Ìtumọ̀ Sura المدّثر ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮪﮫ
ﮬ
Ìwọ olùdaṣọbora.
Verse 2
ﮭﮮ
ﮯ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
Verse 3
ﮰﮱ
ﯓ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
Verse 4
ﯔﯕ
ﯖ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
Verse 5
ﯗﯘ
ﯙ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
Verse 6
ﯚﯛﯜ
ﯝ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
Verse 7
ﯞﯟ
ﯠ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
Verse 8
ﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
Verse 9
ﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
Verse 10
ﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
Verse 11
ﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan.
Verse 12
ﯵﯶﯷﯸ
ﯹ
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
Verse 13
ﯺﯻ
ﯼ
àti àwọn ọmọkúnrin t’ó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
Verse 14
ﯽﯾﯿ
ﰀ
Mo sì ṣe ayé nírọ̀rùn fún un gan-an.
Verse 15
ﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
Verse 16
ﰆﰇﰈﰉﰊﰋ
ﰌ
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
Verse 17
ﰍﰎ
ﰏ
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná).
____________________
Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
____________________
Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
Verse 18
ﰐﰑﰒ
ﰓ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
Verse 19
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
Verse 20
ﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
Verse 21
ﭚﭛ
ﭜ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
Verse 22
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
Verse 23
ﭡﭢﭣ
ﭤ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìn dà, ó sì ṣègbéraga.
Verse 24
ﭥﭦﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Ó sì wí pé: "Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
Verse 25
ﭬﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara"
Verse 26
ﭲﭳ
ﭴ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
Verse 27
ﭵﭶﭷﭸ
ﭹ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ iná Saƙọr?
Verse 28
ﭺﭻﭼﭽ
ﭾ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.
____________________
Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
Verse 29
ﭿﮀ
ﮁ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
Verse 30
ﮂﮃﮄ
ﮅ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: "Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?" Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ̀ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
Verse 32
ﯥﯦ
ﯧ
Ẹ gbọ́! Allāhu búra pẹ̀lú òṣùpá.
Verse 33
ﯨﯩﯪ
ﯫ
Ó tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.
Verse 34
ﯬﯭﯮ
ﯯ
Ó tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́.
Verse 35
ﯰﯱﯲ
ﯳ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) t’ó tóbi.
Verse 36
ﯴﯵ
ﯶ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
Verse 37
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn.
Verse 38
ﯿﰀﰁﰂﰃ
ﰄ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
Verse 39
ﰅﰆﰇ
ﰈ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
Verse 40
ﰉﰊﰋ
ﰌ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
Verse 41
ﰍﰎ
ﰏ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
Verse 42
ﰐﰑﰒﰓ
ﰔ
"Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?"
Verse 43
ﰕﰖﰗﰘﰙ
ﰚ
Wọn yóò wí pé: "Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
Verse 44
ﰛﰜﰝﰞ
ﰟ
Àwa kò sì sí nínú àwọn t’ó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
Verse 45
ﰠﰡﰢﰣ
ﰤ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
Verse 46
ﰥﰦﰧﰨ
ﰩ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́
Verse 47
ﰪﰫﰬ
ﰭ
títí ikú fi dé bá wa."
Verse 48
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
Verse 49
ﭖﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
Verse 50
ﭜﭝﭞ
ﭟ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ t’ó ń sá lọ,
Verse 51
ﭠﭡﭢ
ﭣ
t’ó sá fún kìnìhún?
Verse 52
Rárá, ńṣe ni ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
Verse 53
ﭮﭯﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
Verse 54
ﭵﭶﭷ
ﭸ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
Verse 55
ﭹﭺﭻ
ﭼ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kó rántí rẹ̀.
Verse 56
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì làforíjìn.
تقدم القراءة