Ìtumọ̀ Sura الصافات ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭑﭒ
ﭓ
(Allāhu búra pẹ̀lú) àwọn mọlāika olùtò-lọ́wọ̀ọ̀wọ́ tààrà;
Verse 2
ﭔﭕ
ﭖ
àti àwọn mọlāika t’ó ń wọ́ ẹ̀ṣújò kiri tààrà;
Verse 3
ﭗﭘ
ﭙ
àti àwọn mọlāika òǹké-tírà ìrántí.
Verse 4
ﭚﭛﭜ
ﭝ
Dájúdájú Ọlọ́hun yín, Ọ̀kan ṣoṣo ni;
Verse 5
Olúwa àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ àti ohunkóhun tí ń bẹ láààrin àwọn méjèèjì. Òun sì ni Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn.
Verse 6
ﭦﭧﭨﭩﭪﭫ
ﭬ
Dájúdájú Àwa fi àwọn ìràwọ̀ ṣe sánmọ̀ ilé ayé ní ọ̀ṣọ́
Verse 7
ﭭﭮﭯﭰﭱ
ﭲ
àti ìṣọ́ níbi (aburú) gbogbo èṣù olóríkunkun.
Verse 8
(Àwọn èṣù) kò sì níí lè tẹ́tí sí ìjọ (mọlāika t’ó wà ní) àyè gíga jùlọ (nínú sánmọ̀). (Àwọn mọlāika) yó sì máa ku (àwọn èṣù) lókò (ẹ̀ta ìràwọ̀) ní gbogbo agbègbè (sánmọ̀).
Verse 9
ﭽﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Wọ́n ń lé wọn dànù. Ìyà àìlópin sì wà fún wọn.
Verse 10
(Wọn kò níí gbọ́ ọ̀rọ̀ ní kíkún) àyàfi ẹni tí ó bá rí ọ̀rọ̀ àjígbọ́ gbé, nígbà náà (ni mọlāika) yó sì fi ẹ̀ta ìràwọ̀ iná t’ó máa jó o tẹ̀lé e.
Verse 11
Bi wọ́n léèrè wò pé ṣé àwọn ni ìṣẹ̀dá wọn lágbára jùlọ ni tàbí àwọn (ènìyàn) tí A dá? Dájúdájú Àwa dá wọn láti ara erùpẹ̀ t’ó lẹ̀ mọ́ra wọn.
Verse 12
ﮙﮚﮛ
ﮜ
Rárá (kò jọra wọn); ìwọ ṣèèmọ̀ (nípa al-Ƙur’ān), àwọn sì ń ṣe yẹ̀yẹ́.
Verse 13
ﮝﮞﮟﮠ
ﮡ
Àti pé nígbà tí wọ́n bá ṣe ìrántí fún wọn, wọn kò níí lo ìrántí.
Verse 14
ﮢﮣﮤﮥ
ﮦ
Nígbà tí wọ́n bá tún rí àmì kan, wọn yóò máa ṣe yẹ̀yẹ́.
Verse 15
ﮧﮨﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Wọ́n sì wí pé: "Èyí kò jẹ́ kiní kan bí kò ṣe idán pọ́nńbélé.
Verse 16
Ṣé nígbà tí a bá kú tán, tí a ti di erùpẹ̀ àti egungun, ṣé dájúdájú Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
Verse 17
ﯗﯘ
ﯙ
Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"
Verse 18
ﯚﯛﯜﯝ
ﯞ
Sọ pé: "Bẹ́ẹ̀ ni. Ẹ̀yin yó sì di ẹni yẹpẹrẹ."
Verse 19
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan mà ni. Nígbà náà ni wọn yóò máa wò sùn.
Verse 20
ﯧﯨﯩﯪﯫ
ﯬ
Wọ́n á wí pé: "Ègbé wa! Èyí ni Ọjọ́ ẹ̀san."
Verse 21
Èyí ni ọjọ́ Ìdájọ́ èyí tí ẹ̀ ń pè nírọ́.
Verse 22
Ẹ kó àwọn t’ó ṣàbòsí jọ, àwọn ìyàwó wọn àti ohun tí wọ́n ń jọ́sìn fún
Verse 23
lẹ́yìn Allāhu. Kí ẹ sì júwe wọn sí ojú ọ̀nà iná Jẹhīm.
Verse 24
ﰆﰇﰈﰉ
ﰊ
Ẹ dá wọn dúró ná, dájúdájú wọ́n máa bi wọ́n léèrè ìbéèrè.
Verse 25
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Kí ni kò jẹ́ kí ẹ ranra yín lọ́wọ́?
Verse 26
ﭖﭗﭘﭙ
ﭚ
Rárá, wọ́n ti juwọ́ jusẹ̀ sílẹ̀ ní òní ni.
Verse 27
ﭛﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, tí wọn yóò máa bira wọn léèrè ìbéèrè.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mu’minūn; 23:101.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mu’minūn; 23:101.
Verse 28
ﭡﭢﭣﭤﭥﭦ
ﭧ
(Àwọn ènìyàn) wí pé: "Dájúdájú ẹ̀yin l’ẹ̀ ń gba ọ̀tún wọlé sí wa lára (láti ṣì wá lọ́nà)."
____________________
Gbígba ọ̀tún wọlé sí ni lára ni pé, wọ́n ń lo orúkọ ’Islām láti fi pe àwọn ènìyàn lọ síbi ìṣẹbọ dípò mímú Allāhu ní Ọ̀kan ṣoṣo. Àpẹẹrẹ àwọn wọ̀nyí ni àwọn àáfà tí wọ́n bá àwọn àlùjọ̀nnú dòwò pọ̀ tán, tí wọ́n sọra wọn di oníṣẹ́-ìyanu àti àwọn onibidiah bí ìjọ Ahmadiyyah àti ìjọ Tijāniyyah.
____________________
Gbígba ọ̀tún wọlé sí ni lára ni pé, wọ́n ń lo orúkọ ’Islām láti fi pe àwọn ènìyàn lọ síbi ìṣẹbọ dípò mímú Allāhu ní Ọ̀kan ṣoṣo. Àpẹẹrẹ àwọn wọ̀nyí ni àwọn àáfà tí wọ́n bá àwọn àlùjọ̀nnú dòwò pọ̀ tán, tí wọ́n sọra wọn di oníṣẹ́-ìyanu àti àwọn onibidiah bí ìjọ Ahmadiyyah àti ìjọ Tijāniyyah.
Verse 29
ﭨﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
(Àwọn àlùjànnú) wí pé: "Rárá o (àwa kọ́), ẹ̀yin ni ẹ kò jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 30
Àti pé àwa kò ní agbára kan lórí yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin jẹ́ ìjọ olùtayọ-ẹnu àlà.
Verse 31
Ọ̀rọ̀ Olúwa wa sì kò lé wa lórí pé dájúdájú àwa yóò tọ́ Iná wò.
Verse 32
ﮂﮃﮄﮅ
ﮆ
Nítorí náà, a ṣì yín lọ́nà. Dájúdájú àwa náà sì jẹ́ olùṣìnà."
Verse 33
ﮇﮈﮉﮊﮋ
ﮌ
Dájúdájú ní ọjọ́ yẹn, akẹgbẹ́ ni wọ́n nínú Ìyà.
Verse 34
ﮍﮎﮏﮐ
ﮑ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa yóò ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
Verse 35
Dájúdájú nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé "Kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Allāhu.", wọn yóò máa ṣègbéraga.
Verse 36
ﮝﮞﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Wọ́n sì ń wí pé: "Ṣé a máa fi àwọn òrìṣà wa sílẹ̀ nítorí eléwì wèrè kan?"
Verse 37
ﮤﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Kò rí bẹ́ẹ̀. Ó mú òdodo wá ni. Ó sì ń jẹ́rìí sí òdodo àwọn Òjíṣẹ́ náà.
Verse 38
ﮪﮫﮬﮭ
ﮮ
Dájúdájú ẹ máa tọ́ ìyà ẹlẹ́ta-eléro wò.
Verse 39
ﮯﮰﮱﯓﯔﯕ
ﯖ
A ò níí san yín ní ẹ̀san kan àfi ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Verse 40
ﯗﯘﯙﯚ
ﯛ
Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.
Verse 41
ﯜﯝﯞﯟ
ﯠ
Ti àwọn wọ̀nyẹn sì ni arísìkí tí wọ́n ti mọ̀;
Verse 42
ﯡﯢﯣ
ﯤ
àwọn èso. Àwọn sì ni alápọ̀n-ọ́nlé
Verse 43
ﯥﯦﯧ
ﯨ
nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Verse 44
ﯩﯪﯫ
ﯬ
Lórí àwọn ìtẹ́ ni wọn yóò ti kọjú síra wọn.
Verse 45
ﯭﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Wọn yóò máa gbé ife ọtí mímọ́ káà kiri ọ̀dọ̀ wọn.
Verse 46
ﯳﯴﯵ
ﯶ
Funfun ni (ọtí náà). Ó ń dùn lẹ́nu àwọn t’ó máa mu ún.
Verse 47
Kò sí ìpalára kan fún wọn nínú rẹ̀, wọn kò sì níí hunrírà lórí rẹ̀.
Verse 48
ﯿﰀﰁﰂ
ﰃ
Àwọn obìnrin tí kì í wo ẹlòmíìràn, àwọn ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ yó sì wà lọ́dọ̀ wọn.
Verse 49
ﰄﰅﰆ
ﰇ
Wọ́n dà bí tinú ẹyin.
____________________
Àwọn kristiẹni, nínú ọ̀rọ̀ wọn kan tí wọ́n ń fi tàbùkù àwọn ìkẹ́ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra, wọ́n sọ pé, “Nítorí ọ̀wọ́n èso ní erúkùsù ilẹ̀ Lárúbáwá ni Allāhu fi ṣàdéhùn ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso fún àwọn mùsùlùmí nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀; nítorí pé àwọn Lárúbáwá fẹ́ràn ọtí àmupara ni Allāhu fi bá wọn pèsè ọtí ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ sílẹ̀ dè wọ́n nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀; nítorí pé àwọn Lárúbáwá fẹ́ràn àgbèrè ṣíṣe ni Allāhu fi bá wọn pèsè obìnrin ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ sílẹ̀ fún ẹnì kọ̀ọ̀kan àwọn mùsùlùmí nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀!”
Èsì: Ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn kristiẹni wọ̀nyí, yàtọ̀ sí pé ó ń fi wọ́n hàn gẹ́gẹ́ bí aláwàdà kẹríkẹrì, ó tún jẹ́ kí á mọ̀ pé wọn kò retí ìkẹ́ kan kan lọ́run ní tiwọn. Tí ó bá jẹ́ pé, wọ́n ń retí ìkẹ́ kan ní ọ̀run, irú ìkẹ́ wo gan-an ni wọ́n ń retí nígbà náà? Síwájú sí i, kì í kúkú ṣe Lárúbáwá nìkan ni mùsùlùmí. Gbogbo àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu ni mùsùlùmí. Àwọn kristiẹni ṣe wá ń sọ̀rọ̀ bí ẹni pé nítorí Lárúbáwá nìkan ni Allāhu fi dá Ọgbà Ìdẹ̀ra! Ìgbádùn inú Ọgbà Ìdẹ̀ra wulẹ̀ pọ̀ tayọ èso, ọtí tí kìí pani àti obìnrin. Àmọ́ sá, kò wulẹ̀ sí ìgbádùn kan kan fún àwọn aláìgbàgbọ́ lọ́run bí kò ṣe Iná gbére.
____________________
Àwọn kristiẹni, nínú ọ̀rọ̀ wọn kan tí wọ́n ń fi tàbùkù àwọn ìkẹ́ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra, wọ́n sọ pé, “Nítorí ọ̀wọ́n èso ní erúkùsù ilẹ̀ Lárúbáwá ni Allāhu fi ṣàdéhùn ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso fún àwọn mùsùlùmí nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀; nítorí pé àwọn Lárúbáwá fẹ́ràn ọtí àmupara ni Allāhu fi bá wọn pèsè ọtí ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ sílẹ̀ dè wọ́n nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀; nítorí pé àwọn Lárúbáwá fẹ́ràn àgbèrè ṣíṣe ni Allāhu fi bá wọn pèsè obìnrin ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ sílẹ̀ fún ẹnì kọ̀ọ̀kan àwọn mùsùlùmí nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra Rẹ̀!”
Èsì: Ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn kristiẹni wọ̀nyí, yàtọ̀ sí pé ó ń fi wọ́n hàn gẹ́gẹ́ bí aláwàdà kẹríkẹrì, ó tún jẹ́ kí á mọ̀ pé wọn kò retí ìkẹ́ kan kan lọ́run ní tiwọn. Tí ó bá jẹ́ pé, wọ́n ń retí ìkẹ́ kan ní ọ̀run, irú ìkẹ́ wo gan-an ni wọ́n ń retí nígbà náà? Síwájú sí i, kì í kúkú ṣe Lárúbáwá nìkan ni mùsùlùmí. Gbogbo àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu ni mùsùlùmí. Àwọn kristiẹni ṣe wá ń sọ̀rọ̀ bí ẹni pé nítorí Lárúbáwá nìkan ni Allāhu fi dá Ọgbà Ìdẹ̀ra! Ìgbádùn inú Ọgbà Ìdẹ̀ra wulẹ̀ pọ̀ tayọ èso, ọtí tí kìí pani àti obìnrin. Àmọ́ sá, kò wulẹ̀ sí ìgbádùn kan kan fún àwọn aláìgbàgbọ́ lọ́run bí kò ṣe Iná gbére.
Verse 50
ﰈﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, tí wọn yóò máa bira wọn léèrè ìbéèrè.
Verse 51
Òǹsọ̀rọ̀ kan nínú wọn yóò sọ pé: "Dájúdájú èmi ní ọ̀rẹ́ kan
Verse 52
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
tí ó ń wí pé, “Ṣé dájúdájú ìwọ wà nínú àwọn onígbàgbọ́ nínú Ọjọ́ Àjíǹde?
Verse 53
Ṣé nígbà tí a bá kú tán, tí a ti di erùpẹ̀ àti egungun, ṣé dájúdájú Wọn yóò san wá ní ẹ̀san ni?”
Verse 54
ﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Ó sọ pé: "Ṣé ẹ̀yin yóò yọjú wo (ẹni náà tí kò gbàgbọ́ nínú Ọjọ́ àjíǹde)?"
Verse 55
ﭣﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Ó yọjú wò ó. Ó sì rí i láààrin gbùngbùn nínú iná Jẹhīm.
Verse 56
ﭩﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Ó (sì) sọ pé: "Mó fi Allāhu búra, ìwọ fẹ́ẹ̀ kó ìparun bá mi tán.
Verse 57
ﭯﭰﭱﭲﭳﭴ
ﭵ
Àti pé tí kì í bá ṣe ìdẹ̀ra Olúwa mi ni, èmi náà ìbá wà nínú ẹni tí wọ́n máa mú wá sínú Iná.
Verse 58
ﭶﭷﭸ
ﭹ
Àwa kò sá níí kú mọ́ báyìí?
Verse 59
ﭺﭻﭼﭽﭾﭿ
ﮀ
Àfi ikú wa àkọ́kọ́. Wọn kò sì níí jẹ àwa níyà.
Verse 60
ﮁﮂﮃﮄﮅ
ﮆ
Dájúdájú èyí, òhun ni èrèǹjẹ ńlá."
Verse 61
ﮇﮈﮉﮊ
ﮋ
Nítorí irú èyí, kí àwọn olùṣẹ̀sìn máa ṣẹ̀sìn lọ.
Verse 62
ﮌﮍﮎﮏﮐﮑ
ﮒ
Ǹjẹ́ ìyẹn l’ó lóore jùlọ ní ibùdésí ni tàbí igi zaƙūm (igi ẹlẹ́gùn-ún)?
Verse 63
ﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Dájúdájú Àwa ṣe é ní àdánwò fún àwọn alábòsí.
Verse 64
ﮘﮙﮚﮛﮜﮝ
ﮞ
Dájúdájú òhun ni igi kan tí ó máa hù jáde láti ìdí iná Jẹhīm.
Verse 65
ﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Èso rẹ̀ dà bí orí àwọn èṣù.
Verse 66
ﮤﮥﮦﮧﮨﮩ
ﮪ
Dájúdájú wọn yóò máa jẹ nínú rẹ̀. Nítorí náà, wọn yóò fi kún inú wọn bámúbámú.
Verse 67
Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò mu n̄ǹkan mímu àwọyúnwẹ̀jẹ̀ gbígbóná lé e lórí.
Verse 68
ﯔﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ibùpadàsí wọn ni iná Jẹhīm.
Verse 69
ﯚﯛﯜﯝ
ﯞ
Dájúdájú wọ́n bá àwọn bàbá wọn ní olùṣìnà.
Verse 70
ﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Àwọn náà sì ń yára tẹ̀lé orípa wọn.
Verse 71
ﯤﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
Dájúdájú ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn ẹni àkọ́kọ́ ti ṣìnà ṣíwájú wọn.
Verse 72
ﯪﯫﯬﯭ
ﯮ
Dájúdájú A ti rán àwọn olùkìlọ̀ sí wọn.
Verse 73
ﯯﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Nítorí náà, wo bí àtubọ̀tán àwọn ẹni-akìlọ̀-fún ti rí.
Verse 74
ﯵﯶﯷﯸ
ﯹ
Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.
Verse 75
ﯺﯻﯼﯽﯾ
ﯿ
Dájúdájú (Ànábì) Nūh pè Wá. A sì dára ní olùjẹ́pè.
Verse 76
ﰀﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
A gba òun àti àwọn ará ilé rẹ̀ là kúrò nínú ìbànújẹ́ ńlá.
Verse 77
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
A dá àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ sí lẹ́yìn rẹ̀.
Verse 78
ﭖﭗﭘﭙ
ﭚ
A sì fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.
Verse 79
ﭛﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) Nūh láààrin gbogbo ẹ̀dá.
Verse 80
ﭡﭢﭣﭤ
ﭥ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 81
ﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
Dájúdájú òun wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 82
ﭫﭬﭭ
ﭮ
Lẹ́yìn náà, A tẹ àwọn yòókù rì sínú agbami.
Verse 83
ﭯﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Dájúdájú (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm wà nínú ìjọ (tí ó tẹ̀lé ìlànà) rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, ẹ̀sìn Ànábì Nūh ni ẹ̀sìn Ànábì ’Ibrọ̄hīm (aleehimọ sọlātu wa salām), ẹ̀sìn ’Islām.
____________________
Ìyẹn ni pé, ẹ̀sìn Ànábì Nūh ni ẹ̀sìn Ànábì ’Ibrọ̄hīm (aleehimọ sọlātu wa salām), ẹ̀sìn ’Islām.
Verse 84
ﭵﭶﭷﭸﭹ
ﭺ
(Ẹ rántí) nígbà tí òun náà dojú kọ Olúwa rẹ̀ pẹ̀lú ọkàn mímọ́.
Verse 85
ﭻﭼﭽﭾﭿﮀ
ﮁ
(Rántí) nígbà tí ó sọ fún bàbá rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: "Kí ni ẹ̀ ń jọ́sìn fún?
Verse 86
ﮂﮃﮄﮅﮆ
ﮇ
Ṣé ẹ̀ ń gbèrò láti sọ irọ́ di ọlọ́hun lẹ́yìn Allāhu?
Verse 87
ﮈﮉﮊﮋ
ﮌ
Kí sì ni èrò ọkàn yín sí Olúwa gbogbo ẹ̀dá?”
Verse 88
ﮍﮎﮏﮐ
ﮑ
Ó ṣíjú wo àwọn ìràwọ̀ gan-an.
Verse 89
ﮒﮓﮔ
ﮕ
Ó sì sọ pé: "Dájúdájú ó rẹ̀ mí."
Verse 90
ﮖﮗﮘ
ﮙ
Nítorí náà, wọ́n pa á tì, wọ́n sì lọ.
Verse 91
ﮚﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
Nígbà náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn òrìṣà wọn. Ó sì sọ pé: "Ṣé ẹ ò níí jẹun ni?
Verse 92
ﮡﮢﮣﮤ
ﮥ
Kí ni ó ṣe yín tí ẹ ò sọ̀rọ̀?"
Verse 93
ﮦﮧﮨﮩ
ﮪ
Nígbà náà, ó dojú lílù kọ wọ́n pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún (ó sì rún wọn wómúwómú).
Verse 94
ﮫﮬﮭ
ﮮ
(Àwọn abọ̀rìṣà) sáré wá dojú kọ ọ́.
Verse 95
ﮯﮰﮱﯓ
ﯔ
Ó sọ pé: "Ṣé ẹ óò máa jọ́sìn fún n̄ǹkan tí ẹ gbẹ́ kalẹ̀ lére ni?
Verse 96
ﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
Allāhu l’Ó sì dá ẹ̀yin àti n̄ǹkan tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́."
Verse 97
Wọ́n wí pé: "Ẹ mọ ilé kan fún un, kí ẹ sì jù ú sínú iná."
Verse 98
ﯢﯣﯤﯥﯦ
ﯧ
Wọ́n gbèrò ète sí i. A sì sọ wọ́n di ẹni yẹpẹrẹ.
Verse 99
ﯨﯩﯪﯫﯬﯭ
ﯮ
Ó sọ pé: "Dájúdájú mo máa lọ sí (ìlú tí) Olúwa mi (pa mí láṣẹ láti lọ). Ó sì máa tọ́ mi sọ́nà (láti dé ibẹ̀).
____________________
Ìyẹn ìlú Ṣām.
____________________
Ìyẹn ìlú Ṣām.
Verse 100
ﯯﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Olúwa mi, ta mí lọ́rẹ ọmọ nínú àwọn ẹni rere."
Verse 101
ﯵﯶﯷ
ﯸ
A sì fún un ní ìró ìdùnnú (nípa bíbí) ọmọkùnrin aláfaradà.
Verse 102
Nígbà tí (ọmọ náà) dàgbà, tí ó tó bá (bàbá rẹ̀) ṣe iṣẹ́, (bàbá rẹ̀) sọ pé: "Ọmọ mi, dájúdájú èmi lá àlá pé dájúdájú mò ń dúńbú rẹ. Nítorí náà, wòye sí i, kí ni o rí sí i." Ó sọ pé: "Bàbá mi, ṣe ohun tí Wọ́n pa láṣẹ fún ọ. O máa bá mi nínú àwọn onísùúrù, tí Allāhu bá fẹ́."
Verse 103
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Nígbà tí àwọn méjèèjì juwọ́ jusẹ̀ sílẹ̀, tí (Ànábì ’Ibrọ̄hīm) sì dojú (ọmọ) rẹ̀ bolẹ̀,
____________________
Ìtúmọ̀ “jẹbīn” ni iwájú orí.
____________________
Ìtúmọ̀ “jẹbīn” ni iwájú orí.
Verse 104
ﭖﭗﭘ
ﭙ
A pè é (báyìí) pé, ’Ibrọ̄hīm,
Verse 105
o kúkú ti mú àlá náà ṣẹ. Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 106
ﭣﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Dájúdájú èyí, òhun ni àdánwò pọ́nńbélé.
Verse 107
ﭩﭪﭫ
ﭬ
A sì fi àgbò ńlá ṣèràpadà rẹ̀.
Verse 108
ﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
A tún fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.
Verse 109
ﭲﭳﭴ
ﭵ
Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm.
Verse 110
ﭶﭷﭸ
ﭹ
Báyẹn ni A ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 111
ﭺﭻﭼﭽ
ﭾ
Dájúdájú ó wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 112
ﭿﮀﮁﮂﮃ
ﮄ
A tún fún un ní ìró ìdùnnú (nípa bíbí) ’Ishāƙ, (ó máa jẹ́) Ànábì. (Ó sì máa wà) nínú àwọn ẹni rere.
Verse 113
Àti pé A fún òun àti ’Ishāƙ ní ìbùkún. Ẹni rere àti alábòsí pọ́nńbélé (t’ó ń ṣàbòsí sí) ẹ̀mí ara rẹ̀ wà nínú àrọ́mọdọ́mọ àwọn méjèèjì.
____________________
Bẹ̀rẹ̀ láti āyah 100 títí dé āyah 113, ó ti hàn kedere pé: (ìkíní) Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni àkọ́bí Ànábì ’Ibrọ̄hīm ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām); (ìkejì) Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni ẹni tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pa láṣẹ pé kí Ànábì ’Ibrọ̄hīm ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) pa láti fi jọ́sìn fún Òun; (ìkẹta) Kò sí ohun t’ó jẹmọ́ ẹ̀jẹ́ àti ìmúṣẹ ẹ̀jẹ́ nínú àlá àti ìṣẹ̀lẹ̀ náà; (ìkẹrin) Ìkíní kejì àwọn ọmọ méjèèjì náà ni ẹni ìbùkún. Àmọ́, àwọn kristiẹni, gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti àṣà wọn, orúkọ burúkú ni wọ́n ń fún Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah Hūd; 11:71.
____________________
Bẹ̀rẹ̀ láti āyah 100 títí dé āyah 113, ó ti hàn kedere pé: (ìkíní) Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni àkọ́bí Ànábì ’Ibrọ̄hīm ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām); (ìkejì) Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni ẹni tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pa láṣẹ pé kí Ànábì ’Ibrọ̄hīm ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) pa láti fi jọ́sìn fún Òun; (ìkẹta) Kò sí ohun t’ó jẹmọ́ ẹ̀jẹ́ àti ìmúṣẹ ẹ̀jẹ́ nínú àlá àti ìṣẹ̀lẹ̀ náà; (ìkẹrin) Ìkíní kejì àwọn ọmọ méjèèjì náà ni ẹni ìbùkún. Àmọ́, àwọn kristiẹni, gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti àṣà wọn, orúkọ burúkú ni wọ́n ń fún Ànábì ’Ismā‘īl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ẹ tún wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah Hūd; 11:71.
Verse 114
ﮑﮒﮓﮔﮕ
ﮖ
Dájúdájú A ṣoore fún (Ànábì) Mūsā àti Hārūn.
Verse 115
ﮗﮘﮙﮚﮛ
ﮜ
A gba àwọn méjèèjì àti ìjọ àwọn méjèèjì là kúrò nínú ìbànújẹ́ ńlá.
Verse 116
ﮝﮞﮟﮠ
ﮡ
A tún ṣàrànṣe fún wọn. Àwọn ni wọ́n jẹ́ olùborí (ọ̀tá wọn).
Verse 117
ﮢﮣﮤ
ﮥ
A sì fún àwọn méjèèjì ní Tírà t’ó yanjú.
Verse 118
ﮦﮧﮨ
ﮩ
A tún fi àwọn méjèèjì mọ̀nà tààrà.
Verse 119
ﮪﮫﮬﮭ
ﮮ
A fún àwọn méjèèjì ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.
Verse 120
ﮯﮰﮱﯓ
ﯔ
Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) Mūsā àti Hārūn.
Verse 121
ﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 122
ﯚﯛﯜﯝ
ﯞ
Dájúdájú àwọn méjèèjì wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 123
ﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Dájúdájú (Ànábì) ’Ilyās wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.
Verse 124
ﯤﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
(Ẹ rántí) nígbà tí ó sọ fún ìjọ rẹ̀ pé: "Ṣé ẹ ò níí bẹ̀rù Allāhu ni?
Verse 125
ﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Ṣé ẹ óò máa pe òrìṣà kan, ẹ sì máa fi Ẹni t’Ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá sílẹ̀,
____________________
Ṣé ẹlẹ́dàá mìíràn wà lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni? Ẹ yiri àwọn gbólóhùn wọ̀nyí wò: أَحْسَنَ ٱلْخَٰلِقِينَ Ẹni t’Ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá. (Ó tún wà nínú sūrah al-Mu’minūn; 23:14)
Irúfẹ́ gbólóhùn yìí nìwọ̀nyí: وَأَنتَ خَيْرُ ٱلرَّٰزِقِينَ Ìwọ sì lóore jùlọ nínú àwọn olùpèsè. (sūrah al-Mọ̄’idah; 5:114); وَهُوَ خَيْرُ ٱلْحَٰكِمِينَ Òun l’Ó sì dára jùlọ nínú àwọn olùdájọ́. (sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:87);
وَأَنتَ أَرْحَمُ ٱلرَّٰحِمِينَ Ìwọ sì ni Aláàánú jùlọ nínú àwọn aláàánú. (sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:151); وَهُوَ أَسْرَعُ ٱلْحَٰسِبِينَ Òun sì yára jùlọ nínú àwọn oníṣirò. (sūrah al-’Ani‘ām; 6:62); àti وَٱللَّهُ خَيْرُ ٱلْمَٰكِرِينَ Allāhu sì l’óore jùlọ nínú àwọn adéte. (āl-‘Imrọ̄n; 3:54).
Àwọn gbólóhùn wọ̀nyẹn ń fi rinlẹ̀ pé Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń jẹ́ Ọ̀kan nínú àwọn ẹlẹ́dàá, olùpèsè, olùdájọ́, aláàánú, oníṣirò àti eléte. Kíyè sí i, nínú àwọn iṣẹ́ tí Allāhu máa ń ṣe fún àwọn ẹ̀dá Rẹ̀, àmọ́ tí a tún ń rí àwọn kan nínú àwọn ẹ̀dá Rẹ̀ tí àwọn náà máa ń ṣe wọ́n ni dídá ẹ̀dá, ìpèsè, ẹjọ́ dídá, àánú ṣíṣe, ìṣírò iṣẹ́ àti ète dídá. Ṣùgbọ́n ìkọ̀ọ̀kan àwọn iṣẹ́ náà bùkátà sí àlàyé.
Dídá ẹ̀dá: Ní òdodo ni pé, kò sí ẹ̀dá kan láyé àti lọ́run, ìbáà mọ bíi ọmọ iná igún, àfi kí Allāhu jẹ́ Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Kódà àdámọ́, ẹ̀dá kan nínú ẹ̀dá Allahu ni. Àmọ́ ohun tí a gbà lérò pẹ̀lú fífi dídá ẹ̀dá tì sọ́dọ̀ ẹ̀dá ni ṣíṣe iṣẹ́-ọnà bíi ère gbígbẹ́ àti yíya àwòrán n̄ǹkan ẹlẹ́mìí. Èdè abunikù fún agbẹ́gilére ni “ẹlẹ́dàá”. Tí agbẹ́gilére bá mọ súná burúkú tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fún òun, tí ó sì mọ̀ pé dájúdájú òun kò lè fi ẹ̀mí sára ère rẹ̀ t’ó ń gbẹ́ kalẹ̀, bóyá ó máa mọ̀ ọ́n ní ọ̀ràn. Ìdí nìyí tí hadīth kan fi sọ pé, lára ìyà tí ń bẹ nílẹ̀ ní ọ̀run nínú Iná de agbẹ́gi-lére ni pé, wọ́n máa sọ fún un pé kí ó fi ẹ̀mí sára ère rẹ̀. Kò sì níí lè ṣe bẹ́ẹ̀. Wàyí, wọ́n ń pé agbẹ́gilére ní “ẹlẹ́dàá” nítorí pé, wọ́n ń fi iṣẹ́-ọnà wọn jọ ẹ̀dá tí Allāhu dá. Tí a bá wá lo orúkọ “ẹlẹ́dàá” fún wọn, dípò oníṣẹ́-ọnà, tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì ń jẹ́ Ẹlẹ́dàá, ta ni Ẹlẹ́dàá t’ó dára jùlọ tí ẹ̀dá tirẹ̀ jẹ́ ojúlówó? Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ pé, “Òun ni Ẹni t’ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá.” Pípe “oníṣẹ́-ọnà” ni “ẹlẹ́dàá” kò sì túmọ̀ sí pé ẹ̀dá kan wà t’ó ṣẹ̀dá ara rẹ̀ tàbí pé ẹ̀dá kan wà t’ó ń dá ẹ̀dá mìíràn bí kò ṣe ṣíṣe iṣẹ́-ọnà. Nítorí náà, ìtúmọ̀ àwọn ẹlẹ́dàá nínú āyah yìí ni “àwọn oníṣẹ́-ọnà tàbí àwọn agbẹ́gilére”.
Ìpèsè: Àwọn ẹ̀dá kan gbàgbọ́ pé àwọn òrìṣà kan ń pèsè ìjẹ-ìmu àti owó fún àwọn. Bí àpẹẹrẹ, Yorùbá gbàgbọ́ pé òrìṣà Ajé ń ṣe ìjẹ-ìmu, owó àti okòwò tí wọ́n sọ di “ọrọ̀-Ajé. Àwọn t’ó ń bọ́ ẹlòmíìràn náà ń sọra wọn di olùpèsè. Yàtọ̀ sí pé Allāhu ti fi rinlẹ̀ pé Òun nìkan ni Olùpèsè fún gbogbo ẹ̀dá Rẹ̀. Tí èyí kò bá tí ì dá àwọn kan lójú bẹ́ẹ̀, tí wọ́n sì fẹ́ gbé gbogbo ìpèsè olúkùlùkù lórí ìwọ̀n, ó máa hàn sí wọn kedere pé, ìpèsè ti Allāhu pọ̀ jùlọ, kò sì ṣe é kà. Àti pé nínú ìpèsè Rẹ̀ ni wọ́n ti fún àwọn òrìṣà.
Ẹjọ́ dídá; A kúkú ní àwọn adájọ́ láààrin àwọn ènìyàn, yálà nílé ẹjọ́ tàbí ní àyè mìíràn. Àmọ́ kò sí adájọ́ tí ó jẹ́ arínú-róde. Àti pé ó wà nínú àwọn adájọ́ t’ó ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti fi ẹjọ́ ṣègbè. Allāhu nìkan ṣoṣo ni kì í fí ẹjọ́ ṣègbè. Àti pé ìdájọ́ Rẹ̀ dúró sórí mímọ ìkọ̀kọ̀ àti gban̄gba olùrojọ́. Nítorí náà, ìdí nìyí tí Allāhu fi mọ ẹjọ́ da jùlọ nínú àwọn adájọ́. Ìdájọ́ Rẹ̀ sì ni òpin.
Àánú Ṣíṣe: Ojú àánú àti ọkàn àánú ń bẹ lára àwọn ẹ̀dá kan, tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ tí wọ́n fi ń pè wọ́n ní ẹlẹ́yinjú-àánú. Àmọ́ Allāhu ní àánú ẹ̀dá Rẹ̀ púpọ̀ jùlọ. Àti pé, nínú àánú tí Allāhu fi sí àwọn ẹ̀dá kan lọ́kàn ni wọ́n fi di aláàánú. Nítorí náà, Allāhu ni Aláàánú jùlọ nínú àwọn aláàánú.
Bí àlàyé ṣe máa lọ nìyẹn lórí irú àwọn gbólóhùn bẹ́ẹ̀ nínú al-Ƙur’ān, gẹ́gẹ́ bíi gbólóhùn “Olùyára jùlọ nínú àwọn olùṣírò-iṣẹ́”. Àmọ́ ní ti ète dídá, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
____________________
Ṣé ẹlẹ́dàá mìíràn wà lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni? Ẹ yiri àwọn gbólóhùn wọ̀nyí wò: أَحْسَنَ ٱلْخَٰلِقِينَ Ẹni t’Ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá. (Ó tún wà nínú sūrah al-Mu’minūn; 23:14)
Irúfẹ́ gbólóhùn yìí nìwọ̀nyí: وَأَنتَ خَيْرُ ٱلرَّٰزِقِينَ Ìwọ sì lóore jùlọ nínú àwọn olùpèsè. (sūrah al-Mọ̄’idah; 5:114); وَهُوَ خَيْرُ ٱلْحَٰكِمِينَ Òun l’Ó sì dára jùlọ nínú àwọn olùdájọ́. (sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:87);
وَأَنتَ أَرْحَمُ ٱلرَّٰحِمِينَ Ìwọ sì ni Aláàánú jùlọ nínú àwọn aláàánú. (sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:151); وَهُوَ أَسْرَعُ ٱلْحَٰسِبِينَ Òun sì yára jùlọ nínú àwọn oníṣirò. (sūrah al-’Ani‘ām; 6:62); àti وَٱللَّهُ خَيْرُ ٱلْمَٰكِرِينَ Allāhu sì l’óore jùlọ nínú àwọn adéte. (āl-‘Imrọ̄n; 3:54).
Àwọn gbólóhùn wọ̀nyẹn ń fi rinlẹ̀ pé Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń jẹ́ Ọ̀kan nínú àwọn ẹlẹ́dàá, olùpèsè, olùdájọ́, aláàánú, oníṣirò àti eléte. Kíyè sí i, nínú àwọn iṣẹ́ tí Allāhu máa ń ṣe fún àwọn ẹ̀dá Rẹ̀, àmọ́ tí a tún ń rí àwọn kan nínú àwọn ẹ̀dá Rẹ̀ tí àwọn náà máa ń ṣe wọ́n ni dídá ẹ̀dá, ìpèsè, ẹjọ́ dídá, àánú ṣíṣe, ìṣírò iṣẹ́ àti ète dídá. Ṣùgbọ́n ìkọ̀ọ̀kan àwọn iṣẹ́ náà bùkátà sí àlàyé.
Dídá ẹ̀dá: Ní òdodo ni pé, kò sí ẹ̀dá kan láyé àti lọ́run, ìbáà mọ bíi ọmọ iná igún, àfi kí Allāhu jẹ́ Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Kódà àdámọ́, ẹ̀dá kan nínú ẹ̀dá Allahu ni. Àmọ́ ohun tí a gbà lérò pẹ̀lú fífi dídá ẹ̀dá tì sọ́dọ̀ ẹ̀dá ni ṣíṣe iṣẹ́-ọnà bíi ère gbígbẹ́ àti yíya àwòrán n̄ǹkan ẹlẹ́mìí. Èdè abunikù fún agbẹ́gilére ni “ẹlẹ́dàá”. Tí agbẹ́gilére bá mọ súná burúkú tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fún òun, tí ó sì mọ̀ pé dájúdájú òun kò lè fi ẹ̀mí sára ère rẹ̀ t’ó ń gbẹ́ kalẹ̀, bóyá ó máa mọ̀ ọ́n ní ọ̀ràn. Ìdí nìyí tí hadīth kan fi sọ pé, lára ìyà tí ń bẹ nílẹ̀ ní ọ̀run nínú Iná de agbẹ́gi-lére ni pé, wọ́n máa sọ fún un pé kí ó fi ẹ̀mí sára ère rẹ̀. Kò sì níí lè ṣe bẹ́ẹ̀. Wàyí, wọ́n ń pé agbẹ́gilére ní “ẹlẹ́dàá” nítorí pé, wọ́n ń fi iṣẹ́-ọnà wọn jọ ẹ̀dá tí Allāhu dá. Tí a bá wá lo orúkọ “ẹlẹ́dàá” fún wọn, dípò oníṣẹ́-ọnà, tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì ń jẹ́ Ẹlẹ́dàá, ta ni Ẹlẹ́dàá t’ó dára jùlọ tí ẹ̀dá tirẹ̀ jẹ́ ojúlówó? Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ pé, “Òun ni Ẹni t’ó dára jùlọ nínú àwọn ẹlẹ́dàá.” Pípe “oníṣẹ́-ọnà” ni “ẹlẹ́dàá” kò sì túmọ̀ sí pé ẹ̀dá kan wà t’ó ṣẹ̀dá ara rẹ̀ tàbí pé ẹ̀dá kan wà t’ó ń dá ẹ̀dá mìíràn bí kò ṣe ṣíṣe iṣẹ́-ọnà. Nítorí náà, ìtúmọ̀ àwọn ẹlẹ́dàá nínú āyah yìí ni “àwọn oníṣẹ́-ọnà tàbí àwọn agbẹ́gilére”.
Ìpèsè: Àwọn ẹ̀dá kan gbàgbọ́ pé àwọn òrìṣà kan ń pèsè ìjẹ-ìmu àti owó fún àwọn. Bí àpẹẹrẹ, Yorùbá gbàgbọ́ pé òrìṣà Ajé ń ṣe ìjẹ-ìmu, owó àti okòwò tí wọ́n sọ di “ọrọ̀-Ajé. Àwọn t’ó ń bọ́ ẹlòmíìràn náà ń sọra wọn di olùpèsè. Yàtọ̀ sí pé Allāhu ti fi rinlẹ̀ pé Òun nìkan ni Olùpèsè fún gbogbo ẹ̀dá Rẹ̀. Tí èyí kò bá tí ì dá àwọn kan lójú bẹ́ẹ̀, tí wọ́n sì fẹ́ gbé gbogbo ìpèsè olúkùlùkù lórí ìwọ̀n, ó máa hàn sí wọn kedere pé, ìpèsè ti Allāhu pọ̀ jùlọ, kò sì ṣe é kà. Àti pé nínú ìpèsè Rẹ̀ ni wọ́n ti fún àwọn òrìṣà.
Ẹjọ́ dídá; A kúkú ní àwọn adájọ́ láààrin àwọn ènìyàn, yálà nílé ẹjọ́ tàbí ní àyè mìíràn. Àmọ́ kò sí adájọ́ tí ó jẹ́ arínú-róde. Àti pé ó wà nínú àwọn adájọ́ t’ó ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti fi ẹjọ́ ṣègbè. Allāhu nìkan ṣoṣo ni kì í fí ẹjọ́ ṣègbè. Àti pé ìdájọ́ Rẹ̀ dúró sórí mímọ ìkọ̀kọ̀ àti gban̄gba olùrojọ́. Nítorí náà, ìdí nìyí tí Allāhu fi mọ ẹjọ́ da jùlọ nínú àwọn adájọ́. Ìdájọ́ Rẹ̀ sì ni òpin.
Àánú Ṣíṣe: Ojú àánú àti ọkàn àánú ń bẹ lára àwọn ẹ̀dá kan, tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ tí wọ́n fi ń pè wọ́n ní ẹlẹ́yinjú-àánú. Àmọ́ Allāhu ní àánú ẹ̀dá Rẹ̀ púpọ̀ jùlọ. Àti pé, nínú àánú tí Allāhu fi sí àwọn ẹ̀dá kan lọ́kàn ni wọ́n fi di aláàánú. Nítorí náà, Allāhu ni Aláàánú jùlọ nínú àwọn aláàánú.
Bí àlàyé ṣe máa lọ nìyẹn lórí irú àwọn gbólóhùn bẹ́ẹ̀ nínú al-Ƙur’ān, gẹ́gẹ́ bíi gbólóhùn “Olùyára jùlọ nínú àwọn olùṣírò-iṣẹ́”. Àmọ́ ní ti ète dídá, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
Verse 126
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
(ẹ̀ ń fi) Allāhu (sílẹ̀), Olúwa yín àti Olúwa àwọn bàbá yín, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"
Verse 127
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Wọ́n sì pè é ní òpùrọ́. Nítorí náà, wọ́n máa mú wọn wá sínú Iná.
Verse 128
ﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.
Verse 129
ﭚﭛﭜﭝ
ﭞ
A fún un ní orúkọ rere láààrin àwọn ẹni ìkẹ́yìn.
Verse 130
ﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Àlàáfíà kí ó máa bá (Ànábì) ’Ilyās.
Verse 131
ﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 132
ﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
Dájúdájú ó wà nínú àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 133
ﭮﭯﭰﭱ
ﭲ
Dájúdájú (Ànábì) Lūt wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.
Verse 134
ﭳﭴﭵﭶ
ﭷ
(Ẹ rántí) nígbà tí A gba òun àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀ là.
Verse 135
ﭸﭹﭺﭻ
ﭼ
Àyàfi arúgbóbìnrin kan tí ó wà nínú àwọn t’ó ṣẹ́ kù lẹ́yìn (láààrin àwọn tí A parẹ́).
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah aṣ-Ṣu‘arọ̄’; 26:171.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah aṣ-Ṣu‘arọ̄’; 26:171.
Verse 136
ﭽﭾﭿ
ﮀ
Lẹ́yìn náà, A pa àwọn yòókù run.
Verse 137
ﮁﮂﮃﮄ
ﮅ
Dájúdájú ẹ̀yin náà kúkú ń gba ọ̀dọ̀ wọn kọjá láàárọ̀-láàárọ̀
Verse 138
ﮆﮇﮈﮉ
ﮊ
àti ní alaalẹ́. Ṣé ẹ ò níí ṣe làákàyè ni?
Verse 139
ﮋﮌﮍﮎ
ﮏ
Dájúdájú (Ànábì) Yūnus kúkú wà nínú àwọn Òjíṣẹ́.
Verse 140
ﮐﮑﮒﮓﮔ
ﮕ
(Ẹ rántí) nígbà tí ó sá lọ sínú ọkọ̀ ojú-omi t’ó kún kẹ́kẹ́.
Verse 141
ﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Ó sì bá wọn muje pọ̀. Ó sì wà nínú àwọn tí aje ṣí mọ́ lórí.
____________________
Ìyẹn ni pé, nígbà tí ọkọ̀ ojú-omi takú sórí omi, wọ́n jọ fẹnu kò pé kí àwọn kọ orúkọ àwọn èrò inú ọkọ̀ ojú-omi sí ara fọ́nrán ọ̀pá kọ̀ọ̀kan. Wọ́n sì jọ fẹnu kò pé ẹni tí wọ́n bá yọ fọ́nrán orúkọ rẹ̀ jáde nínú koto fọ́nrán ni wọn yóò jù sínú odò nítorí kí ọkọ t’ó takú lè lágbára láti rìn. Fọ́nrán orúkọ ti Ànábì Yūnus ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni wọ́n rí mú jáde. Wọ́n sì jù ú sínú odò. Ó sì ṣe wẹ́kú ẹnu ẹja.
____________________
Ìyẹn ni pé, nígbà tí ọkọ̀ ojú-omi takú sórí omi, wọ́n jọ fẹnu kò pé kí àwọn kọ orúkọ àwọn èrò inú ọkọ̀ ojú-omi sí ara fọ́nrán ọ̀pá kọ̀ọ̀kan. Wọ́n sì jọ fẹnu kò pé ẹni tí wọ́n bá yọ fọ́nrán orúkọ rẹ̀ jáde nínú koto fọ́nrán ni wọn yóò jù sínú odò nítorí kí ọkọ t’ó takú lè lágbára láti rìn. Fọ́nrán orúkọ ti Ànábì Yūnus ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ni wọ́n rí mú jáde. Wọ́n sì jù ú sínú odò. Ó sì ṣe wẹ́kú ẹnu ẹja.
Verse 142
ﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Nítorí náà, ẹja gbé e mì; ó sì ń dá ara rẹ̀ lẹ́bi.
Verse 143
ﮠﮡﮢﮣﮤ
ﮥ
Nítorí náà, tí kò bá jẹ́ pé ó wà nínú àwọn olùṣàfọ̀mọ́ fún Allāhu,
Verse 144
ﮦﮧﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
dájúdájú ìbá wà nínú ẹja títí di ọjọ́ tí wọn yóò gbé ẹ̀dá dìde.
Verse 145
ﮭﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
Nítorí náà, A jù ú sí orí ilẹ́ gban̄sasa létí omi. Ó sì jẹ́ aláìlera.
Verse 146
ﯔﯕﯖﯗﯘ
ﯙ
A sì mú igi Yẹƙtīn hù jáde láti ṣíji bò ó.
Verse 147
ﯚﯛﯜﯝﯞﯟ
ﯠ
A tún rán an níṣẹ́ sí ọ̀kẹ́ márùn-ún (ènìyàn) tàbí kí wọ́n lékún sí i.
____________________
Ọ̀kẹ́ márùn-ún ni ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún (100,000). Wàyí, àwọn kristiẹni lérò pé Allāhu kò nímọ̀ nípa pàtó òǹkà ìjọ Ànábì Yūnus ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) l’Ó fi mú ọ̀rọ̀ Rẹ̀ wá pẹ̀lú “ ’ao” - “tàbí”. Ọ̀rọ̀ kò sì rí bẹ́ẹ̀ rárá. Nítorí náà, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:74 fún àlàyé lórí rẹ̀.
____________________
Ọ̀kẹ́ márùn-ún ni ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún (100,000). Wàyí, àwọn kristiẹni lérò pé Allāhu kò nímọ̀ nípa pàtó òǹkà ìjọ Ànábì Yūnus ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) l’Ó fi mú ọ̀rọ̀ Rẹ̀ wá pẹ̀lú “ ’ao” - “tàbí”. Ọ̀rọ̀ kò sì rí bẹ́ẹ̀ rárá. Nítorí náà, ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:74 fún àlàyé lórí rẹ̀.
Verse 148
ﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo. A sì fún wọn ní ìgbádùn títí di ìgbà díẹ̀.
Verse 149
ﯦﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Bi wọ́n léèrè wò pé: "Ṣé Olúwa rẹ l’ó ni àwọn ọmọbìnrin, tiwọn sì ni ọmọkùnrin?
Verse 150
ﯬﯭﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Tàbí A dá àwọn mọlāika ní obìnrin, tí àwọn sì jẹ́ ẹlẹ́rìí?"
Verse 151
ﯳﯴﯵﯶﯷ
ﯸ
Gbọ́, nínú irọ́ wọn ni pé dájúdájú wọ́n ń wí pé:
Verse 152
ﯹﯺﯻﯼ
ﯽ
"Allāhu bímọ." Dájúdájú òpùrọ́ ni wọ́n.
Verse 153
ﯾﯿﰀﰁ
ﰂ
Ṣé (Allāhu) ṣẹ̀ṣà àwọn ọmọbìnrin lórí àwọn ọmọkùnrin ni?
Verse 154
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Kí l’ó ń ṣe yín tí ẹ fi ń dájọ́ báyìí?
Verse 155
ﭖﭗ
ﭘ
Ṣé ẹ ò níí lo ìrántí ni?
Verse 156
ﭙﭚﭛﭜ
ﭝ
Tàbí ẹ ní ẹ̀rí t’ó yanjú lọ́wọ́ ni?
Verse 157
ﭞﭟﭠﭡﭢ
ﭣ
Ẹ mú tírà yín wà nígbà náà tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
Verse 158
Wọ́n tún fi ìbátan sáààrin (Allāhu) àti àlùjànnú! Àwọn àlùjànnú sì ti mọ̀ pé dájúdájú wọ́n kúkú máa mú àwọn wá sínú Iná ni.
Verse 159
ﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Mímọ́ ni fún Allāhu tayọ ohun tí wọ́n ń fi ròyìn (Rẹ̀).
Verse 160
ﭵﭶﭷﭸ
ﭹ
Àfi àwọn ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà.
Verse 161
ﭺﭻﭼ
ﭽ
Dájúdájú ẹ̀yin àti n̄ǹkan tí ẹ̀ ń jọ́sìn fún (lẹ́yìn Allāhu),
Verse 162
ﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
ẹ ò lè fi ṣi ẹnì kan kan lọ́nà
Verse 163
ﮃﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
àfi ẹni tí ó bá fẹ́ wọ inú iná Jẹhīm.
Verse 164
ﮉﮊﮋﮌﮍﮎ
ﮏ
Kò sí ẹnì kan nínú àwa (mọlāika) àfi kí ó ní ibùdúró tí wọ́n ti mọ̀.
Verse 165
ﮐﮑﮒ
ﮓ
Dájúdájú àwa, a kúkú wà ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.
Verse 166
ﮔﮕﮖ
ﮗ
Àti pé dájúdájú àwa, àwa kúkú ni olùṣàfọ̀mọ́ (fún Allāhu).
Verse 167
ﮘﮙﮚ
ﮛ
Wọ́n kúkú ń wí pé:
Verse 168
ﮜﮝﮞﮟﮠﮡ
ﮢ
"Tí ó bá jẹ́ pé dájúdájú a bá ní (tírà) ìrántí kan nínú (àwọn tírà) àwọn ẹni àkọ́kọ́,
Verse 169
ﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
dájúdájú àwa ìbá jẹ́ ẹrúsìn Allāhu, àwọn ẹni ẹ̀ṣà."
Verse 170
ﮨﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Ṣùgbọ́n wọ́n ṣàì gbàgbọ́ nínú (Allāhu). Láìpẹ́ wọ́n máa mọ̀.
Verse 171
ﮮﮯﮰﮱﯓ
ﯔ
Dájúdájú ọ̀rọ̀ Wa ti ṣíwájú fún àwọn ẹrúsìn Wa, àwọn Òjíṣẹ́.
Verse 172
ﯕﯖﯗ
ﯘ
Dájúdájú àwọn, àwọn l’a kúkú máa ṣàrànṣe fún.
Verse 173
ﯙﯚﯛﯜ
ﯝ
Àti pé dájúdájú àwọn ọmọ ogun Wa, àwọn kúkú ni olùborí.
Verse 174
ﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
Nítorí náà, ṣẹ́rí kúrò lọ́dọ̀ wọn fún ìgbà díẹ̀.
Verse 175
ﯣﯤﯥ
ﯦ
Àti pé máa wò wọ́n níran ná, àwọn náà ń bọ̀ wá ríran wò.
Verse 176
ﯧﯨ
ﯩ
Ṣé ìyà Wa ni wọ́n ń wá pẹ̀lú ìkánjú?
Verse 177
ﯪﯫﯬﯭﯮﯯ
ﯰ
Nígbà tí ó bá sọ̀kalẹ̀ sí agboolé wọn, òwúrọ̀ ọjọ́ náà yó sì burú fún àwọn ẹni-akìlọ̀-fún.
Verse 178
ﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Kúrò lọ́dọ̀ wọn títí di ìgbà kan ná.
Verse 179
ﯶﯷﯸ
ﯹ
Àti pé máa wò wọ́n níran ná, àwọn náà ń bọ̀ wá ríran wò.
Verse 180
ﯺﯻﯼﯽﯾﯿ
ﰀ
Mímọ́ ni fún Olúwa rẹ, Olúwa agbára, tayọ ohun tí wọ́n ń fi ròyìn (Rẹ̀).
Verse 181
ﰁﰂﰃ
ﰄ
Kí àlàáfíà máa bá àwọn Òjíṣẹ́
Verse 182
ﰅﰆﰇﰈ
ﰉ
Gbogbo ọpẹ́ ń jẹ́ ti Allāhu, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
تقدم القراءة