Òjíṣẹ́ náà (sollalāhu 'alayhi wa sallam) gbàgbọ́ nínú ohun tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀. Àwọn onígbàgbọ́ òdodo náà (gbàgbọ́ nínú rẹ̀). Ẹnì kọ̀ọ̀kan (wọn) gbàgbọ́ nínú Allāhu, àwọn mọlāika Rẹ̀, àwọn Tírà Rẹ̀ àti àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀. A kò ya ẹnì kan sọ́tọ̀ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Rẹ̀. Wọ́n sì sọ pé: “A gbọ́ (àṣẹ), a sì tẹ̀lé (àṣẹ). À ń tọrọ àforíjìn Rẹ, Olúwa wa. Ọ̀dọ̀ Rẹ sì ni àbọ̀ ẹ̀dá.”
____________________
Kíyè sí i, ìgbàgbọ́ àwa ọmọlẹ́yìn Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) nínú àwọn Tírà àti àwọn Òjíṣẹ́ t’ó ṣíwájú (ahm.s.w.) tí gbogbo wọ́n jẹ́ ẹlẹ́sìn ’Islām, kò túmọ̀ sí títẹ̀lé wọn nínú ìlànà ìjọ́sìn wọn àti ìdájọ́ ṣíṣe ní àsìkò yìí. Ìdí ni pé, nínú oore àjùlọ tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe fún Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ni pé, bí àwọn Òjíṣẹ́ alápọ̀n-ọ́nlé wọ̀nyí bá fi lè wà lórí ilẹ̀ ayé títí di àsìkò Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam), àti àwọn àti ọmọlẹ́yìn wọn, wọ́n gbọ́dọ̀ tẹ̀lé Ànábì wa, wọ́n sì gbọ́dọ̀ tẹ̀lé al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé dípò tírà tiwọn. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:81. Ìdí nìyí tí ó sì fi jẹ́ pé, nígbà tí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) bá padà sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ ní òpin ayé, al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé ni tírà tí ó máa tẹ̀lé nínú ìlànà ìjọ́sìn rẹ̀ àti ìdájọ́ ṣíṣe. Irú oore àjùlọ yìí jẹ́ oore ẹ̀ṣà fún Ànábì wa nìkan ṣoṣo (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Bí àpẹẹrẹ, ní àsìkò Ànábì Mūsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) àti Kidr (rọdiyallāhu 'anhu), ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ìlànà ìjọ́sìn àti ìdájọ́ ṣíṣe tí Allāhu fún àwọn méjèèjì. Irú èyí kò lè ṣẹlẹ̀ ní àsìkò ti Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Nítorí náà, tí ẹnikẹ́ni bá ṣe bí Kidr ní àsìkò Ànábì wa, tí ó sì tẹ̀lé ìlànà ìjọ́sìn àti ìdájọ́ mìíràn yàtọ̀ sí èyí tí Ànábì wa mú wá, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti di òbìlẹ̀jẹ́. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:82.
____________________
Kíyè sí i, ìgbàgbọ́ àwa ọmọlẹ́yìn Ànábì Muhammad (sollalāhu 'alayhi wa sallam) nínú àwọn Tírà àti àwọn Òjíṣẹ́ t’ó ṣíwájú (ahm.s.w.) tí gbogbo wọ́n jẹ́ ẹlẹ́sìn ’Islām, kò túmọ̀ sí títẹ̀lé wọn nínú ìlànà ìjọ́sìn wọn àti ìdájọ́ ṣíṣe ní àsìkò yìí. Ìdí ni pé, nínú oore àjùlọ tí Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe fún Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam) ni pé, bí àwọn Òjíṣẹ́ alápọ̀n-ọ́nlé wọ̀nyí bá fi lè wà lórí ilẹ̀ ayé títí di àsìkò Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam), àti àwọn àti ọmọlẹ́yìn wọn, wọ́n gbọ́dọ̀ tẹ̀lé Ànábì wa, wọ́n sì gbọ́dọ̀ tẹ̀lé al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé dípò tírà tiwọn. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:81. Ìdí nìyí tí ó sì fi jẹ́ pé, nígbà tí Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) bá padà sọ̀kalẹ̀ láti ojú sánmọ̀ ní òpin ayé, al-Ƙur’ān Alápọ̀n-ọ́nlé ni tírà tí ó máa tẹ̀lé nínú ìlànà ìjọ́sìn rẹ̀ àti ìdájọ́ ṣíṣe. Irú oore àjùlọ yìí jẹ́ oore ẹ̀ṣà fún Ànábì wa nìkan ṣoṣo (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Bí àpẹẹrẹ, ní àsìkò Ànábì Mūsā ('alaehi-ssọlātu wa-ssalām) àti Kidr (rọdiyallāhu 'anhu), ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ìlànà ìjọ́sìn àti ìdájọ́ ṣíṣe tí Allāhu fún àwọn méjèèjì. Irú èyí kò lè ṣẹlẹ̀ ní àsìkò ti Ànábì wa (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Nítorí náà, tí ẹnikẹ́ni bá ṣe bí Kidr ní àsìkò Ànábì wa, tí ó sì tẹ̀lé ìlànà ìjọ́sìn àti ìdájọ́ mìíràn yàtọ̀ sí èyí tí Ànábì wa mú wá, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti di òbìlẹ̀jẹ́. Èyí wà ní ìbámu sí sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:82.
الترجمة اليورباوية