Ìtumọ̀ Sura البروج ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﭛﭜﭝ
ﭞ
(Allāhu) búra pẹ̀lú sánmọ̀ tí àwọn ibùsọ̀ (òòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀) wà nínú rẹ̀.
Verse 2
ﭟﭠ
ﭡ
Ó tún búra pẹ̀lú ọjọ́ tí wọ́n ṣe ní àdéhùn.
Verse 3
ﭢﭣ
ﭤ
Ó tún búra pẹ̀lú olùjẹ́rìí àti ohun t’ó jẹ́rìí sí.
Verse 4
ﭥﭦﭧ
ﭨ
A ṣẹ́bi lé àwọn t’ó gbẹ́ kòtò (iná),
Verse 5
ﭩﭪﭫ
ﭬ
. (ìyẹn) iná tí wọ́n ń fi igi kò (nínú kòtò).
Verse 6
ﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
(Rántí) nígbà tí wọ́n jókòó sí ìtòsí rẹ̀.
Verse 7
ﭲﭳﭴﭵﭶﭷ
ﭸ
Wọ́n sì ń wo ohun tí wọ́n ń ṣe fún àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
Verse 8
Kò sì sí kiní kan tí wọ́n torí rẹ̀ jẹ wọ́n níyà bí kò ṣe pé wọ́n ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu, Alágbára, Ọlọ́pẹ́,
Verse 9
Ẹni tí Ó ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Allāhu sì ni Ẹlẹ́rìí lórí gbogbo n̄ǹkan.
Verse 10
Dájúdájú àwọn t’ó fi ìnira kan àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, lẹ́yìn náà tí wọn kò ronú pìwàdà, ìyà iná Jahanamọ ń bẹ fún wọn. Ìyà iná t’ó ń jò sì wà fún wọn.
Verse 11
Dájúdájú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, tiwọn ni àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra kan, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Ìyẹn sì ni èrèǹjẹ ńlá.
Verse 12
ﮮﮯﮰﮱ
ﯓ
Dájúdájú ìgbámú ti Olúwa rẹ mà le.
Verse 13
ﯔﯕﯖﯗ
ﯘ
Dájúdájú Òun ni Ó pìlẹ̀ (ẹ̀dá), Ó sì máa dá (ẹ̀dá) padà (fún àjíǹde).
Verse 14
ﯙﯚﯛ
ﯜ
Òun ni Aláforíjìn, Olólùfẹ́ (ẹ̀dá),
Verse 15
ﯝﯞﯟ
ﯠ
Òun l’Ó ni Ìtẹ́-ọlá, Ẹni-ọ̀wọ̀ jùlọ,
Verse 16
ﯡﯢﯣ
ﯤ
Olùṣe-ohun-t’Ó-bá-fẹ́.
Verse 17
ﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
Ṣebí ìró àwọn ọmọ ogun ti dé ọ̀dọ̀ rẹ,
Verse 18
ﯪﯫ
ﯬ
(ọmọ ogun) Fir‘aon àti (ìjọ) Thamūd?
Verse 19
ﯭﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ sì ń pe òdodo nírọ́.
Verse 20
ﯳﯴﯵﯶ
ﯷ
Allāhu sì yí wọn ká lẹ́yìn wọn.
Verse 21
ﯸﯹﯺﯻ
ﯼ
Àmọ́ sá, ohun (tí A fi ránṣẹ́ sí ọ ni) al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé,
Verse 22
ﯽﯾﯿ
ﰀ
tí ó wà nínú wàláà tí À ń ṣọ́.
تقدم القراءة