سورة النازعات

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura النازعات ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́.
Verse 2
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 3
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀.
Verse 4
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà.
Verse 5
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń ṣètò ilé ayé.
Verse 6
Ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa mi gbogbo ayé tìtì pẹ̀lú ohùn igbe.
Verse 7
Ìfọn kejì fún Àjíǹde sì máa tèlé e.
Verse 8
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
Verse 9
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
Wọn yóò wí pé: "Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
Verse 11
Ṣé nígbà tí a ti di eegun t’ó kẹfun tán?"
Wọ́n wí pé: "Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni t’ó pè é nírọ́.)"
Verse 14
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
Verse 15
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonífojì mímọ́, Tuwā.
Kí o sì sọ pé: "Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
Verse 19
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, kí o páyà (Rẹ̀)."
Verse 20
Ó sì fi àmì t’ó tóbi hàn án.
Verse 21
(Àmọ́) ó pè é lópùrọ́. Ó sì yapa rẹ̀.
Verse 22
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
Verse 23
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
Verse 24
Ó sì wí pé: "Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ."
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).
____________________
Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: "Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!" Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni t’ó ń páyà (Allāhu).
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
Verse 28
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé t’ó gún régé.
Verse 29
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
Verse 30
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
Verse 31
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
Verse 32
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
Verse 33
Ìgbádùn ni fun yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
Verse 36
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni t’ó ríran.
Verse 37
Nítorí náà, ní ti ẹni t’ó bá tayọ ẹnu-àlà,
Verse 38
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
Verse 39
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Ní ti ẹni tí ó bá páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
Verse 41
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: "Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?"
Verse 43
Ọ̀nà wo ni ìwọ lè fi ní (ìmọ̀) ìrántí rẹ̀ ná?
Verse 44
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni t’ó ń páyà rẹ̀.
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò lò tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan lọ (nílé ayé).
تقدم القراءة