ترجمة سورة الحج

الترجمة اليورباوية
ترجمة معاني سورة الحج باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية .
من تأليف: أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني .

Ẹ̀yin ènìyàn, ẹ bẹ̀rù Olúwa yín. Dájúdájú ìmì tìtì Àkókò náà, n̄ǹkan ńlá ni.
(Àkókò náà ni) ọjọ́ tí ẹ máa rí i tí gbogbo obìnrin t’ó ń fún ọmọ lọ́mú mu yóò gbàgbé ọmọ tí wọ́n ń fún lọ́mú àti pé gbogbo aboyún yó sì máa bí oyún wọn. Ìwọ yó sì rí àwọn ènìyàn tí ọtí yóò máa pa wọ́n. Ọtí kò sì pa wọ́n, ṣùgbọ́n ìyà Allāhu (t’ó) le (l’ó fà á).
Ó sì ń bẹ nínú àwọn ènìyàn ẹni t’ó ń jiyàn nípa (ẹ̀sìn) Allāhu láì ní ìmọ̀. Ó sì ń tẹ̀lé gbogbo èṣù olórí kunkun.
Wọ́n kọ ọ́ lé (Èṣù) lórí pé dájúdájú ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé e, ó máa ṣì í lọ́nà. Ó sì máa tọ́ ọ sí ọ̀nà ìyà Iná t’ó ń jò fòfò.
Ẹ̀yin ènìyàn, tí ẹ bá wà nínú iyèméjì nípa àjíǹde, dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá yín láti inú erùpẹ̀, lẹ́yìn náà láti inú àtọ̀, lẹ́yìn náà láti inú ẹ̀jẹ̀ dídì, lẹ́yìn náà láti inú bááṣí ẹran tí ó pé ní ẹ̀dá àti èyí tí kò pé ní ẹ̀dá nítorí kí A lè ṣàlàyé (agbára Wa) fun yín. A sì ń mú ohun tí A bá fẹ́ dúró sínú àpò ìbímọ títí di gbèdéke àkókò kan. Lẹ́yìn náà, A óò mu yín jáde ní òpóǹló. Lẹ́yìn náà, (ẹ óò máa ṣẹ̀mí lọ) nítorí kí ẹ lè sánn̄gun dópin agbára yín. Ẹni tí ó máa kú (ní kékeré) wà nínú yín. Ó sì wà nínú yín ẹni tí A óò dá (ìṣẹ̀mí) rẹ̀ sí di àsìkò ogbó kùjọ́kùjọ́ nítorí kí ó má lè mọ́ n̄ǹkan kan mọ́ lẹ́yìn tí ó ti mọ̀ ọ́n. Àti pé o máa rí ilẹ̀ ní gbígbẹ. Nígbà tí A bá sì sọ òjò kalẹ̀ lé e lórí, ó máa yíra padà. Ó máa gbèrú. Ó sì máa mú gbogbo oríṣiríṣi irúgbìn t’ó dára jáde.
Ìyẹn nítorí pé dájúdájú Allāhu, Òun ni Òdodo. Dájúdájú Òun l’Ó ń sọ àwọn òkú di alààyè. Dájúdájú Òun sì ni Alágbára lórí gbogbo n̄ǹkan.
Àti pé dájúdájú Àkókò náà ń bọ̀. Kò sí iyèméjì nínú rẹ̀. Dájúdájú Allāhu yóò gbé àwọn t’ó ń bẹ nínú sàréè dìde.
Ó ń bẹ nínú àwọn ènìyàn ẹni t’ó ń jiyàn nípa (ẹ̀sìn) Allāhu láì ní ìmọ̀ (al-Ƙur’ān) àti ìmọ̀nà (sunnah Ànábì) àti tírà (onímọ̀-ẹ̀sìn) t’ó ń tan ìmọ́lẹ̀ (sọ̀rọ̀ ẹ̀sìn).
Ó ń yí ọrùn rẹ̀ ká ní ti ìgbéraga nítorí kí ó lè kó ìṣìnà bá àwọn ènìyàn lójú ọ̀nà (ẹ̀sìn) Allāhu. Àbùkù ń bẹ fún un nílé ayé. Ní Ọjọ́ Àjíǹde, A sì máa fún un ní ìyà Iná jónijóni tọ́ wò.
Ìyẹn nítorí ohun tí ọwọ́ rẹ̀ tì síwájú. Dájúdájú Allāhu kò níí ṣàbòsí sí àwọn ẹrúsìn Rẹ̀.
Ó tún wà nínú àwọn ènìyàn ẹni t’ó ń jọ́sìn fún Allāhu lórí ahọ́n. Tí rere bá ṣẹlẹ̀ sí i, ó máa fi ọkàn balẹ̀ (sínú ẹ̀sìn). Tí ìfòòró bá sì ṣẹlẹ̀ sí i, ó máa yíjú rẹ̀ padà kúrò nínú ẹ̀sìn. Ó ṣòfò láyé àti lọ́run. Ìyẹn ni òfò pọ́nńbélé.
Ó ń pè lẹ́yìn Allāhu ohun tí kò lè kó ìnira bá a, tí kò sì lè ṣe é ní oore; ìyẹn ni ìṣìnà t’ó jìnnà (sí ìmọ̀nà).
Ó ń pe ohun tí ìnira rẹ̀ súnmọ́ ju àǹfààní rẹ̀ lọ. Dájúdájú (òrìṣà) burú ní olùrànlọ́wọ́, ó sì burú ní alásùn-únmọ́.
Dájúdájú Allāhu yóò mú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. Dájúdájú Allāhu ń ṣe ohun tí Ó bá fẹ́.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá lérò pé Allāhu kò níí ran (Ànábì) lọ́wọ́ láyé àti lọ́run, kí ó na okùn sí sánmọ̀ lẹ́yìn náà kí ó gé e (ìyẹn ni pé, kí ó pokùn so). Kí ó wò ó nígbà náà bóyá ète rẹ̀ lè mú (àrànṣe) t’ó ń bínú sí kúrò (lọ́dọ̀ Ànábì s.a.w.).
____________________
Ìyẹn ni pé, abínú-ẹni kò lè pa kádàrá-ẹni dà. Ó kàn fẹ́ han ara rẹ̀ léémọ̀ ni.
Báyẹn ni A ṣe sọ̀ ọ́ kalẹ̀ ní àwọn āyah t’ó yanjú. Dájúdájú Allāhu ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sí ọ̀nà.
Dájúdájú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo àti àwọn t’ó di yẹhudi, àwọn sọ̄bi’ūn, àwọn kristiẹni, àwọn mọjūs àti àwọn t’ó ṣẹbọ, dájúdájú Allāhu yóò ṣèdájọ́ láààrin wọn ní Ọjọ́ Àjíǹde. Dájúdájú Allāhu ni Arínú-róde gbogbo n̄ǹkan.
Ṣé o ò rí i pé dájúdájú Allāhu ni àwọn t’ó ń bẹ nínú àwọn sánmọ̀ àti àwọn t’ó ń bẹ lórí ilẹ̀, àti òòrùn, òṣùpá, àwọn ìràwọ̀, àwọn àpáta, àwọn igi, àwọn n̄ǹkan ẹlẹ́mìí àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ nínú àwọn ènìyàn ń forí kanlẹ̀ fún? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì tún ni ìyà ti kò lé lórí. Ẹnikẹ́ni tí Allāhu bá fi àbùkù kàn, kò sí ẹnì kan tí ó máa ṣe àpọ́nlé rẹ̀. Dájúdájú Allāhu ń ṣe ohun tí Ó bá fẹ́.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah ar-Ra‘d; 13:15.
Àwọn oníjà méjì (kan) nìyí, wọ́n ń takò ara wọn nípa Olúwa wọn. Nítorí náà, àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, wọ́n máa gé aṣọ Iná fún wọn, wọ́n sì máa da omi gbígbóná lé wọn lórí láti òkè orí wọn.
Wọ́n máa fi yọ́ ohun tí ń bẹ nínú ikùn wọn àti awọ ara wọn.
Àwọn òdùrọ irin (ìyà) sì wà fún wọn pẹ̀lú.
Ìgbàkígbà tí wọ́n bá fẹ́ jáde kúrò nínú rẹ̀ látara ìbànújẹ́, wọ́n á dá wọn padà sínú rẹ̀. (A óò sọ pé): “Ẹ tọ́ ìyà Iná jónijóni wò.”
Dájúdájú Allāhu yóò fi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere wọ inú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra, tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀. A óò ṣe wọ́n ní ọ̀ṣọ́ nínú rẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀gbà wúrà àti àlúùlúù. Aṣọ àlàárì sì ni aṣọ wọn nínú rẹ̀.
A fún wọn ní ìmọ̀nà síbi ohun t’ó dára nínú ọ̀rọ̀. A sì tọ́ wọn sí ọ̀nà Ẹlẹ́yìn.
____________________
"Ohun t’ó dára nínú ọ̀rọ̀" túmọ̀ sí kalmọtuṣ-ṣahādah àti al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé. "Ojú ọ̀nà Ẹlẹ́yìn" túmọ̀ sí ẹ̀sìn ’Islām àti Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Dájúdájú àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, tí wọ́n ń ṣẹ́rí àwọn ènìyàn kúrò lójú ọ̀nà (ẹ̀sìn) Allāhu àti Mọ́sálásí Haram, èyí tí A ṣe ní dọ́gbadọ́gba fún àwọn ènìyàn, olùgbé-inú rẹ̀ àti àlejò (fún ìjọ́sìn ṣíṣe), ẹnikẹ́ni tí ó bá ní èrò láti ṣe ìyípadà kan níbẹ̀ pẹ̀lú àbòsí, A máa mú un tọ́ ìyà ẹlẹ́ta-eléro wò.
(Ẹ rántí) nígbà tí A ṣàfi hàn àyè ilé náà fún (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm (A sì pa á láṣẹ) pé o ò gbọdọ̀ sọ kiní kan di akẹgbẹ́ fún Mi. Àti pé kí o ṣe ilé Mi ní mímọ́ fún àwọn olùyípo rẹ̀, olùkírun, olùdáwọ́tẹ-orúnkún àti olùforíkanlẹ̀.
Kí o sì pe ìpè fún àwọn ènìyàn fún iṣẹ́ Hajj. Wọn yóò wá bá ọ pẹ̀lú ìrìn ẹsẹ̀. Wọn yó sì máa gun àwọn ràkúnmí wá láti àwọn ọ̀nà jíjìn
nítorí kí wọ́n lè rí àwọn àǹfààní t’ó ń bẹ fún wọn àti nítorí kí wọ́n lè ṣèrántí orúkọ Allāhu fún àwọn ọjọ́ tí wọ́n ti mọ̀ lórí n̄ǹkan tí Allāhu pa lésè fún wọn nínú àwọn ẹran-ọ̀sìn. Nítorí náà, ẹ jẹ nínú rẹ̀, kí ẹ sì fi bọ́ aláìlera, tálíkà.
____________________
Ìyẹn àwọn ọjọ́ mẹ́wàá àkọ́kọ́ nínú oṣù Thul-hijjah.
Lẹ́yìn náà, kí wọ́n parí iṣẹ́ Hajj wọn, kí wọ́n mú àwọn ẹ̀jẹ́ wọn ṣẹ, kí wọ́n sì yípo Ilé Láéláé.
Ìyẹn (nìyẹn). Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì pàtàkì àwọn n̄ǹkan tí Allāhu fi ṣe àríṣàmì fún ẹ̀sìn ’Islām, ó lóore jùlọ fún un lọ́dọ̀ Olúwa rẹ̀. Wọ́n sì ṣe àwọn ẹran-ọ̀sìn ní ẹ̀tọ́ fun yín àyàfi àwọn tí wọ́n ń kà (ní èèwọ̀) fun yín. Nítorí náà, ẹ jìnnà sí ẹ̀gbin òrìṣà. Kí ẹ sì jìnnà sí ọ̀rọ̀ irọ́.
(Ẹ jẹ́) olùdúró-déédé-nínú-ẹ̀sìn fún Allāhu, láì níí jẹ́ ọ̀ṣẹbọ sí I. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣẹbọ sí Allāhu, ó dà bí ẹni t’ó jábọ́ láti ojú sánmọ̀, tí ẹyẹ sì gbé e lọ tàbí (tí) atẹ́gùn jù ú sínú àyè t’ó jìnnà.
____________________
Ìyẹn ni pé, rádaràda réderède ni ìkángun ẹni t’ó bá ṣẹbọ kú.
Ìyẹn (nìyẹn). Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì pàtàkì àwọn n̄ǹkan tí Allāhu fi ṣe àríṣàmì fún ẹ̀sìn ’Islām, dájúdájú ó wà lára níní ìbẹ̀rù Allāhu nínú ọkàn.
Àwọn àǹfààní wà fun yín lára àwọn ẹran-ọ̀sìn títí di gbèdéke àkókò kan. Lẹ́yìn náà, Ilé Láéláé ni ibùpa àwọn ẹran náà.
Ìkọ̀ọ̀kan ìjọ (mùsùlùmí t’ó ṣíwájú) ni A yan ẹran pípa fún nítorí kí wọ́n lè dárúkọ Allāhu lórí ohun tí Ó pèsè fún wọn nínú àwọn ẹran-ọ̀sìn. Nítorí náà, Ọlọ́hun yín, Ọlọ́hun Ọ̀kan ṣoṣo ni. Òun ni kí ẹ jẹ́ mùsùlùmí fún. Kí o sì fún àwọn ọlọ́kàn ìrẹ̀lẹ̀, àwọn olùfọkànbalẹ̀ sọ́dọ̀ Allāhu ní ìró ìdùnnú.
(Àwọn ni) àwọn tí ó jẹ́ pé tí A bá dárúkọ Allāhu (fún wọn), ọkàn wọn máa gbọ̀n rìrì. (Wọ́n jẹ́) onísùúrù lórí ohun tí ó bá ṣẹlẹ̀ sí wọn. (Wọ́n jẹ́) olùkírun. Wọ́n sì ń ná nínú ohun tí A pa lésè fùn wọn.
Àwọn ràkúnmí, A ṣe wọ́n nínú àwọn n̄ǹkan àríṣàmì fún ẹ̀sìn Allāhu fun yín. Oore wà lára wọn fun yín. Nítorí náà, ẹ dárúkọ Allāhu lé wọn lórí (kí ẹ sì gún wọn) ní ìdúró. Nígbà tí wọ́n bá fi ẹ̀gbẹ́ lélẹ̀, ẹ jẹ nínú rẹ̀. Ẹ fi bọ́ onítẹ̀ẹ́lọ́rùn àti atọrọjẹ. Báyẹn ni A ṣe rọ̀ wọ́n fun yín nítorí kí ẹ lè dúpẹ́ (fún Un).
Ẹran (tí ẹ pa) àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kò níí dé ọ̀dọ̀ Allāhu. Ṣùgbọ́n ìbẹ̀rù Allāhu láti ọ̀dọ̀ yín l’ó máa dé ọ̀dọ̀ Rẹ̀. Báyẹn ni (Allāhu) ṣe rọ̀ wọ́n fun yín nítorí kí ẹ lè ṣe ìgbétóbi fún Allāhu nípa bí Ó ṣe fi ọ̀nà mọ̀ yín. Kí o sì fún àwọn olùṣe-rere ní ìró ìdùnnú.
Dájúdájú Allāhu ń ti aburú kúrò fún àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo. Dájúdájú Allāhu kò nífẹ̀ẹ́ gbogbo àwọn oníjàǹbá, aláìgbàgbọ́.
A yọ̀ǹda (ogun ẹ̀sìn jíjà) fún àwọn (mùsùlùmí) tí (àwọn kèfèrí) ń gbógun tì nítorí pé (àwọn kèfèrí) ti ṣe àbòsí sí wọn. Dájúdájú Allāhu ni Alágbára lórí àrànṣe wọn.
(Àwọn ni) àwọn tí wọ́n lé jáde kúrò nínú ilé wọn ní ọ̀nà àìtọ́ àfi (nítorí pé) wọ́n ń sọ pé: “Allāhu ni Olúwa wa.” Tí kò bá jẹ́ pé Allāhu ń dènà (aburú) fún àwọn ènìyàn ni, tí Ó ń fi apá kan wọn dènà (aburú) fún apá kan, wọn ìbá ti wó ilé ìsìn àwọn fadá, ṣọ́ọ̀ṣì, sínágọ́gù àti àwọn mọ́sálásí tí wọ́n ti ń dárúkọ Allāhu ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀.1 Dájúdájú Allāhu yóò ṣe àrànṣe fún ẹnikẹ́ni t’ó ń ran (ẹ̀sìn ’Islām) Rẹ̀ lọ́wọ́. Dájúdájú Allāhu mà ni Alágbára, Olùborí.2
____________________
1 Ó ti rinlẹ̀ nínú sunnah Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) pé àwa mùsùlùmí kò gbọdọ̀ da ilé ìsìn àwọn yẹhudi àti nasara wó lulẹ̀ ní àsìkò ogun ẹ̀sìn nítorí pé, àwọn ilé ìsìn náà rọrùn láti sọ di mọ́sálásí, ní pàtàkì jùlọ nígbà tí ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) bá padà sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ ní òpin ayé. 2 Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah at-Taobah; 9:13.
(Àwọn náà ni) àwọn tí ó jẹ́ pé tí A bá fún wọn ní ipò lórí ilẹ̀, wọn yóò kírun, wọn yóò yọ Zakāh, wọn yóò pàṣẹ ohun rere, wọn yó sì kọ ohun burúkú. Ti Allāhu sì ni ìkángun àwọn ọ̀rọ̀ ẹ̀dá.
Tí wọ́n bá pè ọ́ ní òpùrọ́, àwọn ìjọ Nūh, ìjọ ‘Ād àti ìjọ Thamūd kúkú ti pe àwọn Òjíṣẹ́ wọn ní òpùrọ́ ṣíwájú wọn.
Àti pé ìjọ ’Ibrọhīm àti ìjọ (Ànábì) Lūt,
àti àwọn ará ìlú Mọdyan (àwọn náà ṣe bẹ́ẹ̀). Wọ́n tún pe (Ànábì) Mūsā ní òpùrọ́. Mo sì lọ́ àwọn aláìgbàgbọ́ lára. Lẹ́yìn náà, Mo gbá wọn mú. Báwo sì ni bí Mo ṣe (fi ìyà) kọ (aburú fún wọn) ti rí!
Nítorí náà, mélòó mélòó nínú ìlú tí A ti parẹ́ nígbà tí wọ́n jẹ́ alábòsí; àwọn ilé wọn dàwó lulẹ̀ pẹ̀lú òrùlé rẹ̀. (Mélòó mélòó nínú) kànǹga tí wọ́n ti patì (nípasẹ̀ ìparun) àti ilé pẹ̀tẹ́ẹ̀sì oníbíríkì (t’ó ti dahoro)!
Ṣé wọn kò rìn kiri lórí ilẹ̀ kí wọ́n sì ní àwọn ọkàn tí wọ́n máa fi ṣe làákàyè tàbí àwọn etí tí wọn máa fi gbọ́rọ̀? Dájúdájú àwọn ojú kò fọ́, ṣùgbọ́n àwọn ọkàn t’ó wà nínú igbá-àyà l’ó ń fọ́.
Wọ́n sì ń kán ọ lójú fún ìyà náà. Allāhu kò sì níí yapa àdéhùn Rẹ̀. Dájúdájú ọjọ́ kan lọ́dọ̀ Olúwa rẹ dà bí ẹgbẹ̀rún ọdún nínú ohun tí ẹ̀ ń kà (ní òǹkà).
____________________
Nínú āyah yìí, sūrah al-Hajj; 22:47 àti sūrah as-Sajdah; 32:5, ọjọ́ ẹyọ kan lọ́dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni ẹgbẹ̀rún ọdún tiwa, àmọ́ nínú sūrah al-Mọ‘ārij; 70:4, ọjọ́ ẹyọ kan lọ́dọ̀ Allāhu ni ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ (ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta) tiwa (50,000).
Àwọn āyah mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyẹn fẹ́ takora wọn lójú aláìnímọ̀ nípa ìṣe Allāhu (subhānahu wa ta'ālā), àmọ́ kò sí ìtakora láààrin wọn ní ọ̀dọ̀ àwọn onímọ̀-ẹ̀sìn ’Islām. Ní ti āyah 47 nínú sūrah al-Hajj, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń sọ nípa ìdí tí ìyà kò fi tètè sọ̀kalẹ̀ lé àwọn aláìgbàgbọ́ lórí pé, tí Òun bá sọ fún wọn pé àárọ̀ ọ̀la ni ọjọ́ ìyà wọn (bí àpẹẹrẹ), ìyẹn dúró fún ẹgbẹ̀rún ọdún kan. Ní ti āyah 5 nínú sūrah as-Sajdah, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ń sọ nípa ìsọ̀kalẹ̀ àti ìgùnkè àwọn mọlāika láààrin òkè sánmọ̀ keje àti ilẹ̀ keje ní ojoojúmọ pé, òǹkà ọdún tí ẹ̀dá mìíràn máa lò fún rírin ìrìn-àjò náà ní àlọbọ̀ máa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún tiwa (1,000).
Àmọ́ ní ti āyah 4 nínú sūrah al-Mọ‘ārij, Allāhu fún ìrìn-àjò yìí kan náà ní òdíwọ̀n ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún, dípò ẹgbẹ̀rún ọdún. Kíyè sí i, nínú āyah ọjọ́ kan ẹlẹ́gbẹ̀rún ọdún, Allāhu fi gbólóhùn yìí parí rẹ̀ “nínú ohun tí ẹ̀ ń kà ní òǹkà” ìyẹn nílé ayé. Àmọ́ Allāhu kò fi gbólóhùn yẹn parí rẹ̀ nínú āyah ọjọ́ ọlọ́kẹ̀ẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún. Ìtúmọ̀ èyí ni pé, ọjọ́ ọlọ́kẹ̀ẹ́ méjì-ààbọ̀ ọdún yẹn máa dúró fún ọjọ́ kan lọ́jọ́ Àjíǹde lára àwọn aláìgbàgbọ́ nítorí kí wọ́n lè kan ìnira tí ẹ̀mí wọn kò níí gbé. Àwọn onímímọ̀ wulẹ̀ tún sọ pé, yálà ọjọ́ kan ẹlẹ́gbẹ̀rún ọdún tàbí ọjọ́ ọlọ́kẹ̀ẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún, ìkíní kejì l’ó máa ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ Àjíǹde. Wọ́n ní, wàhálà ọjọ́ kan lọ́jọ́ Àjíǹde máa dọ́gba sí ẹgbẹ̀rún ọdún lára onígbàgbọ́ òdodo nítorí kí ìnira ọjọ́ náà máa baà pọ̀ jù lára wọn, nígbà tí wàhálà ọjọ́ kan lọ́jọ́ Àjíǹde máa dọ́gba sí ọ̀kẹ́ méjì-ààbọ̀ ọdún lára àwọn aláìgbàgbọ́ nítorí kí ìnira ọjọ́ náà lè tán wọn ní sùúrù. Èyí sì wà ní ìbámu sí sūrah al-Mudaththir; 74: 8-10.
Síwájú sí i, bí ọjọ́ kan ní ọ̀dọ̀ Allāhu ṣe lè jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún kan, ó tún lè jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún, yálà nílé yìí tàbí lọ́jọ́ Àjíǹde, tí Allāhu bá fẹ́ bẹ́ẹ̀. Ní àkọ́kọ́ ná, “Allāhu l’Ó ń díwọ̀n òru àti ọ̀sán” (sūrah al-Muzammil; 73:20). Bákan náà, nínú ẹ̀gbàwá Nawwās bun Sam‘ān (rọdiyallāhu 'anhu) lórí ọ̀rọ̀ òǹkà ọjọ́ tí Mọsīh Dajjāl máa lò nílé ayé láti fi da ilé ayé rú pátápátá ṣíwájú kí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam, ẹni-àńretí ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) tó wá fi idà pa á. Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ pé. “Ó máa lo ogójì ọjọ́. Ọjọ́ kìíní bí ọdún kan. Ọjọ́ kejì bí oṣù kan. Ọjọ́ kẹta bí ọ̀ṣẹ̀ kan. Ọjọ́ yòókù bí ọjọ́ yín.” (Muslim) Nítorí náà, ọjọ́ kàn lè dọ́gba sí ẹgbẹ̀rún ọdún tiwa (1000), tí Allāhu bá fẹ́. Ọjọ́ kan sì lè dọ́gba sí ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún tiwa (50,000), tí Allāhu bá fẹ́. Aṣèyí-ówùú ni Allāhu.
Mélòó mélòó nínú ìlú tí Mo lọ́ lára, tí wọ́n jẹ́ alábòsí. Lẹ́yìn náà, Mo gbá wọn mú. Ọ̀dọ̀ Mi sì ni àbọ̀ ẹ̀dá.
Sọ pé: "Ẹ̀yin ènìyàn, èmi mà ni olùkìlọ̀ pọ́nńbélé fun yín."
Nítorí náà, àwọn t’ó bá gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe iṣẹ́ rere, àforíjìn àti arísìkí alápọ̀n-ọ́nlé ń bẹ fún wọn.
Àwọn t’ó ṣe iṣẹ́ burúkú nípa àwọn āyah Wa, (tí wọ́n lérò pé) àwọn mórí bọ́ nínú ìyà; àwọn wọ̀nyẹn ni èrò inú iná Jẹhīm.
A kò rán Òjíṣẹ́ kan tàbí Ànábì kan níṣẹ́ ṣíwájú rẹ àfi kí ó jẹ́ pé nígbà tí ó bá sọ̀rọ̀, Èṣù máa ju (n̄ǹkan) sínú ọ̀rọ̀ rẹ̀. Nítorí náà, Allāhu yóò pa ohun tí Èṣù ń jù sínú rẹ̀ rẹ́. Lẹ́yìn náà, Ó máa fi òdodo àwọn āyah Rẹ̀ rinlẹ̀. Allāhu sì ni Onímọ̀, Ọlọ́gbọ́n.
____________________
yah 52 yìí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn āyah pàtàkì tí àwọn kristiẹṅi máa ń tọ́ka sí láti fi tako al-Ƙur’ān alápọ̀n-ọ́nlé àti Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Àwọn kristiẹni máa ń sọ pé, “Kókó t’ó wà nínú āyah náà ni pé, Èṣù máa ń gbé ọ̀rọ̀ sẹ́nu Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) lásìkò tí ó bá fẹ́ ka al-Ƙur’ān fún àwọn ènìyàn láti fi jíṣẹ́ fún wọn. Wọ́n fi kún un pé Èṣù l’ó máa ń gba ẹnu Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ̀rọ̀ nígbàkígbà tí ó bá ń jíṣẹ́ Ọlọ́hun.” Nítorí kí ọ̀rọ̀ ẹnu àwọn kristiẹni wọ̀nyí lè dùn létí àwọn ènìyàn, wọ́n túlé kan ẹ̀gbàwá ọ̀rọ̀ kan tí wọ́n ṣe àfitì rẹ̀ sọ́dọ̀ ọmọ ‘Abbās (rọdiyallāhu 'anhu) pé, “Ní ọjọ́ kan Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ń ka sūrah an-Najm, ìyẹn sūrah 53, fún àwọn ará ìlú Mọkkah. Nígbà tí ó ka sūrah náà dé orí āyah 19 sí āyah 20, ní àyè tí Allāhu (s..w.t.) ti sọ pé “Ẹ sọ fún mi nípa òrìṣà Lāt àti òrìṣà ‘Uzzā, àti òmíràn, Mọnāh, òrìṣà kẹta”, ó sọ pé “Ìwọ̀nyẹn ni àwọn ẹyẹ àgbà. Àti pé ìrètí wà nínú ìṣìpẹ̀ tí wọ́n máa ṣe.” Nígbà tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ bẹ́ẹ̀ tán, gbogbo àwọn mùsùlùmí àti àwọn ọ̀ṣẹbọ sì dìjọ forí kanlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀…” Àwọn kristiẹni wá sọ pé, “àwọn òrìṣà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyẹn tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) pè ní ẹyẹ àgbà ni ọ̀rọ̀ náà tí Èṣù jù sẹnu Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) lásìkò t’ó ń ké al-Ƙur’ān náà. Ìtàn náà sì wà nínú àkọsílẹ̀ àwọn tírà tafsīr àwọn mùsùlùmí.” Ọ̀rọ̀ wọn lórí ìtúmọ̀ tí wọ́n fún āyah 52 àti ẹ̀rí wọn lórí rẹ̀ parí.
Èsì ọ̀rọ̀: Ọ̀rọ̀ ńlá ni àwọn kristiẹni sọ yìí. Ọ̀rọ̀ náà kì í ṣe òdodo rárá. Àfiwé ìtúkútùú àwọn kristiẹni wọ̀nyí dà bí ọ̀rọ̀ arákùnrin wọn kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ “Lákin”. Lákin yìí l’ó sọ pé òun náà nímọ̀ ìtúmọ̀ al-Ƙur’ān ju àwa mùsùlùmí lọ. Ó sì sọ pé kódà Allāhu dárúkọ òun nínú al-Ƙur’ān. A sì bi í léèrè pé ibo ni orúkọ rẹ̀ wà nínú al-Ƙur’ān. Ó sì fèsì pé orúkọ òun ni gbogbo ibi tí al-Ƙur’ān bá ti sọ pé “لَكِنْ” (lākin)!? Ẹ̀yin onímọ̀, ṣé ìtúmọ̀ “لَكِنْ” (lākin) nínú èdè Lárúbáwá sì ni ìtúmọ̀ “Lákin” nínú èdè Yorùbá? “Ṣùgbọ́n / àmọ́” ni ìtúmọ̀ “لَكِنْ” (lākin) nínú èdè Lárúbáwá. “Ẹni tí ó ní akin-ọkàn” sì ni ìtúmọ̀ “Lákin” nínú èdè Yorùbá. Ṣé ẹ rí i báyìí pé “ṣùgbọ́n” ti wọnú ọ̀rọ̀ àwọn kristiẹni. Ìyẹn ni pé, wọn kò ní ìmọ̀ olóóókan nípa al-Ƙur’ān àti hadīth, ṣùgbọ́n wọ́n mọ irọ́ funfun báláú pa mọ́ ẹ̀sìn ’Islām. Ìṣe wọn yìí sì ṣe wẹ́kú ọ̀rọ̀ tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ nípa wọn nínú sūrah al-Baƙọrah; 2: 78.
Wàyí tí a ti mọ irú ènìyàn tí àwọn kristiẹni í ṣe, ẹ jẹ́ kí á ṣàlàyé āyah tí wọ́n ń túmọ̀ sódì náà. Ní àkọ́kọ́ ná, ẹni tí Èṣù bá ń gbẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀, bí kò jẹ́ wèrè, ó máa jẹ́ eléṣù tí ó bá Èṣù dòwò pọ̀. Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kì í ṣe wèrè. Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) kò sì lọ́dẹ orí rí. Bẹ́ẹ̀ sì ni pé kò bọ̀rìṣà rí áḿbọ̀sìbọ́sí pé Èṣù yóò máa gùn ún. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sì ti fi rinlẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ āyah al-Ƙur’ān pé Èṣù àti àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kò lágbára lórí àwọn onígbàgbọ́ òdodo. Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sì ni ọ̀gá àwọn onígbàgbọ́ òdodo. Díẹ̀ nínú àwọn àyè tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti sọ èyí ni sūrah al-Hijr; 15:42 àti sūrah an-Nahl; 16:99-100. Bákan náà, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) tún fi rinlẹ̀ pé ààbò mímọ́ wà fún ìsọ̀kalẹ̀ al-Ƙur’ān, kíké rẹ̀ àti ṣíṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ láti ojú ayé Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) títí di òpin ayé, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà nínú sūrah al-Hijr; 15:9 àti sūrah Fussilat; 41:41-42. Nítorí náà, Èsù kan kan kò lè rọ́nà ti ọ̀rọ̀ tirẹ̀ bọ inú al-Ƙur’ān. Bákan náà, ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ tàbí ọ̀rọ̀ eléṣù kò tẹnu Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) jáde rí nínú ìgbésí ayé rẹ̀ ní ìbámu sí sūrah an-Najm; 53: 3-4. Síwájú sí i, Èṣù kan kan kò lè rí àwòrán tàbí ohùn Ànábì wa (s.a.w) yá lò yálà lójú oorun tàbí lójú ayé nítorí hadīth Sọhīh, ní ibi tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ti sọ pé “Èṣù kò lè gbé àwòrán mi wọ̀.” Kódà “ƙọrīn” èṣù àlùjọ̀nnú alábàárìn tí Allāhu fi sára ènìyàn kọ̀ọ̀kan, láì yọ Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ kan sílẹ̀, tí ó máa ń pa ènìyàn láṣẹ aburú nínú ẹ̀mí, òun gan-an kò lè pa Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) láṣẹ aburú nítorí pé Allāhu ṣe àrànṣe fún Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) lórí rẹ̀. Àlùjọ̀nnú náà sì gba ’Islām, kò sì pa Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) láṣẹ aburú. Nítorí náà, “ma‘sūm” ẹni tí ààbò mímọ́ wà fún ni Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Pẹ̀lú àwọn ẹ̀rí tààrà wọ̀nyẹn, mùsùlùmí onígbàgbọ́ òdodo kò níí pẹ̀lú ọ̀bọ jẹko láti sọ pé èṣù kan gba ẹnu Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ̀rọ̀ láti sọ pé “Ìwọ̀nyẹn ni àwọn ẹyẹ àgbà. Àti pé ìrètí wà nínú ìṣìpẹ̀ tí wọ́n máa ṣe.”
Ní ti àwọn hadīth tí wọ́n fi gbe ọ̀rọ̀ burúkú náà lẹ́sẹ̀, gbogbo àwọn hadīth náà l’ó lẹ, tí kò ṣe é fi ṣe ẹ̀rí àfi hadīth ẹyọ kan péré. Ìyẹn ni pé, gbogbo hadīth t’ó ń sọ nípa pé Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ pé “Ìwọ̀nyẹn ni àwọn ẹyẹ àgbà. Àti pé ìrètí wà nínú ìṣìpẹ̀ tí wọ́n máa ṣe.” jẹ́ hadīth t’ó lẹ pátápátá. Àmọ́ èyí tí ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ nínú wọn kò tayọ èyí tí ó wà nínú sọhīhu-l-Bukọ̄riy, lábẹ́ àkọlé ìforíkanlẹ̀ àwọn mùsùlùmí pẹ̀lú àwọn ọ̀ṣẹbọ. Láti ọ̀dọ̀ Ọmọ ‘Abbās (rọdiyallāhu 'anhu), ó sọ pé: “Dájúdájú Ànábì forí kanlẹ̀ níbi āyah ìforíkanlẹ̀ nínú sūrah an-Najm. Àwọn mùsùlùmí, àwọn ọ̀ṣẹbọ, àlùjọ̀nnú àti ènìyàn sì forí kanlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀.” Hadīth nìyí t’ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà. Kò sì sí ọ̀rọ̀ “àwọn ẹyẹ àgbà” kan nínú rẹ̀. Ohun tí ènìyàn yó kàn fẹ́ mọ̀ nípa rẹ̀ ni pé, kí ló mú àwọn ọ̀ṣẹbọ forí kanlẹ̀ láì tí ì gba ’Islām. Ìdí tí àwọn ọ̀ṣẹbọ wọ̀nyẹn fi forí kanlẹ̀ ni pé, wọ́n gbọ́ orúkọ òrìṣà wọn mẹ́ta kan nínú āyah al-Ƙur’ān, ìyẹn nínú sūrah an-Najm; 53:19-20, wọ́n bá lérò pé Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) náà ń pàtàkì àwọn òrìṣà náà. Inú wọn sì dùn. Wọ́n bá forí kanlẹ̀. Ìforíkanlẹ̀ wọn kò sì wulẹ̀ wúlò fún n̄ǹkan kan. Àmọ́ níkété tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ké sūrah náà síwájú wọ āyah 26. Ara wọn balẹ̀. Wọ́n sì rí i dájú pé, ọ̀tọ̀ ni ohun tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) sọ. Ọ̀tọ̀ ni ohun tí àwọn èṣù inú ẹ̀mí wọn gbé jù sínú ọkàn wọn. wọn fúnra wọn ni wọ́n sọ ohun tí àwọn èṣù inú ẹ̀mí wọn gbé jù sínú ẹ̀mí wọn. Àmọ́ nítorí kí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) máa baà banújẹ́ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) fi sọ ọ́ di ohun mímọ̀ fún un nínú āyah 52 (ìyẹn, nínú sūrah al-Hajj) pé, kò sí Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ ti irú rẹ̀ kò sẹlẹ̀ sí rí ní ọ̀nà kan tàbí òmíràn. Nítorí náà, Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) fẹ́ pe làákàyè wọn wálé pé, Allāhu kò lọ́wọ́ nínú àwọn orúkọ òrìṣà náà. Àti pé, kò sí ìkápá ìpẹ̀ ṣíṣe fún wọn lọ́dọ̀ Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Āyah 23 sí 26 nínú sūrah an-Najm sì ń jẹ́rìí sí èyí.
Síwájú sí i, mímú tí àwọn tírà tafsīr mú ìṣẹ̀lẹ̀ náà wà láì sọ àwílé jẹ́ àsọọ̀yán àti àsọọ̀tó. Àmọ́ sá, ẹ̀gbàwá Bukọ̄riy ti yanjú ọ̀rọ̀ náà. Kò sì sí ọ̀rọ̀ “àwọn ẹyẹ àgbà mẹ́ta” kan kan nínú rẹ̀. Nítorí náà, hadīth kò báà lé ní igba lórí ọ̀rọ̀ kan náà, tí ó bá ti tako āyah kan nínú al-Ƙur’ān tàbí tí ó bá tako hadīth Bukọ̄riy tàbí hadīth Muslim, irú hadīth náà kò wúlò nínú ẹ̀sìn wa láti fi ṣe ẹ̀rí ọ̀rọ̀.
(Èyí ń ṣẹlẹ̀) nítorí kí (Allāhu) lè fi ohun tí Èṣù ń jù (sínú rẹ̀) ṣe àdánwò fún àwọn tí àìsàn ń bẹ nínú ọkàn wọn àti àwọn tí ọkàn wọn le. Dájúdájú àwọn alábòsí sì wà nínú ìyapa t’ó jìnnà (sí òdodo).
(Èyí ń ṣẹlẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní ìmọ̀ lè mọ̀ pé dájúdájú al- Ƙur’ān jẹ́ òdodo láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, wọn yó sì gbàgbọ́ nínú rẹ̀, ọkàn wọn yó sì balẹ̀ sí i. Dájúdájú Allāhu l’Ó ń fi ẹsẹ̀ àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo rinlẹ̀ sójú ọ̀nà tààrà (’Islām).
Àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ kò sì níí yé wà nínú iyèméjì nípa rẹ̀ títí Àkókò náà yóò fi dé bá wọn ní òjijì tàbí (títí) ìyà ọjọ́ ìparun yóò fi dé bá wọn.
Gbogbo ìjọba ọjọ́ yẹn ń jẹ́ ti Allāhu tí Ó máa ṣèdájọ́ láààrin wọn. Nítorí náà, àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere, (wọn yóò wà) nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.
Àwọn t’ó sì ṣàì gbàgbọ́, tí wọ́n tún pe àwọn āyah Wa nírọ́; àwọn wọ̀nyẹn ni ìyà tí í yẹpẹrẹ ẹ̀dá sì wà fún.
Àwọn tí wọ́n gbé ìlú wọn jù sílẹ̀ nítorí ẹ̀sìn Allāhu, lẹ́yìn náà, tí wọ́n pa wọ́n tàbí tí wọ́n kú; dájúdájú Allāhu yóò pèsè fún wọn ní ìpèsè t’ó dára. Dájúdájú Allāhu, Ó mà l’óore jùlọ nínú àwọn olùpèsè.
Dájúdájú (Allāhu) yóò fi wọ́n sí àyè kan tí wọn yóò yọ́nú sí. Dájúdájú Allāhu mà ni Onímọ̀, Aláfaradà.
60. Ìyẹn (nìyẹn). Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbẹ̀san irú ìyà tí wọ́n fi jẹ ẹ́, lẹ́yìn náà tí wọ́n bá tún ṣàbòsí sí i, dájúdájú Allāhu yóò ṣàrànṣe fún un. Dájúdájú Allāhu mà ni Alámòjúúkúrò, Aláforíjìn.
Ìyẹn nítorí pé dájúdájú Allāhu ń fi òru bọ inú ọ̀sán, Ó sì ń fi ọ̀sán bọ inú òru. Allāhu sì ni Olùgbọ́, Olùríran.
Ìyẹn nítorí pé dájúdájú Allāhu, Òun ni Òdodo. Àti pé dájúdájú ohun tí wọ́n ń pè lẹ́yìn Rẹ̀ ni irọ́. Dájúdájú Allāhu, Òun ni Ó ga, Ó tóbi.
Ṣé o ò rí i pé dájúdájú Allāhu ń sọ omi kalẹ̀ láti sánmọ̀, ilẹ̀ sì máa lọ́ràá wá? Dájúdájú Allāhu ni Aláàánú, Alámọ̀tán.
TiRẹ̀ ni ohunkóhun t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀. Dájúdájú Allāhu, Òun mà ni Ọlọ́rọ̀, Ọlọ́pẹ́.
Ṣé o ò rí i pé dájúdájú Allāhu rọ ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀ fun yín, àti ọkọ̀ ojú-omi t’ó ń rìn nínú agbami odò pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Rẹ̀, Ó ń mú sánmọ̀ dání tí kò fi jábọ́ àyàfi pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Rẹ̀? Dájúdájú Allāhu mà ni Aláàánú, Oníkẹ̀ẹ́ fún àwọn ènìyàn.
Òun sì ni Ẹni t’Ó ṣe yín ni alààyè, lẹ́yìn náà Ó ń sọ yín di òkú, lẹ́yìn náà Ó máa sọ yín di alààyè. Dájúdájú ènìyàn mà ni aláìmoore.
Ìjọ kọ̀ọ̀kan l’A fún ní ìlànà tí wọ́n máa lò. Nítorí náà, kí wọ́n má ṣe jà ọ́ níyàn nípa ọ̀rọ̀ náà. Kí o sì pèpè sọ́dọ̀ Olúwa rẹ. Dájúdájú o kúkú wà lójú ọ̀nà tààrà.
____________________
Gbólóhùn yìí “Ìjọ kọ̀ọ̀kan l’A fún ní ìlànà tí wọ́n máa lò.” Ìyẹn nínú ’Islām tí Allāhu fi rán Òjíṣẹ́ wọn sí wọn nítorí pé, ’Islām ni ẹ̀sìn fún gbogbo àwọn Ànábì àti àwọn Òjísẹ́ Olọ́hun, àmọ́ ìlànà ìjọ́sìn kan láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn lè yàtọ̀. Bí àpẹẹrẹ, kò sí ìjọ Òjíṣẹ́ kan tí kò ní ìrun tirẹ̀, àmọ́ òǹkà rakaa àti àsìkò ìrun ń yàtọ̀ láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn. Bákan náà ni ìyàtọ̀ tún lè wà nínú ìṣe àti àṣà láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn. Bí àpẹẹrẹ, àṣà ìkúnlẹ̀-kíni jẹ́ ìṣe ẹ̀tọ́ nínú ìjọ ìṣaájú, àmọ́ ó jẹ́ ìṣe èèwọ̀ nínú ìjọ Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Gbogbo ìjọ Òjíṣẹ́ ni wọ́n lè yàtọ̀ síra wọn ní ojú pọ̀n-nà wọ̀nyẹn, àmọ́ kò sí ìyàtọ̀ láààrin ìjọ Òjíṣẹ́ kan sí òmíràn lórí jíjẹ́ tí Allāhu ń jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo Ọlọ́hun, Olúwa àti Olùgbàlà àti ṣíṣe ẹbọ ní èèwọ̀. Èyí gan-an ni ìpìlẹ̀ fún ìgbàgbọ́ òdodo tí gbogbo àwọn Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun mú wá.
Tí wọ́n bá sì jà ọ́ níyàn, sọ nígbà náà pé: "Allāhu nímọ̀ jùlọ nípa ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Allāhu máa ṣèdájọ́ láààrin yín ní Ọjọ́ Àjíǹde nípa ohun tí ẹ̀ ń yapa ẹnu sí."
Ṣé o ò mọ̀ pé dájúdájú Allāhu l’Ó mọ ohun tí ń bẹ nínú sánmọ̀ àti ilẹ̀? Dájúdájú (àkọsílẹ̀) ìyẹn wà nínú tírà kan. Dájúdájú ìyẹn rọrùn fún Allāhu.
Dípò (kí wọ́n jọ́sìn fún) Allāhu, wọ́n ń jọ́sìn fún ohun tí (Allāhu) kò sọ ẹ̀rí kan kalẹ̀ fún àti ohun tí kò sí ìmọ̀ kan fún wọn lórí rẹ̀. Kò sì níí sí alárànṣe kan fún àwọn alábòsí.
Nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa t’ó yanjú fún wọn, o máa rí ìkorò-ojú nínú ojú àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́; wọn yó sì fẹ́ẹ̀ fọwọ́ ìnira kan àwọn tí ń ké àwọn āyah Wa fún wọn. Sọ pé: "Ṣé kí n̄g fun yín ní ìró ohun t’ó burú ju ìyẹn? Iná tí Allāhu ṣèlérí rẹ̀ fún àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́ ni. Ìkángun náà sì burú."
Ẹ̀yin ènìyàn, Wọ́n fi àkàwé kan lélẹ̀. Nítorí náà, ẹ tẹ́tí sí i. Dájúdájú àwọn tí ẹ̀ ń pè lẹ́yìn Allāhu, wọn kò lè dá eṣinṣin kan, wọn ìbàá para pọ̀ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Tí eṣinṣin bá sì gba kiní kan mọ́ wọn lọ́wọ́, wọn kò lè gbà á padà lọ́wọ́ rẹ̀. Ọ̀lẹ ni ẹni tí ń wá n̄ǹkan (lọ́dọ̀ òrìṣà) àti (òrìṣà) tí wọ́n ń wá n̄ǹkan lọ́dọ̀ rẹ̀.
Wọn kò bu ọ̀wọ̀ fún Allāhu ní ọ̀wọ̀ tí ó tọ́ sí I. Dájúdájú Allāhu mà ni Alágbára, Olùborí.
Allāhu l’Ó ń ṣa àwọn kan lẹ́ṣà (láti jẹ́) Òjíṣẹ́ nínú àwọn mọlāika àti nínú àwọn ènìyàn. Dájúdájú Allāhu ni Olùgbọ́, Olùríran.
Ó mọ ohun tí ń bẹ níwájú wọn àti ní ẹ̀yìn wọn. Ọ̀dọ̀ Allāhu sì ni wọ́n máa ṣẹ́rí àwọn ọ̀rọ̀ ẹ̀dá padà sí.
Ẹ̀yin tí ẹ gbàgbọ́ ní òdodo, ẹ dáwọ́ tẹ orúnkún (lórí ìrun), ẹ forí kanlẹ̀, ẹ jọ́sìn fún Olúwa yín, kí ẹ sì ṣe rere nítorí kí ẹ lè jèrè.
Ẹ jagun fún ẹ̀sìn Allāhu ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ tí ẹ lè gbà jagun fún Un. Òun l’Ó ṣà yín lẹ́ṣà, kò sì kó ìdààmú kan kan ba yín nínú ẹ̀sìn. (Ẹ tẹ̀lé) ẹ̀sìn bàbá yín (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm. (Allāhu) l’Ó sọ yín ní mùsùlùmí ṣíwájú (àsìkò yìí) àti nínú (al-Ƙur’ān) yìí nítorí kí Òjíṣẹ́ lè jẹ́ ẹlẹ́rìí fun yín àti nítorí kí ẹ̀yin náà lè jẹ́ ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn. Nítorí náà, ẹ kírun, ẹ yọ Zakāh, kí ẹ sì bá Allāhu dúró. Òun ni Aláàbò yín. Ó dára ni Aláàbò. Ó sì dára ní Alárànṣe.
____________________
Ọ̀kan pàtàkì nínú ẹ̀rí t’ó ń fi rinlẹ̀ pé Allāhu kò fi ẹ̀sìn kristiẹniti tàbí ẹ̀sìn yẹhudi rán Òjíṣẹ́ kan kan rí ni gbólóhùn “(Allāhu) l’Ó sọ yín ní mùsùlùmí ṣíwájú (àsìkò yìí) àti nínú (al-Ƙur’ān) yìí”. Gbólóhùn náà ti fi hàn kedere pé, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) t’Ó fi ẹ̀sìn kan ṣoṣo rán gbogbo àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀ (a.s.w.), Òun l’Ó sọ ẹ̀sìn náà ni ’Islām. Ó sì sọ ẹlẹ́sìn náà ni “mùsùlùmí”. Tí ẹnì kan bá pe ara rẹ̀ ní kristiẹni, ẹ bi í léèrè pé “ta ni ó sọ ẹ̀sìn kan ní kristiẹniti? Ta sì ni ó sọ ọ́ ní kristiẹni?” Ó dájú pé kì í ṣe Allāhu, Ọlọ́hun (subhānahu wa ta'ālā). Ọpẹ́ ni fún Allāhu tí Ó tọ́ wa sọ́nà tààrà Rẹ̀, ’Islām.
Icon