Ìtumọ̀ Sura الطور ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮞ
ﮟ
(Allāhu búra pẹ̀lú) àpáta Tūr.
Verse 2
ﮠﮡ
ﮢ
(Ó tún búra pẹ̀lú) Tírà tí wọ́n kọ sílẹ̀
Verse 3
ﮣﮤﮥ
ﮦ
sínú tákàdá tí wọ́n tẹ́ sílẹ̀.
Verse 4
ﮧﮨ
ﮩ
(Ó tún búra pẹ̀lú) Ilé Àbẹ̀wò náà.
Verse 5
ﮪﮫ
ﮬ
(Ó tún búra pẹ̀lú) àjà tí wọ́n gbé sókè (ìyẹn, sánmọ̀).
Verse 6
ﮭﮮ
ﮯ
(Ó tún búra pẹ̀lú) agbami odò iná.
Verse 7
ﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Dájúdájú ìyà Olúwa rẹ máa ṣẹlẹ̀.
Verse 8
ﯖﯗﯘﯙ
ﯚ
Kò sí olùdènà kan fún un.
Verse 9
ﯛﯜﯝﯞ
ﯟ
(Ó máa ṣẹlẹ̀) ní ọjọ́ tí sánmọ̀ máa mì tìtì tààrà.
Verse 10
ﯠﯡﯢ
ﯣ
Àwọn àpáta sì máa rìn lọ tààrà (bí eruku àfẹ́dànù).
Verse 11
ﯤﯥﯦ
ﯧ
Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́,
Verse 12
ﯨﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
àwọn tí wọ́n wà nínú ìsọkúsọ, tí wọ́n ń ṣeré.
Verse 13
ﯮﯯﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
(Rántí) ọjọ́ tí wọn yóò tì wọ́n lọ́ sínú iná Jahanamọ ní ìtìkutì.
Verse 14
ﯵﯶﯷﯸﯹﯺ
ﯻ
Èyí ni Iná náà tí ẹ̀ ń pè nírọ́.
Verse 15
ﭑﭒﭓﭔﭕﭖ
ﭗ
Ṣé idán ni èyí ni tàbí ẹ ò ríran?
Verse 16
Ẹ wọ inú rẹ̀ lọ. Ẹ fara dà á tàbí ẹ ò fara dà á, bákan náà ni fun yín. Ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́ ni A óò fi san yín ní ẹ̀san.
Verse 17
ﭦﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu) máa wà nínú àwọn Ọgbà àti ìdẹ̀ra.
Verse 18
Wọn yóò máa jẹ ìgbádùn pẹ̀lú ohun tí Olúwa wọn fún wọn. Àti pé (Allāhu) yóò ṣọ́ wọn nínú ìyà iná Jẹhīm.
Verse 19
ﭵﭶﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
Ẹ máa jẹ, ẹ máa mu ní gbẹdẹmukẹ nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Verse 20
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí àwọn ibùsùn tí wọ́n tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. A sì máa fún wọn ní àwọn ìyàwó ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́.
Verse 21
Àti pé àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn tún tẹ̀lé wọn nínú ìgbàgbọ́ òdodo, A máa da àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn pọ̀ mọ́ wọn. A ò sì níí dín kiní kan kù nínú iṣẹ́ wọn. Ẹnì kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
Verse 22
ﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
A máa fún wọn ní àlékún èso àti ẹran tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí.
Verse 23
Wọn yó sì máa gba ife ọtí mu láààrin ara wọn nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Kò sí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ àti ìwà ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Verse 24
Àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ wọn yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn. (Wọ́n) dà bí àlúùúlù àfipamọ́.
Verse 25
ﯓﯔﯕﯖﯗ
ﯘ
Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, wọn yó sì máa bèèrè ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ara wọn.
Verse 26
Wọn yóò sọ pé: "Dájúdájú tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀ àwa jẹ́ olùpáyà láààrin àwọn ènìyàn wa.
Verse 27
ﯡﯢﯣﯤﯥﯦ
ﯧ
Ṣùgbọ́n Allāhu ṣàánú wa. Ó sì là wá níbi ìyà Iná.
Verse 28
Dájúdájú àwa máa ń pè É tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀. Dájúdájú Allāhu, Òun ni Olóore, Àṣàkẹ́-ọ̀run."
Verse 29
Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kì í ṣe adábigba tàbí wèrè lórí ìdẹ̀ra Olúwa rẹ.
Verse 30
Tàbí wọ́n ń wí pé: "Eléwì kan tí à ń retí ikú rẹ̀ ni."
Verse 31
ﰄﰅﰆﰇﰈﰉ
ﰊ
Sọ pé: "Ẹ máa retí. Dájúdájú èmi náà wà pẹ̀lú yín nínú àwọn olùretí.
Verse 32
Tàbí ọpọlọ wọn ń pa wọ́n láṣẹ èyí ni? Tàbí ìjọ alákọyọ ni wọ́n ni?
Verse 33
Tàbí wọ́n ń wí pé: "Ó dá (al-Ƙur’ān) hun fúnra rẹ̀ ni." Rárá o, wọn kò gbàgbọ́ ni.
Verse 34
ﭣﭤﭥﭦﭧﭨ
ﭩ
Kí àwọn náà mú ọ̀rọ̀ kan bí irú rẹ̀ wá tí wọ́n bá jẹ́ olódodo.
Verse 35
Tàbí wọ́n ṣẹ̀dá wọn láì sí Aṣẹ̀dá? Tàbí àwọn ni wọ́n ṣẹ̀dá ara wọn ni?
Verse 36
Tàbí àwọn ni wọ́n ṣẹ̀dá àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀? Rárá o, wọn kò màmọ̀ dájú ni.
Verse 37
Tàbí lọ́dọ̀ wọn ni àwọn àpótí ọrọ̀ Olúwa rẹ wà? Tàbí àwọn ni olùborí?
Verse 38
Tàbí wọ́n ní àkàbà tí wọ́n ń fi gbọ́rọ̀ (nínú sánmọ̀ ni)? Kí olùgbọ́rọ̀ wọn mú ẹ̀rí pọ́nńbélé wá?
Verse 39
ﮏﮐﮑﮒﮓ
ﮔ
Tàbí àwọn ọmọbìnrin ni tiRẹ̀, àwọn ọmọkùnrin sì ni tiyín?
Verse 40
Tàbí ò ń bèèrè owó-ọ̀yà kan lọ́dọ̀ wọn, ni gbèsè fi wọ̀ wọ́n lọ́rùn?
Verse 41
ﮝﮞﮟﮠﮡ
ﮢ
Tàbí ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ wà lọ́dọ̀ wọn, tí wọ́n sì ń kọ ọ́ sílẹ̀?
Verse 42
Tàbí wọ́n ń gbèrò ète kan ni? Nígbà náà, àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, àwọn l’ó máa f’orí kó ète.
Verse 43
Tàbí wọ́n ní ọlọ́hun kan lẹ́yìn Allāhu ni? Mímọ́ ni fún Allāhu tayọ n̄ǹkan tí wọ́n ń fi ṣẹbọ sí I.
Verse 44
Tí wọ́n bá sì rí apá kan nínú sánmọ̀ t’ó ya lúlẹ̀, wọ́n á wí pé: "Ẹ̀ṣújò rẹgẹdẹ ni (wọn kò níí gbàgbọ́)."
Verse 45
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ títí wọn yóò fi bá ọjọ́ wọn tí wọn máa pa wọ́n sínú rẹ̀ pàdé.
Verse 46
Ọjọ́ tí ète wọn kò níí fi kiní kan rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀. A ò sì níí ràn wọ́n lọ́wọ́.
Verse 47
Àti pé dájúdájú ìyà kan ń bẹ fún àwọn t’ó ṣàbòsí yàtọ̀ sí (ìyà ọ̀run) yẹn, ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn ni kò mọ̀.
Verse 48
Ṣe sùúrù fún ìdájọ́ Olúwa Rẹ, dájúdájú ìwọ wà ní ojútó Wa. Kí ó sì ṣe àfọ̀mọ́ pẹ̀lú ìdúpẹ́ fún Olúwa rẹ nígbà tí ó bá ń dìde nàró (fún ìrun kíkí).
Verse 49
ﰋﰌﰍﰎﰏ
ﰐ
Àti ní alẹ́ (nígbà tí) àwọn ìràwọ̀ bá kúrò níta tán, ṣàfọ̀mọ́ fún Un.
تقدم القراءة