Ìtumọ̀ Sura القيامة ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú Ọjọ́ Àjíǹde.
Verse 2
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Mo tún ń búra pẹ̀lú ẹ̀mí t’ó máa dára rẹ̀ lẹ́bi.
Verse 3
ﮔﮕﮖﮗﮘ
ﮙ
Ṣé ènìyàn lérò pé A ò níí kó àwọn eegun rẹ̀ jọ ni?
Verse 4
ﮚﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
Rárá o. A lágbára láti to eegun ọmọníka rẹ̀ dọ́gba.
Verse 5
ﮡﮢﮣﮤﮥ
ﮦ
Ṣùgbọ́n ènìyàn gbèrò láti pe (Ọjọ́ Àjíǹde) t’ó ń bẹ níwájú rẹ̀ nírọ́.
Verse 6
ﮧﮨﮩﮪ
ﮫ
Ó ń bèèrè pé: "Ìgbà wo ni Ọjọ́ Àjíǹde?"
Verse 7
ﮬﮭﮮ
ﮯ
Nígbà tí ojú bá kọ mọ̀nà,
Verse 8
ﮰﮱ
ﯓ
àti (nígbà) tí òṣùpá bá wọ̀ọ̀kùn,
Verse 9
ﯔﯕﯖ
ﯗ
àti (nígbà) tí A bá pa òòrùn àti òṣùpá pọ̀ mọ́ra wọn,
Verse 10
ﯘﯙﯚﯛﯜ
ﯝ
ènìyàn yóò wí ní ọjọ́ yẹn pé: "Níbo ni ibùsásí wà?"
Verse 11
ﯞﯟﯠ
ﯡ
Rárá, kò sí ibùsásí.
Verse 12
ﯢﯣﯤﯥ
ﯦ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni ibùdúró ní ọjọ́ yẹn.
Verse 13
ﯧﯨﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
Wọ́n máa fún ènìyàn ní ìró ní ọjọ́ yẹn nípa ohun t’ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun t’ó fi kẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
Verse 14
ﯮﯯﯰﯱﯲ
ﯳ
Ṣebí ènìyàn dá ara rẹ̀ mọ̀,
Verse 15
ﯴﯵﯶ
ﯷ
ìbáà mú àwọn àwáwí rẹ̀ wá.
Verse 16
ﯸﯹﯺﯻﯼﯽ
ﯾ
Má ṣe gbé ahọ́n rẹ sí ìmísí láti kánjú ké e.
Verse 17
ﯿﰀﰁﰂ
ﰃ
Dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìkójọ rẹ̀ (sínú ọkàn rẹ) àti kíké rẹ̀.
Verse 18
ﰄﰅﰆﰇ
ﰈ
Nígbà tí A bá ń ké e (fún ọ), kí o sì máa tẹ̀lé kíké rẹ̀.
Verse 19
ﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe àlàyé rẹ̀ fún ọ.
Verse 20
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Ẹ gbọ́! Ńṣe l’ẹ nífẹ̀ẹ́ ayé.
Verse 21
ﭖﭗ
ﭘ
Ẹ sì ń pa ọ̀run tì.
Verse 22
ﭙﭚﭛ
ﭜ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn yóò tutù (fún ìdùnnú).
Verse 23
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Olúwa wọn ni wọn yóò máa wò.
Verse 24
ﭡﭢﭣ
ﭤ
Àwọn ojú kan ní ọjọ́ yẹn sì máa bàjẹ́.
Verse 25
ﭥﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
(Ojú náà) yóò mọ̀ dájú pé Wọ́n máa fi aburú kan òhun.
Verse 26
ﭫﭬﭭﭮ
ﭯ
Ẹ gbọ́! Nígbà tí ẹ̀mí bá dé gògòńgò.
Verse 27
ﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
A sì máa sọ pé: "Ǹjẹ́ ọlọ́fọ̀ pípè kan wà bí (tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú)?
Verse 28
ﭵﭶﭷ
ﭸ
Ó sì máa dá a lójú pé dájúdájú ìpínyà ayé ti dé.
Verse 29
ﭹﭺﭻ
ﭼ
Ojúgun yó sì lọ́mọ́ ojúgun.
Verse 30
ﭽﭾﭿﮀ
ﮁ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ sì ni wíwa ẹ̀dá lọ ní ọjọ́ yẹn.
Verse 31
ﮂﮃﮄﮅ
ﮆ
Kò kúkú gba òdodo gbọ́, kò sì kírun.
Verse 32
ﮇﮈﮉ
ﮊ
Ṣùgbọ́n ó pe òdodo nírọ́. Ó sì kẹ̀yìn sí i.
Verse 33
ﮋﮌﮍﮎﮏ
ﮐ
Lẹ́yìn náà, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ń ṣe fáàrí.
Verse 34
ﮑﮒﮓ
ﮔ
Ègbé ni fún ọ, ègbé ni sẹ́.
Verse 35
ﮕﮖﮗﮘ
ﮙ
Lẹ́yìn náà, ègbé ni fún ọ, ègbé sì sẹ́.
Verse 36
ﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
Ṣé ènìyàn lérò pé A máa fi òun sílẹ̀ lásán ni?
Verse 37
ﮠﮡﮢﮣﮤﮥ
ﮦ
Ṣé kò ti jẹ́ àtọ̀ mọnī tí wọ́n dà jáde sínú àpòlùkẹ́ ni?
Verse 38
ﮧﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
Lẹ́yìn náà, ó di ẹ̀jẹ̀ dídì. (Allāhu) sì ṣẹ̀dá (rẹ̀). Ó sì ṣe é t’ó dọ́gba jálẹ̀ léèyàn.
Verse 39
ﮭﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
(Allāhu) sì ṣe ìran méjì jáde láti inú rẹ̀, akọ àti abo.
Verse 40
Ǹjẹ́ Ẹni tí Ó ṣe ìyẹn kò níí ní agbára láti jí àwọn òkú dìde bí?
تقدم القراءة