Ìtumọ̀ Sura عبس ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭑﭒ
ﭓ
(Ànábì s.a.w.) fajú ro, ó sì pẹ̀yìn dà
Verse 2
ﭔﭕﭖ
ﭗ
nítorí pé afọ́jú wá bá a.
Verse 3
ﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)
Verse 4
ﭝﭞﭟﭠ
ﭡ
tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?
Verse 5
ﭢﭣﭤ
ﭥ
Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,
Verse 6
ﭦﭧﭨ
ﭩ
òun ni ìwọ tẹ́tí sí.
Verse 7
ﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).
Verse 8
ﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, t’ó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),
Verse 9
ﭴﭵ
ﭶ
tí ó sì ń páyà (Allāhu),
Verse 10
ﭷﭸﭹ
ﭺ
ìwọ kò sì kọbi ara sí i.
Verse 11
ﭻﭼﭽ
ﭾ
Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
Verse 12
ﭿﮀﮁ
ﮂ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.
Verse 13
ﮃﮄﮅ
ﮆ
(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,
Verse 14
ﮇﮈ
ﮉ
A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́
Verse 15
ﮊﮋ
ﮌ
ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),
Verse 16
ﮍﮎ
ﮏ
àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.
Verse 17
ﮐﮑﮒﮓ
ﮔ
Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!
Verse 18
ﮕﮖﮗﮘ
ﮙ
Kí sì ni Allāhu fi ṣẹ̀dá rẹ̀?
Verse 19
ﮚﮛﮜﮝ
ﮞ
Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.
Verse 20
ﮟﮠﮡ
ﮢ
Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.
Verse 21
ﮣﮤﮥ
ﮦ
Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.
Verse 22
ﮧﮨﮩﮪ
ﮫ
Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.
Verse 23
ﮬﮭﮮﮯﮰ
ﮱ
Ẹ gbọ́, ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.
Verse 24
ﯓﯔﯕﯖ
ﯗ
Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.
Verse 25
ﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Dájúdájú Àwa ń rọ òjò ní púpọ̀.
Verse 26
ﯝﯞﯟﯠ
ﯡ
Lẹ́yìn náà, A mú ilẹ̀ sán kànkàn.
Verse 27
ﯢﯣﯤ
ﯥ
A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;
Verse 28
ﯦﯧ
ﯨ
àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,
Verse 29
ﯩﯪ
ﯫ
àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,
Verse 30
ﯬﯭ
ﯮ
àti àwọn ọgbà t’ó kún fún igi,
Verse 31
ﯯﯰ
ﯱ
àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).
Verse 32
ﯲﯳﯴ
ﯵ
(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Verse 33
ﯶﯷﯸ
ﯹ
Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,
Verse 34
ﯺﯻﯼﯽﯾ
ﯿ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,
Verse 35
ﰀﰁ
ﰂ
àti ìyá rẹ̀ pẹ̀lú bàbá rẹ̀,
Verse 36
ﰃﰄ
ﰅ
àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
Verse 37
ﰆﰇﰈﰉﰊﰋ
ﰌ
Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn t’ó máa tó o ó rán.
Verse 38
ﰍﰎﰏ
ﰐ
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.
Verse 39
ﰑﰒ
ﰓ
Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.
Verse 40
ﰔﰕﰖﰗ
ﰘ
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.
Verse 41
ﭑﭒ
ﭓ
Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Verse 42
ﭔﭕﭖﭗ
ﭘ
Àwọn wọ̀nyẹn, àwọn ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
تقدم القراءة