Kí ni (Ànábì) Muhammad bí kò ṣe Òjíṣẹ́, tí àwọn Òjíṣẹ́ kan ti lọ ṣíwájú rẹ̀. Ṣé tí ó bá kú tàbí tí wọ́n bá pa á, ẹ máa pẹ̀yìn dà (sẹ́sìn)? Ẹnikẹ́ni tí ó bá pẹ̀yìn dà (sẹ́sìn) kò lè kó ìnira kan kan bá Allāhu. Allāhu yó sì san àwọn olùdúpẹ́ ní ẹ̀san rere.
____________________
Āyah yìí jẹ́ ọ̀kan pàtàkì nínú àwọn ẹ̀rí àtamọ́-àtọmọ̀ lọ́dọ̀ àwọn t’ó gbàgbọ́ pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ti kú. Wọ́n ní ikú rẹ̀ ti jẹyọ nínú “Kí ni (Ànábì) Muhammad bí kò ṣe Òjíṣẹ́, tí àwọn Òjíṣẹ́ kan ti lọ ṣíwájú rẹ̀” Èsì: Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé āyah náà ń sọ̀rọ̀ nípa ikú àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu ('alaehim sọlātu wa salām) t’ó ṣíwájú Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam), kò pọn dandan kí āyah náà yà lọ síbi ọ̀rọ̀ nípa àì tí ì kú Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ẹ kíyè sí i, bí ọ̀rọ̀ bá wá ní àwòrán gbogbogbò nínú al-Ƙur’ān, kò túmọ̀ sí pé kò lè ní àyàfi nínú nínú āyah mìíràn tàbí nínú hadīth Ànábì t’ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, nínú sūrah an-Nisā’; 4:117, Allāhu ń sọ̀rọ̀ nípa àwọn n̄ǹkan tí àwọn ènìyàn ń jọ́sìn fún lẹ́yìn Rẹ̀ pé, “Wọn kò pe kiní kan lẹ́yìn Allāhu bí kò ṣe àwọn abo òrìṣà.” Nínú ohun tí àwọn kan sì sọ di òrìṣà ni Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ṣé abo sì ni òun náà ni tàbí akọ? Ìsọkúsọ l’ó sì máa jẹ́ láti pe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ní abo. Bẹ́ẹ̀ sì ni pé, Allāhu kò ṣe “àyàfi” nínú āyah “abo lòrìṣà”, àmọ́ ó yé wa nínú àwọn āyah mìíràn pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kì í ṣe abo. Akọ ni.
Àpẹẹrẹ mìíràn fún mímú “àyàfi” fún āyah al-Ƙur’ān wá nínú hadīth, òhun ni pé nínú al-Ƙur’ān èèwọ̀ ni òkúǹbete ẹran. Nínú hadith Ànábì láti rí “àyàfi” sí èèwọ̀ náà. Àyàfi kìíní ni pé, awọ ẹran òkúǹbete tí wọ́n pa lósè kì í ṣe èèwọ̀ fún lílò fún ọ̀ṣọ́ ilé tàbí ọ̀ṣọ́ ara. Irú awọ ẹran òkúǹbete tí wọ́n pa lósè bẹ́ẹ̀ sì di ẹ̀tọ́ láti fi ṣe bàtà, bẹ́lítì, àpò aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àyàfi kejì: nínú hadīth l’a ti rí i kà pé ẹ̀tọ́ ni òkúǹbete gbogbo ẹran inú omi àti àwọn òkúǹbete ẹja. Bí kò ṣe sí ohun t’ó sọ ọ́ di dandan láti rí àwọn àyàfi wọ̀nyí nínú āyah náà, ohun náà l’ó jẹ́ kí á mọ̀ pé kò sí ohun t’ó sọ ọ́ di dandan nínú āyah òkè yìí láti sọ pé “Kí ni (Ànábì) Muhammad bí kò ṣe Òjíṣẹ́, tí àwọn Òjíṣẹ́ kan ti lọ ṣíwájú rẹ̀ (àyàfi ‘Īsā ọmọ Mọryam). Níwọ̀n ìgbà tí a sì ti rí àwọn hadīth tààrà kà lórí ìpadàbọ̀ Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), èyí ti fi rinlẹ̀ pé “àyàfi” wà fún òun nìkan ṣoṣo láààrin gbogbo àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù nípa pé òun nìkan ni kò ì kú.
____________________
Āyah yìí jẹ́ ọ̀kan pàtàkì nínú àwọn ẹ̀rí àtamọ́-àtọmọ̀ lọ́dọ̀ àwọn t’ó gbàgbọ́ pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ti kú. Wọ́n ní ikú rẹ̀ ti jẹyọ nínú “Kí ni (Ànábì) Muhammad bí kò ṣe Òjíṣẹ́, tí àwọn Òjíṣẹ́ kan ti lọ ṣíwájú rẹ̀” Èsì: Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé āyah náà ń sọ̀rọ̀ nípa ikú àwọn Ànábì àti àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu ('alaehim sọlātu wa salām) t’ó ṣíwájú Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam), kò pọn dandan kí āyah náà yà lọ síbi ọ̀rọ̀ nípa àì tí ì kú Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ẹ kíyè sí i, bí ọ̀rọ̀ bá wá ní àwòrán gbogbogbò nínú al-Ƙur’ān, kò túmọ̀ sí pé kò lè ní àyàfi nínú nínú āyah mìíràn tàbí nínú hadīth Ànábì t’ó fẹsẹ̀ rinlẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, nínú sūrah an-Nisā’; 4:117, Allāhu ń sọ̀rọ̀ nípa àwọn n̄ǹkan tí àwọn ènìyàn ń jọ́sìn fún lẹ́yìn Rẹ̀ pé, “Wọn kò pe kiní kan lẹ́yìn Allāhu bí kò ṣe àwọn abo òrìṣà.” Nínú ohun tí àwọn kan sì sọ di òrìṣà ni Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām). Ṣé abo sì ni òun náà ni tàbí akọ? Ìsọkúsọ l’ó sì máa jẹ́ láti pe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ní abo. Bẹ́ẹ̀ sì ni pé, Allāhu kò ṣe “àyàfi” nínú āyah “abo lòrìṣà”, àmọ́ ó yé wa nínú àwọn āyah mìíràn pé Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) kì í ṣe abo. Akọ ni.
Àpẹẹrẹ mìíràn fún mímú “àyàfi” fún āyah al-Ƙur’ān wá nínú hadīth, òhun ni pé nínú al-Ƙur’ān èèwọ̀ ni òkúǹbete ẹran. Nínú hadith Ànábì láti rí “àyàfi” sí èèwọ̀ náà. Àyàfi kìíní ni pé, awọ ẹran òkúǹbete tí wọ́n pa lósè kì í ṣe èèwọ̀ fún lílò fún ọ̀ṣọ́ ilé tàbí ọ̀ṣọ́ ara. Irú awọ ẹran òkúǹbete tí wọ́n pa lósè bẹ́ẹ̀ sì di ẹ̀tọ́ láti fi ṣe bàtà, bẹ́lítì, àpò aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àyàfi kejì: nínú hadīth l’a ti rí i kà pé ẹ̀tọ́ ni òkúǹbete gbogbo ẹran inú omi àti àwọn òkúǹbete ẹja. Bí kò ṣe sí ohun t’ó sọ ọ́ di dandan láti rí àwọn àyàfi wọ̀nyí nínú āyah náà, ohun náà l’ó jẹ́ kí á mọ̀ pé kò sí ohun t’ó sọ ọ́ di dandan nínú āyah òkè yìí láti sọ pé “Kí ni (Ànábì) Muhammad bí kò ṣe Òjíṣẹ́, tí àwọn Òjíṣẹ́ kan ti lọ ṣíwájú rẹ̀ (àyàfi ‘Īsā ọmọ Mọryam). Níwọ̀n ìgbà tí a sì ti rí àwọn hadīth tààrà kà lórí ìpadàbọ̀ Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām), èyí ti fi rinlẹ̀ pé “àyàfi” wà fún òun nìkan ṣoṣo láààrin gbogbo àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ yòókù nípa pé òun nìkan ni kò ì kú.
الترجمة اليورباوية