ترجمة سورة الشورى

الترجمة اليورباوية
ترجمة معاني سورة الشورى باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية .
من تأليف: أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني .

Hā mīm.
‘Aēn sīn ƙọ̄f.
Báyẹn ni Allāhu, Alágbára, Ọlọ́gbọ́n ṣe ń fi ìmísí ránṣẹ́ sí ìwọ àti àwọn t’ó ṣíwájú rẹ.
TiRẹ̀ ni ohunkóhun t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀. Ó ga, Ó tóbi.
Sánmọ̀ fẹ́ẹ̀ fàya láti òkè wọn (nípa títóbi Allāhu). Àwọn mọlāika sì ń ṣe àfọ̀mọ́ pẹ̀lú ìdúpẹ́ fún Olúwa wọn. Wọ́n sì ń tọrọ àforíjìn fún àwọn t’ó wà lórí ilẹ̀. Gbọ́ Mi, dájúdájú Allāhu, Òun ni Aláforíjìn, Àṣàkẹ́-ọ̀run.
Àwọn t’ó mú àwọn alátìlẹ́yìn kan lẹ́yìn Rẹ̀, Allāhu sì ni Aláàbò lórí wọn. Ìwọ sì kọ́ ni olùṣọ́ lórí wọn.
Báyẹn ni A ṣe fi al-Ƙur’ān ránṣẹ́ sí ọ ní èdè Lárúbáwá nítorí kí o lè fi ṣe ìkìlọ̀ fún ’Ummul-Ƙurọ̄ (ìyẹn, ará ìlú Mọkkah) àti ẹnikẹ́ni tí ó bá wà ní àyíká rẹ̀ (ìyẹn, ará ìlú yòókù), àti nítorí kí o lè fi ṣe ìkìlọ̀ nípa Ọjọ́ Àkójọ, tí kò sí iyèméjì nínú rẹ̀. Ìjọ kan yóò wà nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Ìjọ kan yó sì wà nínú Iná t’ó ń jò.
Tí ó bá jẹ́ pé Allāhu bá fẹ́, ìbá ṣe wọ́n ní ìjọ ẹlẹ́sìn ẹyọ kan. Ṣùgbọ́n Ó ń fi ẹni tí Ó bá fẹ́ sínú ìkẹ́ Rẹ̀. Àwọn alábòsí, kò sì níí sí aláàbò àti alárànṣe kan fún wọn.
Ṣé wọ́n mú àwọn aláàbò kan lẹ́yìn Rẹ̀ ni? Allāhu, Òun sì ni Aláàbò. Òun l’Ó ń sọ àwọn òkú di alààyè. Òun sì ni Alágbára lórí gbogbo n̄ǹkan.
Ohunkóhun tí ẹ bá yapa ẹnu nípa rẹ̀, ìdájọ́ rẹ̀ di ọ̀dọ̀ Allāhu. Ìyẹn ni Allāhu, Olúwa mi. Òun ni mo gbáralé. Ọ̀dọ̀ Rẹ̀ sì ni mo máa ṣẹ́rí padà sí (ní ti ìronúpìwàdà).
____________________
Àgbọ́yé méjì ni gbogbo tafsīr mú wá lórí gbólóhùn yìí “Ohunkóhun tí ẹ bá yapa ẹnu nípa rẹ̀, ìdájọ́ rẹ̀ di ọ̀dọ̀ Allāhu.” Ìkíní ni pé, lẹ́yìn tí Allāhu ti mú ìdájọ́ wá pé ’Islām nìkan ṣoṣo ni ẹ̀sìn àṣelà, àmọ́ tí àwọn aláìgbàgbọ́ yapa rẹ̀, kí àwa mùsùlùmí fi wọ́n sílẹ̀ títí di Ọjọ́ àjíǹde tí Allāhu máa fi ìdájọ́ Rẹ̀ mú ìlèrí ìyà Rẹ̀ ṣẹ lórí wọn. Pẹ̀lú àgbọ́yé yìí, āyah yìí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn āyah t’ó sọ̀kalẹ̀ ṣíwájú àwọn āyah t’ó ń pàṣẹ ìgbógun ti àwọn aláìgbàgbọ́ t’ó ń gbógun ti àwa mùsùlùmí àti āyah t’ó ń pàṣẹ gbígba owó-orí lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́ tí kò gbógun ti àwa mùsùlùmí. Ní àgbékalẹ̀ ọ̀rọ̀ mìíràn, āyah yìí ń pàrọwà sùúrù àti ìfaradà fún èyíkéyìí àwùjọ mùsùlùmí t’ó wà nípò ọ̀lẹ ní orílẹ̀ èdè tí àwọn kèfèrí bá ti ń lo òfin kèfèrí lé wa lórí. Sùúrù náà máa wà bẹ́ẹ̀ títí di ọjọ́ tí ọwọ́ àwa mùsùlùmí yóò ba èkù-idà, tí agbára sì máa jẹ́ ti ’Islām.
Àgbọ́yé kejì ni pé, kí á ṣẹ́rí gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ìyapa-ẹnu bá wáyé lórí wọn sínú al-Ƙur’ān, ọ̀rọ̀ Allāhu àti ìdájọ́ Rẹ̀. Pẹ̀lú àgbọ́yé yìí, āyah yìí jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn āyah t’ó ń pa wá láṣẹ láti fi al-Ƙur’an àti sunnah Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) yanjú àwọn ọ̀rọ̀ ìyapa-ẹnu, gẹ́gẹ́ bí sūrah an-Nisā’; 4:59.
Àṣìgbọ́ l’ó jẹ́ nígbà náà láti lérò pé āyah náà ń pa wá láṣẹ láti má ṣe mú ìdájọ́ wá lórí àwọn ọ̀rọ̀ ìyapa-ẹnu tí al-Ƙur’ān ti yanjú. Èyí sì máa mú ìtúmọ̀ wíwo ìbàjẹ́ níran lọ́wọ́. Nípasẹ̀ bẹ́ẹ̀ ìbàjẹ́ oníran-ànran àti àdádáálẹ̀ ẹ̀sìn nínú ’Islam sì máa gbòde kanrí láààrin àwọn ẹ̀dá. Àṣẹ wíwo ìbàjẹ́ níran títí dọjọ́ àjíǹde kò sì tọ̀dọ̀ Allāhu (s.a.w.t) wá nínú tírà sánmọ̀ kan kan.
(Òun ni) Olùpilẹ̀dá àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Ó ṣẹ̀dá àwọn obìnrin fun yín láti ara yín. Ó tún ṣẹ̀dá àwọn abo ẹran-ọ̀sìn láti ara àwọn akọ ẹran-ọ̀sìn. Ó ń mu yín pọ̀ sí i (nípa ìṣẹ̀dá yín ní akọ-abo). Kò sí kiní kan bí irú Rẹ̀. Òun sì ni Olùgbọ́, Olùríran.
TiRẹ̀ ni àwọn kọ́kọ́rọ́ àpótí-ọ̀rọ̀ àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Ó ń tẹ́ arísìkí sílẹ̀ fún ẹni tí Ó bá fẹ́. Ó sì ń díwọ̀n rẹ̀ (fún ẹlòmíìràn). Dájúdájú Òun ni Onímọ̀ nípa gbogbo n̄ǹkan.
(Allāhu) ṣe ní òfin fun yín nínú ẹ̀sìn (’Islām) ohun tí Ó pa ní àṣẹ fún (Ànábì) Nūh àti èyí tí Ó fi ránṣẹ́ sí ọ, àti ohun tí A pa láṣẹ fún (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm, (Ànábì) Mūsā àti (Ànábì) ‘Īsā pé kí ẹ gbé ẹ̀sìn náà dúró. Kí ẹ sì má ṣe pín sí ìjọ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ nínú rẹ̀. Wàhálà l’ó jẹ́ fún àwọn ọ̀ṣẹbọ nípa n̄ǹkan tí ò ń pè wọ́n sí (níbi mímú Allāhu ní ọ̀kan ṣoṣo). Allāhu l’Ó ń ṣẹ̀ṣà ẹni tí Ó bá fẹ́ sínú ẹ̀sìn Rẹ̀ (tí ò ń pè wọ́n sí). Ó sì ń fi ọ̀nà mọ ẹni tí ó bá ń ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀ (nípasẹ̀ ìronúpìwàdà).
(Àwọn ọ̀ṣẹbọ) kò sì pín sí ìjọ ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àfi lẹ́yìn tí ìmọ̀ (’Islām) dé bá wọn. (Wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀) nípasẹ̀ ọ̀tẹ̀ ààrin wọn (sí àwọn Ànábì). Tí kò bá jẹ́ pé ọ̀rọ̀ kan tí ṣíwájú lọ́dọ̀ Olúwa rẹ (pé Òun yóò lọ́ wọn lára) títí di gbèdéke àkókò kan ni, Wọn ìbá ti dájọ́ láààrin wọn. Dájúdájú àwọn tí A jogún Tírà fún lẹ́yìn wọn sì tún wà nínú iyèméjì t’ó gbópọn nípa ’Islām.
Nítorí ìyẹn, pèpè (sínú ’Islām), kí o sì dúró ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí Wọ́n ṣe pa ọ́ lásẹ. Má sì ṣe tẹ̀lé ìfẹ́-inú wọn. Kí o sì sọ pé: "Mo gbàgbọ́ nínú èyíkéyìí Tírà tí Allāhu sọ̀kalẹ̀. Wọ́n sì pa mí láṣẹ pé kí n̄g ṣe déédé láààrin yín. Allāhu ni Olúwa wa àti Olúwa yín. Tiwa ni àwọn iṣẹ́ wa. Tiyín sì ni àwọn iṣẹ́ yín. Kò sí ìjà láààrin àwa àti ẹ̀yin. Allāhu l’Ó sì máa kó wa jọ papọ̀. Ọ̀dọ̀ Rẹ̀ sì ní àbọ̀ ẹ̀dá.”
____________________
Ìyẹn ṣíwájú àwọn āyah t’ó ń páṣẹ ogun ẹ̀sìn jíjà.
Àwọn t’ó ń bá (Ànábì s.a.w.) jà nípa (ẹ̀sìn) Allāhu lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ènìyàn ti gbà fún un, ẹ̀rí wọn máa wó lọ́dọ̀ Olúwa wọn. Ìbínú ń bẹ lórí wọn. Ìyà líle sì wà fún wọn.
Allāhu ni Ẹni tí Ó sọ Tírà (al-Ƙur’ān) àti (òfin) òṣùwọ̀n (déédé) kalẹ̀ pẹ̀lú òdodo. Àti pé kí l’ó máa fi mọ̀ ọ́ pé ó ṣeé ṣe kí Àkókò náà ti súnmọ́!
____________________
Ẹ wo sūrah ar-Rahmọ̄n; 55: 7-9.
Àwọn tí kò gbà á gbọ́ ń wá a pẹ̀lú ìkánjú. Àwọn t’ó sì gbàgbọ́ ní òdodo ń páyà rẹ̀. Wọ́n sì mọ̀ pé dájúdájú òdodo ni. Kíyè sí i, dájúdájú àwọn t’ó ń jiyàn nípa Àkókò náà ti wà nínú ìṣìnà t’ó jìnnà.
Allāhu ni Aláàánú fún àwọn ẹrúsìn Rẹ̀. Ó ń ṣe arísìkí fún ẹni tí Ó bá fẹ́. Òun sì ni Alágbára, Abiyì.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbèrò láti gba èso (iṣẹ́ rẹ̀ ní) ọ̀run, A máa ṣe àlékún sí èso rẹ̀ fún un. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbèrò láti gba èso (iṣẹ́ rẹ̀ ní) ayé, A máa fún un nínú rẹ̀. Kò sì níí sí ìpín kan kan fún un mọ́ ní ọ̀run.
Tàbí wọ́n ní àwọn òrìṣà kan t’ó ṣòfin (ìbọ̀rìṣà) fún wọn nínú ẹ̀sìn, èyí tí Allāhu kò yọ̀ǹda rẹ̀? Tí kò bá jẹ́ ti ọ̀rọ̀ àsọyán (pé A ò níí kánjú jẹ wọ́n níyà), Àwa ìbá ti mú ìdájọ́ wá láààrin wọn. Dájúdájú àwọn alábòsí, ìyà ẹlẹ́ta-eléro sì wà fún wọn.
O máa rí àwọn alábòsí tí wọn yóò máa páyà nítorí ohun tí wọ́n ṣe níṣẹ́, tí ó sì máa kò lé wọn lórí. Àwọn t’ó sì gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ṣe iṣẹ́ rere máa wà ní àwọn àyè t’ó rẹwà jùlọ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Ohun tí wọ́n bá ń fẹ́ máa wà fún wọn ní ọ̀dọ̀ Olúwa wọn. Ìyẹn, òhun ni oore àjùlọ t’ó tóbi.
Ìyẹn ni èyí tí Allāhu fi ń ṣe ìró ìdùnnú fún àwọn ẹrúsìn Rẹ̀, àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere. Sọ pé: "Èmi kò bèèrè owó-ọ̀yà lọ́wọ́ yín lórí rẹ̀ bí kò ṣe ìfẹ́ ẹbí.” Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe rere kan, A máa ṣe àlékún rere fún un. Dájúdájú Allāhu ni Aláforíjìn, Ọlọ́pẹ́.
____________________
Ìyẹn ni pé, Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ń sọ fún àwọn ẹbí rẹ̀ pé, ẹ má ṣe tìtorí pé mò ń pèyín sínú ẹ̀sìn ’Islām kí ẹ wá máa fi ìnira kan èmi àti àwọn ará ilé mi. Èmi kò kúkú bèèrè owó-ọ̀yà kan kan lọ́wọ́ yín. Ẹ sì mọ̀ pé ẹbí ni wá. Ẹbí sì gbọ́dọ̀ ní ìfẹ́ ẹbí rẹ̀. Nítorí náà, ẹ má ṣe fi fífi ìnira kan ará ilé mi ṣe ẹ̀san fún mi.
Tàbí wọ́n ń wí pé: "Ó dá àdápa irọ́ mọ́ Allāhu ni?" Nítorí náà, tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa fi èdídí dí ọkàn rẹ pa. Àti pé Allāhu yóò pa irọ́ rẹ́. Ó sì máa fi òdodo rinlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Rẹ̀. Dájúdájú Òun ni Onímọ̀ nípa ohun t’ó wà nínú igbá-àyà ẹ̀dá.
Òun ni Ẹni t’Ó ń gba ìronúpìwàdà àwọn ẹrúsìn Rẹ̀. Ó ń ṣe àmójúkúrò níbi àwọn àṣìṣe. Ó sì mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
Ó ń gba àdúà àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere. Ó sì ń ṣe àlékún fún wọn nínú ọlá Rẹ̀. Àwọn aláìgbàgbọ́, ìyà líle sì wà fún wọn.
Tí ó bá jẹ́ pé Allāhu tẹ́ arísìkí sílẹ̀ rẹgẹdẹ fún àwọn ẹrúsìn Rẹ̀ ni, wọn ìbá tayọ ẹnu-àlà lórí ilẹ̀. Ṣùgbọ́n Ó ń sọ (arísìkí) tí Ó bá fẹ́ kalẹ̀ níwọ̀n-níwọ̀n. Dájúdájú Òun ni Alámọ̀tán, Olùríran nípa àwọn ẹrúsìn Rẹ̀.
Òun sì ni Ẹni t’Ó ń sọ omi òjò kalẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti sọ̀rètí nù. Ó sì ń fọ́n ìkẹ́ Rẹ̀ ká. Òun sì ni Aláàbò, Ẹlẹ́yìn.
Àti pé nínú àmì Rẹ̀ ni ìṣẹ̀dá àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti n̄ǹkan tí Ó fọ́nká sáààrin méjèèjì nínú àwọn n̄ǹkan abẹ̀mí. Òun sì ni Alágbára lórí ìkójọ wọn nígbà tí Ó bá fẹ́.
Ohunkóhun tí ó bá kàn yín nínú àdánwò, ohun tí ẹ fi ọwọ́ ara yín fà ni. Ó sì ń ṣàmójúkúrò níbi ọ̀pọ̀lọ́pọ̀.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah an-Nisā’; 4O:79.
Ẹ̀yin kò sì níí mórí bọ́ (mọ́ Allāhu lọ́wọ́) lórí ilẹ̀. Kò sí aláàbò àti alárànṣe kan fun yín lẹ́yìn Allāhu.
Ó tún wà nínú àwọn àmì Rẹ̀, àwọn ọkọ̀ ojú-omi t’ó ń rìn lójú omi (t’ó dà) bí àwọn òkè àpáta gíga.
Tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa mú atẹ́gùn náà dúró, (àwọn ọkọ̀ ojú-omi náà) sì máa di ohun tí kò níí lọ mọ́ lórí omi. Dájúdájú àwọn àmì wà nínú ìyẹn fún gbogbo onísùúrù, olùdúpẹ́.
Tí Allāhu bá fẹ́, Ó máa mú atẹ́gùn náà dúró, (àwọn ọkọ̀ ojú-omi náà) sì máa di ohun tí kò níí lọ mọ́ lórí omi. Dájúdájú àwọn àmì wà nínú ìyẹn fún gbogbo onísùúrù, olùdúpẹ́.
Àwọn t’ó ń ṣe àtakò sí àwọn āyah Wa sì máa mọ̀ pé kò sí ibùsásí kan fún wọn.
Nítorí náà, ohunkóhun tí A bá fun yín, ìgbádùn ayé nìkan ni. Ohun tí ó wà lọ́dọ̀ Allāhu lóore jùlọ, ó sì máa ṣẹ́kù títí láéláé fún àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ń gbáralé Olúwa wọn.
(Ohun tí ó wà lọ́dọ̀ Allāhu tún wà fún) àwọn t’ó ń jìnnà sí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ńláńlá àti àwọn ìwà ìbàjẹ́, àti (àwọn t’ó jẹ́ pé) nígbà tí wọ́n bá bínú, wọ́n yóò ṣàforíjìn.
(Ohun tí ó wà lọ́dọ̀ Allāhu tún wà fún) àwọn t’ó jẹ́pè ti Olúwa wọn, tí wọ́n ń kírun, ọ̀rọ̀ ara wọn sì jẹ́ ìjíròrò láààrin ara wọn, wọ́n tún ń ná nínú arísìkí tí A pèsè fún wọn.
(Ohun tí ó wà lọ́dọ̀ Allāhu tún wà fún) àwọn tí (ó jẹ́ pé) nígbà tí wọ́n bá ṣe àbòsí sí wọn, wọn yóò gbẹ̀san wọn padà.
Ẹ̀san aburú sì ni aburú bí irú rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ṣàmójúkúrò, tí ó tún ṣàtúnṣe, ẹ̀san rẹ̀ wà lọ́dọ̀ Allāhu. Dájúdájú (Allāhu) kò nífẹ̀ẹ́ àwọn alábòsí.
____________________
Kíyè sí i, gbólóhùn yìí “Ẹ̀san aburú sì ni aburú bí irú rẹ̀.” kò tako sūrah Fussilat; 41:31. Ìdí ni pé, gbígba ẹ̀san lára alábòsí tàbí gbígba ààrọ̀ kò sọ pé mùsùlùmí kò ní ẹ̀mí àforíjìn, àmọ́ ó lè má nìí agbára láti ṣàmójú kúrò fún alábòsí náà. Bí àpẹẹrẹ, kí ẹnì kan ba dúkìá mùsùlùmí jẹ́, yálà ó ṣèèsì tàbí ó mọ̀ọ́mọ̀, mùsùlùmí lè gbẹ̀san ààrọ̀ níwọ̀n ìgbà tí agbára rẹ̀ kò bá gbé àtúnṣe rẹ̀ tàbí ìràpadà rẹ̀. Kò sì níí gbà ju ohun tí wọ́n bàjẹ́ lọ. Àti pé tí kò bá sí òfin ẹ̀san gbígbà rárá, àwọn ènìyàn kò níí yé máa fi ìnira àti aburú kan àwọn ẹlòmíìràn. Nítorí náà, ẹ̀san gbígbà tàbí ààrọ̀ gbígbà kò sọ mùsùlùmí di ẹni tí kò lẹ́mìí àforíjìn gẹ́gẹ́ bí àwọn kan ṣe lérò láti fi ba àwa mùsùlùmí lórúkọ jẹ́.
Dájúdájú ẹni tí ó bá sì gbẹ̀san lẹ́yìn tí wọ́n ṣe àbòsí sí i, àwọn wọ̀nyẹn (tí wọ́n ṣàbòsí sí), kò sí ìbáwí kan kan fún wọn.
Àwọn tí ìbáwí wà fún ni àwọn t’ó ń ṣàbòsí sí àwọn ènìyàn, tí wọ́n tún ń tayọ ẹnu-àlà lórí ilẹ̀ láì lẹ́tọ̀ọ́. Àwọn wọ̀nyẹn ni ìyà ẹlẹ́ta-eléro wà fún.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe sùúrù, tí ó tún ṣàforíjìn, dájúdájú ìyẹn wà nínú àwọn ìpinnu ọ̀rọ̀ t’ó pọn dandan.
Ẹnikẹ́ni tí Allāhu bá ṣì lọ́nà, kò tún sí aláàbò kan fún un mọ́ lẹ́yìn Rẹ̀. O sì máa rí àwọn alábòsí nígbà tí wọ́n bá rí Iná, wọn yóò wí pé: "Ǹjẹ́ ọ̀nà kan kan wà tí a lè fi padà sí ilé ayé?"
O sì máa rí wọn tí A máa kó wọn lọ sínú Iná; wọn yóò palọ́lọ́ láti ara ìyẹpẹrẹ, wọn yó si máa wò fín-ín-fín. Àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo sì máa sọ pé: "Dájúdájú àwọn ẹni òfò ni àwọn t’ó ṣe ẹ̀mí ara wọn àti ara ilé wọn ní òfò ní Ọjọ́ Àjíǹde." Kíyè sí i, dájúdájú àwọn alábòsí yóò wà nínú ìyà gbére.
Kò sì níí sí aláàbò kan fún wọn tí ó máa ràn wọ́n lọ́wọ́ lẹ́yìn Allāhu. Àti pé ẹnikẹ́ni tí Allāhu bá ṣì lọ́nà, kò lè sí ọ̀nà kan kan fún un.
Ẹ jẹ́pè Olúwa yín ṣíwájú kí ọjọ́ kan tó de, tí kò sí ìdápadà kan fún un ní ọ̀dọ̀ Allāhu. Kò sí ibùsásí kan fun yín ní ọjọ́ yẹn. Kò sì níí sí olùkọ̀yà kan fun yín.
Nítorí náà, tí wọ́n bá gbúnrí, A ò rán ọ pé kí o jẹ́ olùṣọ́ fún wọn. Kò sí kiní kan t’ó di dandan fún ọ bí kò ṣe iṣẹ́-jíjẹ́. Àti pé dájúdájú nígbà tí A bá fún ènìyàn ní ìkẹ́ kan tọ́ wò láti ọ̀dọ̀ Wa, ó máa dunnú sí i. Tí aburú kan bá sì kàn án nípasẹ̀ ohun tí ọwọ́ wọn tì ṣíwájú (ní iṣẹ́ aburú), dájúdájú ènìyàn ni aláìmoore.
Ti Allāhu ni ìjọba àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀. Ó ń ṣẹ̀dá ohun tí Ó bá fẹ́. Ó ń ta ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́rẹ ọmọbìnrin. Ó sì ń ta ẹni tí Ó bá fẹ́ ní lọ́rẹ ọmọkùnrin.
Tàbí kí Ó ṣe wọ́n ní oríṣi méjì; ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ó sì ń ṣe ẹni tí Ó bá fẹ́ ní àgàn. Dájúdájú Òun ni Onímọ̀, Alágbára.
Kò lẹ́tọ̀ọ́ fún abara kan pé kí Allāhu bá a sọ̀rọ̀ àfi kí (ọ̀rọ̀ náà) jẹ́ ìmísí (ìṣípayá mímọ́), tàbí kí ó jẹ́ lẹ́yìn gàgá, tàbí kí Ó rán Òjíṣẹ́ kan (tí
ó jẹ́ mọlāika) sí i, ó sì máa fi ìmísí jíṣẹ́ fún (abara náà) pẹ̀lú ìyọ̀ǹda (Allāhu). Dájúdájú Ó ga. Ọlọ́gbọ́n sì ni.
Báyẹn sì ni A ṣe fi ìmísí ránṣẹ́ sí ọ nínú àṣẹ Wa. Ìwọ kò mọ kí ni Tírà àti ìgbàgbọ́ òdodo tẹ́lẹ̀ (ṣíwájú ìmísí náà),1 ṣùgbọ́n A ṣe ìmísí náà ní ìmọ́lẹ̀ kan tí À ń fi ṣe ìmọ̀nà fún ẹni tí A bá fẹ́ nínú àwọn ẹrúsìn Wa. Dájúdájú ìwọ ń pèpè sí ọ̀nà tààrà (’Islām). 2
____________________
1. Āyah yìí ń fi kókó pàtàkì kan rinlẹ̀ nípa ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí ayé Ànábì wa Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) pé, ṣíwájú kí ìmísí mímọ́ tó bẹ̀rẹ̀ sí ṣọ̀kalẹ̀ fún un kò sí nínú ẹni t’ó nímọ̀ sí tírà sánmọ̀ kan kan, kò sì dá ìgbàgbọ́ òdodo mọ. Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) tún fi èyí rinlẹ̀ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah ad-Duhā; 93: 7. Àmọ́ níkété tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) bẹ̀rẹ̀ sí gba ìmísí mímọ́, Allāhu fi ìmọ̀ tírà al-Ƙur’ān àti ìgbàgbọ́ òdodo mọ̀ ọ́n. Ó sì di olùpèpè sínú ìmọ̀nà. Ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ àwọn Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun ni ìṣẹ̀mí ayé wọn rí bí Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ti ṣe rí àfi ẹni tí bàbá rẹ̀ bá jẹ́ Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun. Àmọ́ ṣá, kò sí abọ̀rìṣà kan tí Allāhu sọ di Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ Rẹ̀ rí. Ẹni tí Allāhu máa sọ di Ànábì tàbí Òjíṣẹ́ lè má tí ì mọ tírà nígbà tí Ọlọ́hun kò ì tí ì fún un, ó sì lè má tí ì dá ìgbàgbọ́ òdodo mọ̀, nígbà tí Ọlọ́hun kò tí ì ròyìn Ara Rẹ̀ fún un, àmọ́ kò níí sí nínú àwọn ọ̀ṣẹbọ tàbí àwọn òbìlẹ̀jẹ́ ènìyàn. Kódà, láti kékeré wọn ni Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ti máa ń jogún òye fún wọn pé, “irọ́ lòrìṣà” títí àsìkò ìmísí wọn yóò fi dé.
Síwájú sí i, tí ẹnì kan bá sì sọ pé, iṣẹ́ wiridi ni Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) máa ń ṣe nínú ọ̀gbun Hirā ṣíwájú kí ó tó di Ànábì Ọlọ́hun, irọ́ l’ó fi pa. Ìdí ni pé, ẹnì kan kì í ṣe wiridi láì gbọwọ́, ta ni ó fún Ànábì lọ́wọ́ wiridi? Kò sí. Bákan náà, kò sí ojú ọ̀nà wiridi tí kò lórúkọ, kí ni orúkọ tọrikọ sūfī tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ṣe? Kò sí. Èyí t’ó wá kó ọ̀rọ̀ tán nílẹ̀ ni pé, títẹ̀lé Muhammad ọmọ ‘Abdullah (sollalāhu 'alayhi wa sallam), kò di ẹ̀sìn àfi láti àsìkò tí ó di Ànábì àti Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun. Kò sì lọ sínú ọ̀gbun Hirā mọ́ bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí mọlāika Jibrīl ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) ti fún ní ìmísí àkọ́kọ́. Nítorí náà, Ànábì kì í ṣe sūfī, kò sì ṣe wiridi sūfī rí. 2. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Ƙọsọs; 28:56.
Ọ̀nà Allāhu, Ẹni tí ohunkóhun t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ohunkóhun t’ó wà nínú ilẹ̀ ń jẹ́ tiRẹ̀. Gbọ́! Ọ̀dọ̀ Allāhu ni àwọn ọ̀rọ̀ ẹ̀dá yóò padà sí.
Icon