سورة الإنشقاق

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura الإنشقاق ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
Nígbà tí sánmọ̀ bá fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ
Verse 2
- ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ –
Verse 3
àti nígbà tí A bá fẹ ilẹ̀ lójú,
Verse 4
ó máa ju ohun tí ó wà nínú rẹ̀ síta, ó sì máa pa sófo
Verse 5
– ó gbọ́, ó sì tẹ̀lé àṣẹ Olúwa rẹ̀ ni. Ó sì di dandan fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀ – (ní ọjọ́ yẹn ni ẹ̀dá máa rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀)
Ìwọ ènìyàn dájúdájú ìwọ ń ṣe iṣẹ́ kárakára ní iṣẹ́ àṣepàdé Olúwa rẹ. O sì máa mú un pàdé Rẹ̀.
Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀,
Verse 8
láìpẹ́ A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ (rẹ̀) ní ìṣírò ìrọ̀rùn.
Verse 9
Ó sì máa padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra) lẹ́ni ìdùnnú.
Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní ìwé iṣẹ́ rẹ̀ láti ẹ̀yìn rẹ̀,
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Hāƙƙọh; 69:25.
Verse 12
Ó sì máa wọ inú Iná t’ó ń jò fòfò.
Dájúdájú ó ti wà láààrin àwọn ènìyàn rẹ̀ lẹ́ni ìdùnnú (sí àìgbàgbọ́ nílé ayé).
Dájúdájú ó lérò pé òun kò níí padà (sí ọ̀dọ̀ Allāhu ni).
Rárá (ó máa padà). Dájúdájú Olúwa rẹ̀ jẹ́ Olùríran nípa rẹ̀.
Verse 16
Nítorí náà, Èmi (Allāhu) ń búra pẹ̀lú àwòǹpapa.
Verse 17
Mo tún búra pẹ̀lú òru àti ohun tí ó kó jọ sínú rẹ̀.
Verse 18
Mo tún búra pẹ̀lú òṣùpá nígbà tí ó bá dégbá (pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀).
Verse 19
Dájúdájú ẹ̀yin yóò máa bọ́ sínú wàhálà kan láti inú wàhálà kan.
Verse 20
Kí l’ó ṣe wọ́n ná tí wọn kò fi gbàgbọ́ ní òdodo?
Nígbà tí wọ́n bá sì ké al-Ƙur’ān fún wọn, wọn kò níí forí kanlẹ̀.
Verse 22
Rárá, ńṣe ni àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ ń pè é nírọ́.
Verse 23
Allāhu sì nímọ̀ jùlọ nípa ohun tí wọ́n ń fi pamọ́ (sínú ọkàn wọn).
Verse 24
Nítorí náà, fún wọn ní ìró ìyà ẹlẹ́ta-eléro.
Àyàfi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, ẹ̀san tí kò níí pin ń bẹ fún wọn.
تقدم القراءة