سورة عبس

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura عبس ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
(Ànábì s.a.w.) fajú ro, ó sì pẹ̀yìn dà
Verse 3
Kí sì l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí ó ṣàfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́)
Verse 4
tàbí kí ó gbọ́ ìrántí, kí ìrántí náà sì ṣe é ní àǹfààní?
Verse 5
Ní ti ẹni tí ó ka ara rẹ̀ kún ọlọ́rọ̀,
Verse 7
Kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ bí kò bá ṣe àfọ̀mọ́ (ara rẹ̀ kúrò nínú àìgbàgbọ́).
Verse 8
Ní ti ẹni tí ó sì wá bá ọ, t’ó ń yára gágá (sí ìrántí, ìyẹn afọ́jú),
Verse 9
tí ó sì ń páyà (Allāhu),
Verse 11
Rárá (kò tọ́ bẹ́ẹ̀). Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
Verse 12
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó rántí rẹ̀.
Verse 13
(Al-Ƙur’ān) wà nínú àwọn tàkádà alápọ̀n-ọ́nlé,
Verse 14
A gbé e ga, A sì ṣe é ní mímọ́
Verse 15
ní ọwọ́ àwọn òǹkọtíà (ìyẹn, àwọn mọlāika),
Verse 16
àwọn alápọ̀n-ọ́nlé, àwọn ẹni rere.
Verse 17
Wọ́n ti fi ènìyàn gégùn-ún (nípa) bí ó ṣe jẹ́ aláìmoore jùlọ!
Verse 19
Nínú àtọ̀ l’Ó ti ṣẹ̀dá rẹ̀. Ó sì pèbùbù (ẹ̀yà-ara) rẹ̀.
Verse 20
Lẹ́yìn náà, Ó ṣe ọ̀nà àtiwáyé ní ìrọ̀rùn fún un.
Verse 21
Lẹ́yìn náà, Ó máa pa á. Ó sì máa fi sínú sàréè.
Verse 22
Lẹ́yìn náà, nígbà tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa gbé e dìde.
Ẹ gbọ́, ènìyàn kò tí ì ṣe n̄ǹkan tí Allāhu pa láṣẹ fún un.
Verse 24
Nítorí náà, kí ènìyàn wòye sí oúnjẹ rẹ̀.
Verse 27
A sì mú kóró èso hù jáde láti inú rẹ̀;
Verse 28
àti èso àjàrà àti kànnáfùrù,
Verse 29
àti igi òróró Zaetūn àti dàbínù,
Verse 30
àti àwọn ọgbà t’ó kún fún igi,
Verse 31
àti àwọn èso (mìíràn) pẹ̀lú ewé tí ẹranko ń jẹ, (A mú wọn hù jáde).
Verse 32
(Wọ́n jẹ́ n̄ǹkan) ìgbádùn fún ẹ̀yin àti àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
Verse 33
Nígbà tí fífọn sínú ìwo nígbà kejì bá ṣẹlẹ̀,
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò sá fún arákùnrin rẹ̀,
Verse 35
àti ìyá rẹ̀ pẹ̀lú bàbá rẹ̀,
Verse 36
àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀.
Ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn ní ọjọ́ yẹn l’ó ti ní ọ̀ràn t’ó máa tó o ó rán.
Verse 38
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn yóò mọ́lẹ̀.
Verse 39
Wọn yó máa rẹ́rìn-ín, wọn yó sì máa dunnú.
Verse 40
Àwọn ojú kan lọ́jọ́ yẹn ni eruku yó sì bò mọ́lẹ̀.
Verse 41
Òkùnkùn yó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Verse 42
Àwọn wọ̀nyẹn, àwọn ni aláìgbàgbọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
تقدم القراءة