Ìtumọ̀ Sura الإنفطار ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Nígbà tí sánmọ̀ bá fà ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
Verse 2
ﭕﭖﭗ
ﭘ
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
Verse 3
ﭙﭚﭛ
ﭜ
àti nígbà tí àwọn ibúdò bá ṣàn jára wọn,
Verse 4
ﭝﭞﭟ
ﭠ
àti (nígbà tí A bá ta ilẹ̀ sókè), tí A sì mú àwọn òkú jáde (láàyè) láti inú àwọn sàréè,
Verse 5
ﭡﭢﭣﭤﭥ
ﭦ
(nígbà náà ni) ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan yóò mọ ohun tí ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tí ó fi sẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Verse 6
ﭧﭨﭩﭪﭫﭬ
ﭭ
Ìwọ ènìyàn, kí ni ó tàn ọ́ jẹ nípa Olúwa rẹ, Alápọ̀n-ọ́nlé,
Verse 7
ﭮﭯﭰﭱ
ﭲ
Ẹni t’Ó ṣẹ̀dá rẹ? Ó ṣẹ̀dá rẹ̀ ní pípé. Ó sì mú ọ dọ́gba jalẹ̀ léèyàn.
Verse 8
ﭳﭴﭵﭶﭷﭸ
ﭹ
Ó to ẹ̀yà ara rẹ papọ̀ sínú èyíkéyìí àwòrán tí Ó fẹ́.
Verse 9
ﭺﭻﭼﭽ
ﭾ
Ní ti òdodo, ńṣe l’ẹ̀ ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́.
Verse 10
ﭿﮀﮁ
ﮂ
Dájúdájú àwọn ẹ̀ṣọ́ sì wà ní ọ̀dọ̀ yín.
Verse 11
ﮃﮄ
ﮅ
(Wọ́n jẹ́) alápọ̀n-ọ́nlé, òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá.
Verse 12
ﮆﮇﮈ
ﮉ
Wọ́n mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Verse 13
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Dájúdájú àwọn ẹni rere yóò kúkú wà nínú ìgbádùn.
Verse 14
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Dájúdájú àwọn ẹni ibi yó sì kúkú wà nínú iná Jẹhīm.
Verse 15
ﮔﮕﮖ
ﮗ
Wọn yóò wọ inú rẹ̀ ní Ọjọ́ ẹ̀san.
Verse 16
ﮘﮙﮚﮛ
ﮜ
Wọn kò sì níí kúrò nínú rẹ̀.
Verse 17
ﮝﮞﮟﮠﮡ
ﮢ
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
Verse 18
ﮣﮤﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Lẹ́yìn náà, kí ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
Verse 19
(Ọjọ́ ẹ̀san ni) ọjọ́ tí ẹ̀mí kan kò níí kápá kiní kan fún ẹ̀mí kan. Gbogbo àṣẹ ọjọ́ yẹn sì ń jẹ́ ti Allāhu.
تقدم القراءة