سورة القيامة

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura القيامة ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú Ọjọ́ Àjíǹde.
Verse 2
Mo tún ń búra pẹ̀lú ẹ̀mí t’ó máa dára rẹ̀ lẹ́bi.
Ṣé ènìyàn lérò pé A ò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
Ṣùgbọ́n ènìyàn gbèrò láti pe (Ọjọ́ Àjíǹde) t’ó ń bẹ níwájú rẹ̀ nírọ́.
Verse 6
Ó ń bèèrè pé: "Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?"
Verse 8
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
Verse 9
àti (nígbà) tí A bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn,
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: "Níbo ni ibùsásí wà?"
Verse 12
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun t’ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun t’ó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Verse 15
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
Verse 17
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
Verse 18
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
Verse 19
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
Verse 22
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
Verse 24
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé Wọ́n máa fi aburú kan òhun.
Verse 26
Ẹ gbọ́! Nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
Verse 27
A sì máa sọ pé: "Ǹjẹ́ ọlọ́fọ̀ pípè kan wà bí (tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
Verse 28
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
Verse 30
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
Verse 32
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo nírọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
Verse 35
Lẹ́yìn náà, ègbé ni fún ọ, ègbé sì sẹ́.
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é t’ó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti inú rẹ̀, akọ àti abo.
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
تقدم القراءة