Ìtumọ̀ Sura الفجر ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭤ
ﭥ
Allāhu búra pẹ̀lú àfẹ̀mọ́júmọ́.
Verse 2
ﭦﭧ
ﭨ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn òru mẹ́wàá kan.
Verse 3
ﭩﭪ
ﭫ
Ó tún búra pẹ̀lú méjì àti ẹyọ.
Verse 4
ﭬﭭﭮ
ﭯ
Ó tún búra pẹ̀lú òru nígbà tí ó bá lọ (tí ó bá dé).
Verse 5
ﭰﭱﭲﭳﭴﭵ
ﭶ
Ǹjẹ́ ìbúra wà nínú ìyẹn fún onílàákàyè?
Verse 6
ﭷﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
Ṣé o ò rí bí Olúwa rẹ ti ṣe ọ̀rọ̀ ará ‘Ād,
Verse 7
ﭾﭿﮀ
ﮁ
(ìyẹn àwọn ìran) ’Irọm, àwọn òmìrán,
Verse 8
ﮂﮃﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
àwọn tí A ò dá irú wọn mọ́ sínú ìlú?
Verse 9
ﮉﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Àti àwọn Thamūd tí wọ́n gbẹ́ (ilé ìgbé) sínú àpáta nínú àfonífojì,
Verse 10
ﮏﮐﮑ
ﮒ
àti Fir‘aon eléèkàn (ìyà)?
Verse 11
ﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
(Àwọn wọ̀nyí ni) àwọn t’ó tayọ ẹnu-àlà nínú ìlú.
Verse 12
ﮘﮙﮚ
ﮛ
Wọ́n sì ṣe ìbàjẹ́ púpọ̀ sínú rẹ̀.
Verse 13
ﮜﮝﮞﮟﮠ
ﮡ
Olúwa rẹ sì rọ̀jò ìyà lé wọn lórí.
Verse 14
ﮢﮣﮤ
ﮥ
Dájúdájú Olúwa rẹ wà ní ibùṣọ́ (iṣẹ́ ẹ̀dá).
Verse 15
Nítorí náà, ní ti ènìyàn, nígbà tí Olúwa rẹ̀ bá dán an wò, tí Ó pọ́n ọn lé, tí Ó sì ṣe ìdẹ̀ra fún un, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti pọ́n mi lé."
Verse 16
Ṣùgbọ́n nígbà tí Ó bá dán an wò, tí Ó gán arísìkí rẹ̀ lé e lọ́wọ́, nígbà náà ó máa wí pé: "Olúwa mi ti yẹpẹrẹ mi."
Verse 17
ﯞﯟﯠﯡﯢﯣ
ﯤ
Rárá, kò rí bẹ́ẹ̀. Àmọ́, ẹ̀yin kò ṣàpọ́nlé ọmọ-òrukàn.
Verse 18
ﯥﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Àti pé ẹ̀yin kò gbẹra yín lóǹgbẹ láti fún mẹ̀kúnnù ní oúnjẹ.
Verse 19
ﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Ẹ tún ń jẹ ogún ní ìjẹkújẹ.
Verse 20
ﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Àti pé ẹ nífẹ̀ẹ́ sí dúkìá ní ìfẹ́ púpọ̀.
Verse 21
Rárá, (kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀). Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímì tìtì (t’ó rún wómúwómú, tí kò sí kòtò, tí kò sí gelemọ),
Verse 22
ﯽﯾﯿﰀﰁ
ﰂ
(tí) Olúwa rẹ dé pẹ̀lú àwọn mọlāika ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ọ̀wọ̀ọ̀wọ́,
Verse 23
ní ọjọ́ yẹn ni wọ́n máa mú iná Jahanamọ wá. Ní ọjọ́ yẹn, ènìyàn yóò rántí (ọ̀rọ̀ ara rẹ̀). Báwo sì ni ìrántí náà ṣe lè wúlò fún un!
Verse 24
ﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Ó máa wí pé: "Yéè, èmi ìbá ti ti (iṣẹ́ rere) síwájú fún ìṣẹ̀mí mi."
Verse 25
ﭡﭢﭣﭤﭥ
ﭦ
Ní ọjọ́ yẹn, ẹnì kan kò lè fi ìyà jẹ (ẹ̀dá) bí irú ìyà (tí) Allāhu (yóò fi jẹ ẹ́).
Verse 26
ﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Ẹnì kan kò sì lè de (ẹ̀dá) ní ìgbèkùn bí irú ìgbèkùn (tí) Allāhu (yóò fi dè é).
Verse 27
ﭬﭭﭮ
ﭯ
Ìwọ ẹ̀mí olùfọ̀kànbalẹ̀,
Verse 28
ﭰﭱﭲﭳﭴ
ﭵ
padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ní olùyọ́nú, ẹni ìyọ́nú.
Verse 29
ﭶﭷﭸ
ﭹ
Nítorí náà, wọlé sáààrin àwọn ẹrúsìn Mi.
Verse 30
ﭺﭻ
ﭼ
Wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra Mi.
تقدم القراءة