Ìtumọ̀ Sura الغاشية ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭽﭾﭿﮀ
ﮁ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ nípa ohun t’ó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Verse 2
ﮂﮃﮄ
ﮅ
Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.
Verse 3
ﮆﮇ
ﮈ
Oníṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni wọ́n nílé ayé).
Verse 4
ﮉﮊﮋ
ﮌ
Wọ́n máa wọ inú Iná t’ó gbóná janjan (ní ọ̀run).
Verse 5
ﮍﮎﮏﮐ
ﮑ
Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi gbígbóná mu.
Verse 6
ﮒﮓﮔﮕﮖﮗ
ﮘ
Kò sí oúnjẹ kan fún wọn àyàfi igi ẹlẹ́gùn-ún gbígbẹ.
Verse 7
ﮙﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.
Verse 8
ﮠﮡﮢ
ﮣ
Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn
Verse 9
ﮤﮥ
ﮦ
nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.
Verse 10
ﮧﮨﮩ
ﮪ
(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
Verse 11
ﮫﮬﮭﮮ
ﮯ
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.
Verse 12
ﮰﮱﯓ
ﯔ
Omi ìṣẹ́lẹ̀rú t’ó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.
Verse 13
ﯕﯖﯗ
ﯘ
Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,
Verse 14
ﯙﯚ
ﯛ
àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),
Verse 15
ﯜﯝ
ﯞ
àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,
Verse 16
ﯟﯠ
ﯡ
àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.
Verse 17
ﯢﯣﯤﯥﯦﯧ
ﯨ
Nítorí náà, ṣé wọn kò wo ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;
Verse 18
ﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
àti sánmọ̀, bí A ti ṣe gbé e sókè;
Verse 19
ﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);
Verse 20
ﯳﯴﯵﯶ
ﯷ
àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ ní gban̄sasa?
Verse 21
ﯸﯹﯺﯻ
ﯼ
Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.
Verse 22
ﯽﯾﯿ
ﰀ
Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn
Verse 23
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.
Verse 24
ﭖﭗﭘﭙ
ﭚ
Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà t’ó tóbi jùlọ.
Verse 25
ﭛﭜﭝ
ﭞ
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.
Verse 26
ﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.
تقدم القراءة