Ìtumọ̀ Sura الواقعة ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮃﮄﮅ
ﮆ
Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
Verse 2
ﮇﮈﮉ
ﮊ
- kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-E4983
Verse 3
ﮋﮌ
ﮍ
ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).
Verse 4
ﮎﮏﮐﮑ
ﮒ
Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,
Verse 5
ﮓﮔﮕ
ﮖ
àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,
Verse 6
ﮗﮘﮙ
ﮚ
- wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù - E4987
Verse 7
ﮛﮜﮝ
ﮞ
ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.
____________________
Àwọn kristiẹni lérò pé āyah t’ó pín ẹ̀dá sí mẹ́ta ní ọjọ́ Àjíǹde tako āyah t’ó pín wọn sí ìjọ méjì.
Èsì: Kò sí ìtakora láààrin wọn. Nínú sūrah yìí, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ pé oríṣi ìjọ mẹ́ta ni àwọn ẹ̀dá máa pín sí ní ọjọ́ Àjíǹde. Ìjọ ọ̀tún, ìjọ òsì àti ìjọ aṣíwájú. Àmọ́ nínú sūrah al-Balad; 90:18-19 àti sūrah az-Zalzalah; 99:6-8, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pín wọn sí ìjọ méjì. Ìjọ méjì kúkú ni gbogbo ẹ̀dá ní ọ̀run, ìjọ ọ̀tún àti ìjọ òsì nítorí pé, Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ nípa ìgbádùn ìjọ aṣíwájú láti āyah 10 sí āyah 26. Ó sọ nípa ìgbádùn ìjọ ọ̀tún láti āyah 27 sí āyah 40. Ó sì sọ nípa oníran-ànran ìyà ìjọ òsì láti āyah 41 sí āyah 56.
____________________
Àwọn kristiẹni lérò pé āyah t’ó pín ẹ̀dá sí mẹ́ta ní ọjọ́ Àjíǹde tako āyah t’ó pín wọn sí ìjọ méjì.
Èsì: Kò sí ìtakora láààrin wọn. Nínú sūrah yìí, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ pé oríṣi ìjọ mẹ́ta ni àwọn ẹ̀dá máa pín sí ní ọjọ́ Àjíǹde. Ìjọ ọ̀tún, ìjọ òsì àti ìjọ aṣíwájú. Àmọ́ nínú sūrah al-Balad; 90:18-19 àti sūrah az-Zalzalah; 99:6-8, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pín wọn sí ìjọ méjì. Ìjọ méjì kúkú ni gbogbo ẹ̀dá ní ọ̀run, ìjọ ọ̀tún àti ìjọ òsì nítorí pé, Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ nípa ìgbádùn ìjọ aṣíwájú láti āyah 10 sí āyah 26. Ó sọ nípa ìgbádùn ìjọ ọ̀tún láti āyah 27 sí āyah 40. Ó sì sọ nípa oníran-ànran ìyà ìjọ òsì láti āyah 41 sí āyah 56.
Verse 8
ﮟﮠﮡﮢﮣ
ﮤ
Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?
Verse 9
ﮥﮦﮧﮨﮩ
ﮪ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
Verse 10
ﮫﮬ
ﮭ
Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.
Verse 11
ﮮﮯ
ﮰ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)
Verse 12
ﮱﯓﯔ
ﯕ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Verse 13
ﯖﯗﯘ
ﯙ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
Verse 14
ﯚﯛﯜ
ﯝ
Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
Verse 15
ﯞﯟﯠ
ﯡ
(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.
Verse 16
ﯢﯣﯤ
ﯥ
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.
Verse 17
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn
Verse 18
ﭖﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn.
Verse 19
ﭜﭝﭞﭟﭠ
ﭡ
Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.
Verse 20
ﭢﭣﭤ
ﭥ
Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).
Verse 21
ﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).
Verse 22
ﭫﭬ
ﭭ
Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).
Verse 23
ﭮﭯﭰ
ﭱ
Wọ́n dà bí òkúta olówó-iyebíye tí wọ́n fi pamọ́.
Verse 24
ﭲﭳﭴﭵ
ﭶ
(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
Verse 25
ﭷﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Verse 26
ﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.
Verse 27
ﮃﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?
Verse 28
ﮉﮊﮋ
ﮌ
(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,
Verse 29
ﮍﮎ
ﮏ
àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ t’ó so jìgbìnnì,
Verse 30
ﮐﮑ
ﮒ
àti ibòji t’ó gbòòrò,
Verse 31
ﮓﮔ
ﮕ
àti omi t’ó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,
Verse 32
ﮖﮗ
ﮘ
àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,
Verse 33
ﮙﮚﮛﮜ
ﮝ
tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).
Verse 34
ﮞﮟ
ﮠ
(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.
Verse 35
ﮡﮢﮣ
ﮤ
Dájúdájú Àwa tún (àwọn obìnrin wọn) dá ní ẹ̀dá ọ̀tun.
Verse 36
ﮥﮦ
ﮧ
A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,
Verse 37
ﮨﮩ
ﮪ
olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.
Verse 38
ﮫﮬ
ﮭ
(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Verse 39
ﮮﮯﮰ
ﮱ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
Verse 40
ﯓﯔﯕ
ﯖ
Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
____________________
Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā (aleehim sọlātu wa salām). Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan (sollalāhu 'alayhi wa sallam).
____________________
Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā (aleehim sọlātu wa salām). Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan (sollalāhu 'alayhi wa sallam).
Verse 41
ﯗﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
Verse 42
ﯝﯞﯟ
ﯠ
(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná àti omi gbígbóná,
Verse 43
ﯡﯢﯣ
ﯤ
àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,
Verse 44
ﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
kò tutù, kò sì dára.
Verse 45
ﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.
Verse 46
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
Verse 47
Wọ́n sì máa ń wí pé: "Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
Verse 48
ﰀﰁ
ﰂ
Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"
Verse 49
ﰃﰄﰅﰆ
ﰇ
Sọ pé: "Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,
Verse 50
ﰈﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀."
Verse 51
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,
Verse 52
ﭗﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).
Verse 53
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.
Verse 54
ﭡﭢﭣﭤ
ﭥ
Ẹ̀yin yó sì máa mu omi gbígbóná lé e lórí.
Verse 55
ﭦﭧﭨ
ﭩ
Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.
Verse 56
ﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.
Verse 57
ﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ lódodo!
Verse 58
ﭴﭵﭶ
ﭷ
Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),
Verse 59
ﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?
Verse 60
Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Àwa kò sì lè kágara
Verse 61
láti fi irú yín pààrọ̀ yín, kí á sì tun yín dá sínú ohun tí ẹ kò mọ̀.
Verse 62
ﮐﮑﮒﮓﮔﮕ
ﮖ
Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́, ẹ ò ṣe lo ìrántí?
Verse 63
ﮗﮘﮙ
ﮚ
Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,
Verse 64
ﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde ni tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?
Verse 65
ﮡﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).
Verse 66
ﮨﮩ
ﮪ
(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) "Dájúdájú àwa ti di onígbèsè."
Verse 67
ﮫﮬﮭ
ﮮ
(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) "Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni."
Verse 68
ﮯﮰﮱﯓ
ﯔ
Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,
Verse 69
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?
Verse 70
ﯝﯞﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi t’ó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?
Verse 71
ﯤﯥﯦﯧ
ﯨ
Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,
Verse 72
ﯩﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?
Verse 73
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.
Verse 74
ﯶﯷﯸﯹ
ﯺ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
Verse 75
ﯻﯼﯽﯾﯿ
ﰀ
Mò ń búra pẹ̀lú àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀.
Verse 76
ﰁﰂﰃﰄﰅ
ﰆ
Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.
Verse 77
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé,
Verse 78
ﭕﭖﭗ
ﭘ
(t’ó wà) nínú Tírà ààbò (nínú Laohul-Mahfūṭḥ).
Verse 79
ﭙﭚﭛﭜ
ﭝ
Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).
Verse 80
ﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Wọ́n sọ̀ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
Verse 81
ﭣﭤﭥﭦ
ﭧ
Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè nírọ́?
Verse 82
ﭨﭩﭪﭫ
ﭬ
Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo nírọ́.
____________________
Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Irọ́ ni èyí àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu (subhānahu wa ta'ālā), Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Irọ́ ni èyí àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu (subhānahu wa ta'ālā), Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
Verse 83
ﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
Kí ni ó máa ti rí (fun yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,
Verse 84
ﭲﭳﭴ
ﭵ
tí ẹ̀yin yó sì máa wòran nígbà yẹn?
Verse 85
Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mujādilah; 58:7.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mujādilah; 58:7.
Verse 86
ﭾﭿﮀﮁﮂ
ﮃ
Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,
Verse 87
ﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
Verse 88
ﮉﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),
Verse 89
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
ìsinmi, èsè t’ó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).
Verse 90
ﮔﮕﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,
Verse 91
ﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Verse 92
ﮡﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,
Verse 93
ﮨﮩﮪ
ﮫ
n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi gbígbóná
Verse 94
ﮬﮭ
ﮮ
àti wíwọ inú iná Jẹhīm.
Verse 95
ﮯﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo t’ó dájú.
Verse 96
ﯖﯗﯘﯙ
ﯚ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
تقدم القراءة