Ìtumọ̀ Sura القلم ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮉﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Nūn. (Allāhu búra pẹ̀lú) gègé ìkọ̀wé àti ohun tí àwọn mọlāika ń kọ sílẹ̀.
Verse 2
ﮏﮐﮑﮒﮓ
ﮔ
Ìwọ kì í ṣe wèrè nípa ìdẹ̀ra Olúwa rẹ.
Verse 3
ﮕﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Àti pé dájúdájú ẹ̀san tí kò níí dáwọ́ dúró ti wà fún ọ.
Verse 4
ﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Dájúdájú ìwọ sì wà lórí ìwà àpọ́nlé.
Verse 5
ﮠﮡ
ﮢ
Láìpẹ́ ìwọ yóò rí i, àwọn náà yó sì rí i;
Verse 6
ﮣﮤ
ﮥ
èwo nínú yín ni wèrè?
Verse 7
Dájúdájú Olúwa rẹ, Ó nímọ̀ jùlọ nípa ẹni t’ó ṣìnà kúrò lójú ọ̀nà Rẹ̀. Ó sì nímọ̀ jùlọ nípa àwọn olùmọ̀nà.
Verse 8
ﯓﯔﯕ
ﯖ
Nítorí náà, má ṣe tẹ̀lé àwọn olùpe-òdodo-nírọ́.
Verse 9
ﯗﯘﯙﯚ
ﯛ
Àti pé wọ́n fẹ́ kí o dẹwọ́, kí àwọn náà sì dẹwọ́.
Verse 10
ﯜﯝﯞﯟﯠ
ﯡ
Má ṣe tẹ̀lé gbogbo ẹni tí ìbúra rẹ̀ pọ̀, ẹni yẹpẹrẹ,
Verse 11
ﯢﯣﯤ
ﯥ
abúni, alárìnká t’ó ń sòfófó kiri,
Verse 12
ﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
olùdènà iṣẹ́ rere, alákọyọ, ẹlẹ́ṣẹ̀,
Verse 13
ﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
ọ̀dájú. Lẹ́yìn ìyẹn, àsáwọ̀ ni.
____________________
Ìyẹn ni pé, kì í ṣe ojúlówó ọmọ ìran Ƙuraeṣ; àsọdọmọ ni. Ẹni náà ni Walīd ọmọ Mugīrah, ẹni tí ó wà ní ọmọ ọdún méjìdínlógún nígbà tí Mugīrah sọ ọ́ di ọmọ rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, kì í ṣe ojúlówó ọmọ ìran Ƙuraeṣ; àsọdọmọ ni. Ẹni náà ni Walīd ọmọ Mugīrah, ẹni tí ó wà ní ọmọ ọdún méjìdínlógún nígbà tí Mugīrah sọ ọ́ di ọmọ rẹ̀.
Verse 14
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Nítorí pé ó ní dúkìá àti àwọn ọmọkùnrin,
Verse 15
nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa fún un, ó máa wí pé: “Àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́ (nìwọ̀nyí)”.
Verse 16
ﯾﯿﰀ
ﰁ
A máa fi àmì sí i ní góńgórí imú.
Verse 17
Dájúdájú Àwa dán wọn wò gẹ́gẹ́ bí A ṣe dán àwọn ọlọ́gbà wò nígbà tí wọ́n búra pé dájúdájú àwọn yóò ká gbogbo èso ọgbà náà ní òwúrọ̀ kùtùkùtù.
Verse 18
ﭜﭝ
ﭞ
Wọn kò sì ṣe àyàfi pé "tí Allāhu bá fẹ́".
Verse 19
Àdánwò t’ó ń yí n̄ǹkan po láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì yí ọgbà náà po, nígbà tí wọ́n sùn lọ.
Verse 20
ﭧﭨ
ﭩ
Ó sì dà bí oko àgédànù (tí wọ́n ti résun).
Verse 21
ﭪﭫ
ﭬ
Wọ́n ń pera wọn ní òwúrọ̀ kùtùkùtù
Verse 22
pé ẹ jí lọ sí oko yín tí ẹ bá fẹ́ ká èso.
Verse 23
ﭵﭶﭷ
ﭸ
Wọ́n lọ, wọ́n sì ń fi ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ bára wọn sọ̀rọ̀
Verse 24
ﭹﭺﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
pé ní òní mẹ̀kúnnù kan kò gbọdọ̀ wọnú rẹ̀ wá ba yín.
Verse 25
ﮀﮁﮂﮃ
ﮄ
Wọ́n jí lọ lórí èrò-ọkàn kan (pé) àwọn lágbára.
Verse 26
ﮅﮆﮇﮈﮉ
ﮊ
Nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n wí pé: "Dájúdájú àwa ti ṣìnà.
Verse 27
ﮋﮌﮍ
ﮎ
Rárá o, wọ́n ṣe ìkórè oko léèwọ̀ fún wa ni."
Verse 28
Ẹni t’ó dúró déédé jùlọ nínú wọn sọ pé: "Ṣé èmi kò sọ fun yín pé ẹ̀yin kò ṣe ṣàfọ̀mọ́ fún Allāhu (pé "a máa kórè oko wa, ’in ṣā ’Allāhu.)"?
Verse 29
ﮗﮘﮙﮚﮛﮜ
ﮝ
Wọ́n wí pé: "Mímọ́ ni fún Olúwa wa, dájúdájú àwa jẹ́ alábòsí."
Verse 30
ﮞﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Apá kan wọn kọjú sí apá kan; wọ́n sì ń dára wọn lẹ́bi.
Verse 31
ﮤﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Wọ́n wí pé: "Ègbé wa ò! Dájúdájú àwa jẹ́ olùtayọ-ẹnu àlà.
Verse 32
Ó ṣeé ṣe kí Olúwa wa fi èyí t’ó dára ju èyí lọ pààrọ̀ rẹ̀ fún wa. Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa wa ni àwa ń rokàn oore sí."
Verse 33
Báyẹn ni ìyà náà ṣe rí (fún wọn). Ìyà ọ̀run sì tóbi jùlọ, tí ó bá jẹ́ pé wọ́n mọ̀.
Verse 34
ﯡﯢﯣﯤﯥﯦ
ﯧ
Dájúdájú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún àwọn olùbẹ̀rù lọ́dọ̀ Olúwa wọn.
Verse 35
ﯨﯩﯪ
ﯫ
Ṣé A máa ṣe àwọn mùsùlùmí bí (A ṣe máa ṣe) àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bí?
Verse 36
ﯬﯭﯮﯯ
ﯰ
Kí l’ó ń ṣe yín tí ẹ fi ń dájọ́ báyìí ná?
____________________
Ìyẹn ni pé, ẹni tí ó bá lérò pé ìkẹ́ máa wà fún òun ní ọ̀run láì jẹ́ pé ó kú sínú ẹ̀sìn ’Islām, ó ti gbé ìdájọ́ gbági.
____________________
Ìyẹn ni pé, ẹni tí ó bá lérò pé ìkẹ́ máa wà fún òun ní ọ̀run láì jẹ́ pé ó kú sínú ẹ̀sìn ’Islām, ó ti gbé ìdájọ́ gbági.
Verse 37
ﯱﯲﯳﯴﯵ
ﯶ
Tàbí tírà kan wà fun yín tí ẹ̀ ń kẹ́kọ̀ọ́ nínú rẹ̀
Verse 38
ﯷﯸﯹﯺﯻ
ﯼ
pé dájúdájú ẹ̀yin lẹ ni ohun tí ẹ bá ń ṣà lẹ́ṣà nínú ìdájọ́?
Verse 39
Ǹjẹ́ ẹ ni àwọn àdéhùn kan lọ́dọ̀ wa tí ó máa wà títí di Ọjọ́ Àjíǹde pé: "Dájúdájú tiyín ni ìdájọ́ tí ẹ bá ti mú wá."?
Verse 40
ﰊﰋﰌﰍ
ﰎ
Bi wọ́n léèrè wò pé èwo nínú wọn l’ó lè fọwọ́ ìyẹn sọ̀yà!
Verse 41
Tàbí wọ́n ní àwọn òrìṣà kan? Kí wọ́n mú àwọn òrìṣà wọn wá nígbà náà tí wọ́n bá jẹ́ olódodo.
Verse 42
Ní ọjọ́ tí A máa ṣí ojúgun sílẹ̀, A sì máa pè wọ́n síbi ìforíkanlẹ̀, wọn kò sì níí lè ṣe é.
Verse 43
Ojú wọn yóò wálẹ̀. Ìyẹpẹrẹ máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n kúkú ti pè wọ́n síbi ìforíkanlẹ̀ nígbà tí wọ́n ní àlàáfíà (wọn kò sì kírun).
Verse 44
Nítorí náà, fi Èmi àti ẹni t’ó ń pe ọ̀rọ̀ yìí nírọ́ sílẹ̀. A óò máa dẹ wọ́n lẹ́kẹ láti jẹ wọ́n níyà ní àyè tí wọn kò mọ̀.
Verse 45
ﭪﭫﭬﭭﭮﭯ
ﭰ
Mò ń lọ́ra fún wọn ni. Dájúdájú ète Mi lágbára.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
Verse 46
Tàbí ò ń bèèrè owó-ọ̀yà kan lọ́dọ̀ wọn, ni gbèsè fi wọ̀ wọ́n lọ́rùn?
Verse 47
ﭹﭺﭻﭼﭽ
ﭾ
Tàbí lọ́dọ̀ wọn ni (wàláà) ìkọ̀kọ̀ wà ni wọ́n bá ń kọ ọ́ (síta)?
Verse 48
Nítorí náà, ṣe sùúrù fún ìdájọ́ Olúwa rẹ. Kí ìwọ má sì ṣe dà bí ẹlẹ́ja (ìyẹn, Ànábì Yūnus) nígbà tí ó pe (Allāhu) pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Verse 49
Tí kò bá jẹ́ pé ìkẹ́ kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ lé e bá, wọn ìbá jù ú sórí ilẹ̀ gban̄sasa (láti inú ẹja) ní ẹni-èébú.
Verse 50
ﮖﮗﮘﮙﮚ
ﮛ
Nítorí náà, Olúwa rẹ̀ ṣà á lẹ́ṣà. Ó sì ṣe é ní ara àwọn ẹni rere.
Verse 51
Àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ fẹ́ẹ̀ fi ojú wọn gbé ọ ṣubú nígbà tí wọ́n gbọ́ ìrántí náà. Wọ́n sì ń wí pé: "Dájúdájú wèrè mà ni."
Verse 52
ﮩﮪﮫﮬﮭ
ﮮ
Kí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.
تقدم القراءة