سورة الغاشية

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura الغاشية ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Verse 1
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ nípa ohun t’ó máa bo ẹ̀dá mọ́lẹ̀ ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
Verse 2
Àwọn ojú kan yóò wálẹ̀ (ní ti ìyẹpẹrẹ) ní ọjọ́ yẹn.
Verse 3
Oníṣẹ́ àṣekúdórógbó (ni wọ́n nílé ayé).
Verse 4
Wọ́n máa wọ inú Iná t’ó gbóná janjan (ní ọ̀run).
Verse 5
Wọ́n sì máa fún (wọn) ní omi gbígbóná mu.
Kò níí mú wọn sanra. Kò sì níí rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀ nínú ebi.
Verse 8
Àwọn ojú kan yó sì kún fún ìgbádùn ní ọjọ́ yẹn
Verse 9
nítorí pé (ó) yọ́nú sí (ẹ̀san) iṣẹ́ rẹ̀.
Verse 10
(Ó máa) wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
Verse 11
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ nínú rẹ̀.
Verse 12
Omi ìṣẹ́lẹ̀rú t’ó ń ṣàn wà nínú rẹ̀.
Verse 13
Àwọn ibùsùn tí wọ́n gbé sókè wà nínú rẹ̀,
Verse 14
àti àwọn ife ìmumi tí wọ́n gbé kalẹ̀ (sí àrọ́wọ́tó wọn),
Verse 15
àti àwọn ìrọ̀rí tí wọ́n tò sí ẹ̀gbẹ́ ara wọn,
Verse 16
àti àwọn ìtẹ́ àtẹ́ẹ̀ká.
Nítorí náà, ṣé wọn kò wo ràkúnmí, bí A ti ṣẹ̀dá rẹ̀ ni;
Verse 19
àti àpáta, bí A ti ṣe gbé e nàró (sínú ilẹ̀);
Verse 20
àti ilẹ̀, bí A ti ṣe tẹ́ ẹ sílẹ̀ ní gban̄sasa?
Verse 21
Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kúkú ni olùṣèràntí.
Verse 22
Ìwọ kì í ṣe ajẹni-nípá lórí wọn
Verse 23
àfi ẹni tí ó bá pẹ̀yìndà (sí òdodo), tí ó sì ṣàì gbàgbọ́.
Verse 24
Allāhu sì máa jẹ ẹ́ níyà t’ó tóbi jùlọ.
Verse 25
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Wa ni àbọ̀ wọn wà.
Verse 26
Lẹ́yìn náà, dájúdájú Àwa l’A máa ṣe ìṣírò-iṣẹ́ wọn.
تقدم القراءة