سورة المرسلات

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura المرسلات ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń sáré ní tẹ̀léǹtẹ̀lé.
Verse 2
Ó búra pẹ̀lú àwọn ìjì atẹ́gùn t’ó ń jà.
Verse 3
Ó búra pẹ̀lú àwọn atẹ́gùn t’ó ń tú èṣújò ká.
Verse 4
Ó búra pẹ̀lú àwọn t’ó ń ṣèpínyà láààrin òdodo àti irọ́.
Verse 5
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń mú ìrántí wá (bá àwọn Òjíṣẹ́).
Verse 6
(Ìrántí náà jẹ́) àwíjàre tàbí ìkìlọ̀.
Verse 7
Dájúdájú ohun tí A ṣe ní àdéhùn fun yín kúkú máa ṣẹlẹ̀.
Verse 8
Nítorí náà, nígbà tí wọ́n bá pa (ìmọ́lẹ̀) ìràwọ̀ rẹ́,
Verse 9
àti nígbà tí wọ́n bá ṣí sánmọ̀ sílẹ̀ gbagada,
Verse 10
àti nígbà tí wọ́n bá ku àwọn àpáta dànù,
Verse 11
àti nígbà tí wọ́n bá fún àwọn Òjíṣẹ́ ní àsìkò láti kójọ, (Àkókò náà ti dé nìyẹn).
Verse 12
Ọjọ́ wo ni wọ́n so (àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí) rọ̀ fún ná?
Verse 13
Fún ọjọ́ ìpínyà (láààrin àwọn ẹ̀dá) ni.
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ìpínyà?
Verse 15
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Verse 16
Ǹjẹ́ Àwa kò ti pa àwọn ẹni àkọ́kọ́ rẹ́ bí?
Verse 17
Lẹ́yìn náà, A sì máa fi àwọn ẹni Ìkẹ́yìn tẹ̀lé wọn (nínú ìparun).
Verse 18
Báyẹn ni A ó ti ṣe pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
Verse 19
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Ṣé A ò ṣẹ̀dá yin láti inú omi lílẹ yẹpẹrẹ bí?
Verse 21
Lẹ́yìn náà, A fi sínú àyè ààbò (ìyẹn, ilé-ọmọ)
Verse 22
títí di gbèdéke àkókò kan tí A ti mọ̀ (ìyen, ọjọ́ ìbímọ).
Verse 23
A sì ní ìkápá àti àyànmọ́ (lórí rẹ̀). (Àwa sì ni) Olùkápá àti Olùpèbùbù ẹ̀dá t’ó dára.
Verse 24
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Verse 25
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ohun t’ó ń kó ẹ̀dá jọ mọ́ra wọn;
Verse 26
(ìyẹn) àwọn alààyè àti àwọn òkú?
A sì fi àwọn àpáta gbagidi gíga-gíga sínú rẹ̀. A sì fun yín ní omi dídùn mu.
Verse 28
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Kì í ṣe ibòji tútù. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ìjòfòfò Iná.
Verse 32
Dájúdájú (Iná náà) yóò máa ju ẹ̀tapàrà (rẹ̀ sókè t’ó máa dà) bí pẹ̀tẹ́ẹ̀sì.
Verse 33
(Ó máa dà) bí àwọn ràkúnmí aláwọ̀ omi ọsàn.
Verse 34
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Verse 35
Èyí ni ọjọ́ tí wọn kò níí sọ̀rọ̀.
Verse 36
A ò sì níí yọ̀ǹda (ọ̀rọ̀ sísọ) fún wọn, áḿbọ̀sìbọ́sí pé wọ́n yóò mú àwáwí wá.
Verse 37
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Èyí ni ọjọ́ ìpínyà. Àwa yó sì kó ẹ̀yin àti àwọn ẹni àkọ́kọ́ jọ.
Verse 40
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù Allāhu yóò wà níbi ibòji àti àwọn omi ìṣẹ́lẹ̀rú,
Verse 42
àti àwọn èso èyí tí wọ́n bá ń fẹ́.
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbádùn nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Verse 44
Dájúdájú báyẹn ni Àwa ṣe ń san àwọn olùṣe-rere ní ẹ̀san (rere).
Verse 45
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Ẹ jẹ, kí ẹ sì gbádùn fún ìgbà díẹ̀. Dájúdájú ẹlẹ́ṣẹ̀ ni yín.
Verse 47
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Nígbà tí wọ́n bá sọ fún wọn pé kí wọ́n kírun, wọn kò níí kírun.
Verse 49
Ègbé ni ní ọjọ́ yẹn fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Verse 50
Nígbà náà, ọ̀rọ̀ wo ni wọn yóò gbàgbọ́ lẹ́yìn rẹ̀?
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-’A‘rọ̄f; 7:185.
تقدم القراءة