Ìtumọ̀ Sura النبأ ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭑﭒ
ﭓ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
Verse 2
ﭔﭕﭖ
ﭗ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
Verse 3
ﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
èyí tí wọ́n ń yapa ẹnu sí.
Verse 4
ﭝﭞ
ﭟ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Verse 5
ﭠﭡﭢ
ﭣ
Lẹ́yìn náà, ní ti òdodo wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
Verse 6
ﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
Verse 7
ﭩﭪ
ﭫ
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
Verse 8
ﭬﭭ
ﭮ
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
Verse 9
ﭯﭰﭱ
ﭲ
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
Verse 10
ﭳﭴﭵ
ﭶ
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
Verse 11
ﭷﭸﭹ
ﭺ
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
Verse 12
ﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
A tún mọ sánmọ̀ méje t’ó lágbára sókè yín.
Verse 13
ﮀﮁﮂ
ﮃ
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ t’ó ń tàn gbòlà.
Verse 14
ﮄﮅﮆﮇﮈ
ﮉ
Àti pé A sọ omi t’ó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
Verse 15
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
Verse 16
ﮏﮐ
ﮑ
pẹ̀lú àwọn ọgbà t’ó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
Verse 17
ﮒﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
Verse 18
ﮘﮙﮚﮛﮜﮝ
ﮞ
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
Verse 19
ﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
Verse 20
ﮤﮥﮦﮧ
ﮨ
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
Verse 21
ﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
Verse 22
ﮮﮯ
ﮰ
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
Verse 23
ﮱﯓﯔ
ﯕ
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
Verse 24
ﯖﯗﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
Verse 25
ﯝﯞﯟ
ﯠ
àyàfi omi gbígbóná àti àwọyúnwẹ̀jẹ̀.
Verse 26
ﯡﯢ
ﯣ
(Ó jẹ́) ẹ̀san t’ó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
Verse 27
ﯤﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
Verse 28
ﯪﯫﯬ
ﯭ
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa nírọ́ gan-an.
Verse 29
ﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
Verse 30
ﯳﯴﯵﯶﯷ
ﯸ
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fun yín bí kò ṣe ìyà.
Verse 31
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
Verse 32
ﭕﭖ
ﭗ
Àwọn ọgbà àti èso àjàrà,
Verse 33
ﭘﭙ
ﭚ
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
Verse 34
ﭛﭜ
ﭝ
àti ife ọtí t’ó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
Verse 35
ﭞﭟﭠﭡﭢﭣ
ﭤ
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
Verse 36
ﭥﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
Verse 37
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun t’ó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
Verse 38
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ t’ó ṣe wẹ́kú.
Verse 39
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
Verse 40
Dájúdájú A fi ìyà t’ó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fun yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: "Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà)."
تقدم القراءة