سورة العلق

الترجمة اليورباوية

Ìtumọ̀ Sura العلق ní اليورباوية láti الترجمة اليورباوية

الترجمة اليورباوية

Ké (al-Ƙur’ān) pẹ̀lú orúkọ Olúwa rẹ, Ẹni tí Ó dá ẹ̀dá.
Verse 2
Ó ṣẹ̀dá ènìyàn láti ara ẹ̀jẹ̀ dídì.
Verse 3
Ké e. Olúwa rẹ ni Alápọ̀n-ọ́nlé jùlọ.
Verse 4
Ẹni tí Ó fi ìmọ̀ nípa gègé ìkọ̀wé mọ ènìyàn.
Verse 6
Ní ti òdodo, dájúdájú ènìyàn kúkú ń tayọ ẹnu-àlà
Verse 7
nítorí pé ó ríra rẹ̀ ní ọlọ́rọ̀.
Verse 8
Dájúdájú ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni àbọ̀ ẹ̀dá.
Verse 10
fún ẹrúsìn kan nígbà tí (ẹrúsìn náà) kírun!
Sọ fún mi (nípa ẹ̀san rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó wà lórí ìmọ̀nà (’Islām)
Verse 12
tàbí pé ó pàṣẹ ìbẹ̀rù (Allāhu)!
Verse 13
Sọ fún mi (nípa ìyà rẹ̀) tí ó bá jẹ́ pé ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i?
Ṣé kò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu ń rí (òun ni?)
Bẹ́ẹ̀ ni (Allāhu ń rí i.) Dájúdájú tí kò bá jáwọ́ (níbi dídí i lọ́wọ́), dájúdájú A máa fi àásó orí rẹ̀ wọ́ ọ (sínú Iná);
Verse 16
àásó orí òpùrọ́, ẹlẹ́ṣẹ̀.
Verse 17
Nítorí náà, kí ó pe àwọn olùbájókòó rẹ̀.
Verse 18
Àwa máa pe àwọn mọlāika ẹ̀ṣọ́ Iná.
Rárá o, má ṣe tẹ̀lé tirẹ̀. Forí kanlẹ̀ (kí o kírun), kí o súnmọ́ (Allāhu).
تقدم القراءة