Ìtumọ̀ Sura الأعلى ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية
Verse 1
ﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni gíga jùlọ.
Verse 2
ﮤﮥﮦ
ﮧ
Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá. Ó sì ṣe (oríkèé-ríkèé rẹ̀) ní dọ́gbadọ́gba.
Verse 3
ﮨﮩﮪ
ﮫ
Ẹni tí Ó yan kádàrá (fún ẹ̀dá). Ó sì tọ́ ọ sọ́nà.
____________________
Nínú āyah yìí, mẹ́ta gbòòrò ni ìtọ́sọ́nà náà èyí tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń ṣe fún àwa ènìyàn àti àlùjànnú. Ìkíní: ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām. Nítorí ìtọ́sọ́nà yìí gan-an ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe sọ àwọn Tírà Rẹ̀ kalẹ̀, tí Ó sì gbé àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ dìde sí wa. Ìkejì: ìtọ́sọ́nà ẹ̀rí-ọkàn. Nípa èyí ni a fi mọ ohun rere àti ohun burúkú ní ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ìfirinlẹ̀ rẹ̀ sì ń jẹyọ nínú àwọn tírà sánmọ̀ àti nínú ọ̀rọ̀ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu (a.s.w.).
Ìkẹta: ìtọ́sọ́nà òye àtinúwá. Nípa èyí ni a ṣe ń ṣàmúlò àwọn ohun àmúṣọrọ̀ fún ìgbáyé-gbádùn. Ìtọ́sọ́nà yìí kò sì sọ ẹnikẹ́ni di Òjíṣẹ́ Allāhu. Tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá rí ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, kò sí ẹ̀san rere kan fún un lórí rẹ̀ ní ọ̀run. Ó kàn wúlò dànù fún ayé ni.
____________________
Nínú āyah yìí, mẹ́ta gbòòrò ni ìtọ́sọ́nà náà èyí tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń ṣe fún àwa ènìyàn àti àlùjànnú. Ìkíní: ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām. Nítorí ìtọ́sọ́nà yìí gan-an ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe sọ àwọn Tírà Rẹ̀ kalẹ̀, tí Ó sì gbé àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ dìde sí wa. Ìkejì: ìtọ́sọ́nà ẹ̀rí-ọkàn. Nípa èyí ni a fi mọ ohun rere àti ohun burúkú ní ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ìfirinlẹ̀ rẹ̀ sì ń jẹyọ nínú àwọn tírà sánmọ̀ àti nínú ọ̀rọ̀ àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu (a.s.w.).
Ìkẹta: ìtọ́sọ́nà òye àtinúwá. Nípa èyí ni a ṣe ń ṣàmúlò àwọn ohun àmúṣọrọ̀ fún ìgbáyé-gbádùn. Ìtọ́sọ́nà yìí kò sì sọ ẹnikẹ́ni di Òjíṣẹ́ Allāhu. Tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá rí ìtọ́sọ́nà ẹ̀sìn ’Islām nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ̀, kò sí ẹ̀san rere kan fún un lórí rẹ̀ ní ọ̀run. Ó kàn wúlò dànù fún ayé ni.
Verse 4
ﮬﮭﮮ
ﮯ
Ẹni tí Ó mú koríko tútù (hù) jáde,
Verse 5
ﮰﮱﯓ
ﯔ
Ó sì sọ ọ́ di gbígbẹ t’ó dúdú.
Verse 6
ﯕﯖﯗ
ﯘ
Àwa yóò máa ké (al-Ƙur’ān) fún ọ. Ìwọ kò sì níí gbàgbé.
Verse 7
Àyàfi ohun tí Allāhu bá fẹ́. Dájúdájú Ó mọ gban̄gba àti ohun t’ó pamọ́.
____________________
Ìyẹn nípasẹ̀ fífí ìdájọ́ kan pa ìdájọ́ t’ó ṣíwájú rẹ̀ rẹ́. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:106.
____________________
Ìyẹn nípasẹ̀ fífí ìdájọ́ kan pa ìdájọ́ t’ó ṣíwájú rẹ̀ rẹ́. Ẹ wo sūrah al-Baƙọrah; 2:106.
Verse 8
ﯤﯥ
ﯦ
Àwa yó sì ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún ọ.
Verse 9
ﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Nítorí náà, ṣèrántí ní àyè tí ìrántí ti wúlò.
____________________
Ìyẹn ni pé, wọ́n fẹ́ kí ṣíṣe ìrántí ọ̀rọ̀ Allāhu jìnnà sí àyè ìhunrírà (bí ilé ọtí), ilé eré àti ilé awàdà nítorí pé, àwọn ènìyàn t’ó wà níbẹ̀ kò níí kọbi ara sí olùsọ̀rọ̀. Āyah yìí jọ sūrah an-Nisā’; 4:140 àti sūrah al-’Ani‘ām; 6:68.
____________________
Ìyẹn ni pé, wọ́n fẹ́ kí ṣíṣe ìrántí ọ̀rọ̀ Allāhu jìnnà sí àyè ìhunrírà (bí ilé ọtí), ilé eré àti ilé awàdà nítorí pé, àwọn ènìyàn t’ó wà níbẹ̀ kò níí kọbi ara sí olùsọ̀rọ̀. Āyah yìí jọ sūrah an-Nisā’; 4:140 àti sūrah al-’Ani‘ām; 6:68.
Verse 10
ﯬﯭﯮ
ﯯ
Ẹni tí ó máa páyà (Allāhu) máa lo ìrántí.
Verse 11
ﭑﭒ
ﭓ
Olórí-burúkú sì máa takété sí i.
Verse 12
ﭔﭕﭖﭗ
ﭘ
(Òun sì ni) ẹni tí ó máa wọ inú Iná t’ó tóbi.
Verse 13
ﭙﭚﭛﭜﭝﭞ
ﭟ
Lẹ́yìn náà, kò níí kú sínú rẹ̀, kò sì níí ṣẹ̀mí (àlàáfíà).
Verse 14
ﭠﭡﭢﭣ
ﭤ
Dájúdájú ẹni tí ó bá ṣàfọ̀mọ́ (ọkàn rẹ̀) ti jèrè.
Verse 15
ﭥﭦﭧﭨ
ﭩ
Ó tún rántí orúkọ Olúwa rẹ̀, ó sì kírun.
Verse 16
ﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Rárá, ńṣe l’ẹ̀ ń gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé.
Verse 17
ﭯﭰﭱ
ﭲ
Ọ̀run sì lóore jùlọ, ó sì máa wà títí láéláé.
Verse 18
ﭳﭴﭵﭶﭷ
ﭸ
Dájúdájú èyí wà nínú àwọn tákàdá àkọ́kọ́,
Verse 19
ﭹﭺﭻ
ﭼ
tákàdá (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm àti (Ànábì) Mūsā.
تقدم القراءة