Ìtumọ̀ Sura الإنشقاق ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭣﭤﭥ
ﭦ
Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ
Verse 2
ﭧﭨﭩ
ﭪ
- ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ –
Verse 3
ﭫﭬﭭ
ﭮ
àti nígbà tí A bá fẹ ilẹ̀ lójú,
Verse 4
ﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
ó máa ju ohun tí ó wà nínú rẹ̀ síta, ó sì máa pa sófo
Verse 5
ﭴﭵﭶ
ﭷ
– ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ – (ní ọjọ́ yẹn ni ẹ̀dá máa rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀)
Verse 6
Ìwọ ènìyàn dájúdájú ìwọ ń ṣe iṣẹ́ kárakára ní iṣẹ́ àṣepàdé Olúwa rẹ. O sì máa mú un pàdé Rẹ̀.
Verse 7
ﮁﮂﮃﮄﮅ
ﮆ
Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀,
Verse 8
ﮇﮈﮉﮊ
ﮋ
láìpẹ́ A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ (rẹ̀) ní ìṣírò ìrọ̀rùn.
Verse 9
ﮌﮍﮎﮏ
ﮐ
Ó sì máa padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra) lẹ́ni ìdùnnú.
Verse 10
ﮑﮒﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ láti ẹ̀yìn rẹ̀,
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Hāƙƙọh; 69:25.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Hāƙƙọh; 69:25.
Verse 11
ﮘﮙﮚ
ﮛ
láìpẹ́ ó máa kígbe ìparun.
Verse 12
ﮜﮝ
ﮞ
Ó sì máa wọ inú Iná t’ó ń jò fòfò.
Verse 13
ﮟﮠﮡﮢﮣ
ﮤ
Dájúdájú ó ti wà láààrin àwọn ènìyàn rẹ̀ lẹ́ni ìdùnnú (sí àìgbàgbọ́ nílé ayé).
Verse 14
ﮥﮦﮧﮨﮩ
ﮪ
Dájúdájú ó lérò pé òun kò níí padà (sí ọ̀dọ̀ Allāhu ni).
Verse 15
Rárá (ó máa padà). Dájúdájú Olúwa rẹ̀ jẹ́ Olùríran nípa rẹ̀.
Verse 16
ﯔﯕﯖ
ﯗ
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwòǹpapa.
Verse 17
ﯘﯙﯚ
ﯛ
Mo tún búra pẹ̀lú òru àti ohun tí ó kó jọ sínú rẹ̀.
Verse 18
ﯜﯝﯞ
ﯟ
Mo tún búra pẹ̀lú òṣùpá nígbà tí ó bá dégbá (pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀).
Verse 19
ﯠﯡﯢﯣ
ﯤ
Dájúdájú ẹ̀yin yóò máa bọ́ sínú wàhálà kan láti inú wàhálà kan.
Verse 20
ﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
Kí l’ó ṣe wọ́n ná tí wọn kò fi gbàgbọ́ ní òdodo?
Verse 21
Nígbà tí wọ́n bá sì ké al-Ƙur’ān fún wọn, wọn kò níí forí kanlẹ̀.
Verse 22
ﯲﯳﯴﯵ
ﯶ
Rárá, ńṣe ni àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ ń pè é nírọ́.
Verse 23
ﯷﯸﯹﯺ
ﯻ
Allāhu sì nímọ̀ jùlọ nípa ohun tí wọ́n ń fi pamọ́ (sínú ọkàn wọn).
Verse 24
ﯼﯽﯾ
ﯿ
Nítorí náà, fún wọn ní ìró ìyà ẹlẹ́ta-eléro.
Verse 25
Àyàfi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, ẹ̀san tí kò níí pin ń bẹ fún wọn.
تقدم القراءة