ترجمة معاني سورة الطور باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﮞ
ﮟ
(Allāhu búra pẹ̀lú) àpáta Tūr.
آية رقم 2
ﮠﮡ
ﮢ
(Ó tún búra pẹ̀lú) Tírà tí wọ́n kọ sílẹ̀
آية رقم 3
ﮣﮤﮥ
ﮦ
sínú tákàdá tí wọ́n tẹ́ sílẹ̀.
آية رقم 4
ﮧﮨ
ﮩ
(Ó tún búra pẹ̀lú) Ilé Àbẹ̀wò náà.
آية رقم 5
ﮪﮫ
ﮬ
(Ó tún búra pẹ̀lú) àjà tí wọ́n gbé sókè (ìyẹn, sánmọ̀).
آية رقم 6
ﮭﮮ
ﮯ
(Ó tún búra pẹ̀lú) agbami odò iná.
آية رقم 7
ﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Dájúdájú ìyà Olúwa rẹ máa ṣẹlẹ̀.
آية رقم 8
ﯖﯗﯘﯙ
ﯚ
Kò sí olùdènà kan fún un.
آية رقم 9
ﯛﯜﯝﯞ
ﯟ
(Ó máa ṣẹlẹ̀) ní ọjọ́ tí sánmọ̀ máa mì tìtì tààrà.
آية رقم 10
ﯠﯡﯢ
ﯣ
Àwọn àpáta sì máa rìn lọ tààrà (bí eruku àfẹ́dànù).
آية رقم 11
ﯤﯥﯦ
ﯧ
Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo-nírọ́,
آية رقم 12
ﯨﯩﯪﯫﯬ
ﯭ
àwọn tí wọ́n wà nínú ìsọkúsọ, tí wọ́n ń ṣeré.
آية رقم 13
ﯮﯯﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
(Rántí) ọjọ́ tí wọn yóò tì wọ́n lọ́ sínú iná Jahanamọ ní ìtìkutì.
آية رقم 14
ﯵﯶﯷﯸﯹﯺ
ﯻ
Èyí ni Iná náà tí ẹ̀ ń pè nírọ́.
آية رقم 15
ﭑﭒﭓﭔﭕﭖ
ﭗ
Ṣé idán ni èyí ni tàbí ẹ ò ríran?
آية رقم 16
Ẹ wọ inú rẹ̀ lọ. Ẹ fara dà á tàbí ẹ ò fara dà á, bákan náà ni fun yín. Ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́ ni A óò fi san yín ní ẹ̀san.
آية رقم 17
ﭦﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Dájúdájú àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu) máa wà nínú àwọn Ọgbà àti ìdẹ̀ra.
آية رقم 18
Wọn yóò máa jẹ ìgbádùn pẹ̀lú ohun tí Olúwa wọn fún wọn. Àti pé (Allāhu) yóò ṣọ́ wọn nínú ìyà iná Jẹhīm.
آية رقم 19
ﭵﭶﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
Ẹ máa jẹ, ẹ máa mu ní gbẹdẹmukẹ nítorí ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
آية رقم 20
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí àwọn ibùsùn tí wọ́n tò ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. A sì máa fún wọn ní àwọn ìyàwó ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́.
آية رقم 21
Àti pé àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn tún tẹ̀lé wọn nínú ìgbàgbọ́ òdodo, A máa da àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn pọ̀ mọ́ wọn. A ò sì níí dín kiní kan kù nínú iṣẹ́ wọn. Ẹnì kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
آية رقم 22
ﮚﮛﮜﮝﮞ
ﮟ
A máa fún wọn ní àlékún èso àti ẹran tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí.
آية رقم 23
Wọn yó sì máa gba ife ọtí mu láààrin ara wọn nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra. Kò sí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ àti ìwà ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
آية رقم 24
Àwọn ọmọ-ọ̀dọ̀ wọn yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn. (Wọ́n) dà bí àlúùúlù àfipamọ́.
آية رقم 25
ﯓﯔﯕﯖﯗ
ﯘ
Apá kan wọn yóò dojú kọ apá kan, wọn yó sì máa bèèrè ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ara wọn.
آية رقم 26
Wọn yóò sọ pé: "Dájúdájú tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀ àwa jẹ́ olùpáyà láààrin àwọn ènìyàn wa.
آية رقم 27
ﯡﯢﯣﯤﯥﯦ
ﯧ
Ṣùgbọ́n Allāhu ṣàánú wa. Ó sì là wá níbi ìyà Iná.
آية رقم 28
Dájúdájú àwa máa ń pè É tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀. Dájúdájú Allāhu, Òun ni Olóore, Àṣàkẹ́-ọ̀run."
آية رقم 29
Nítorí náà, ṣèrántí. Ìwọ kì í ṣe adábigba tàbí wèrè lórí ìdẹ̀ra Olúwa rẹ.
آية رقم 30
Tàbí wọ́n ń wí pé: "Eléwì kan tí à ń retí ikú rẹ̀ ni."
آية رقم 31
ﰄﰅﰆﰇﰈﰉ
ﰊ
Sọ pé: "Ẹ máa retí. Dájúdájú èmi náà wà pẹ̀lú yín nínú àwọn olùretí.
آية رقم 32
Tàbí ọpọlọ wọn ń pa wọ́n láṣẹ èyí ni? Tàbí ìjọ alákọyọ ni wọ́n ni?
آية رقم 33
Tàbí wọ́n ń wí pé: "Ó dá (al-Ƙur’ān) hun fúnra rẹ̀ ni." Rárá o, wọn kò gbàgbọ́ ni.
آية رقم 34
ﭣﭤﭥﭦﭧﭨ
ﭩ
Kí àwọn náà mú ọ̀rọ̀ kan bí irú rẹ̀ wá tí wọ́n bá jẹ́ olódodo.
آية رقم 35
Tàbí wọ́n ṣẹ̀dá wọn láì sí Aṣẹ̀dá? Tàbí àwọn ni wọ́n ṣẹ̀dá ara wọn ni?
آية رقم 36
Tàbí àwọn ni wọ́n ṣẹ̀dá àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀? Rárá o, wọn kò màmọ̀ dájú ni.
آية رقم 37
Tàbí lọ́dọ̀ wọn ni àwọn àpótí ọrọ̀ Olúwa rẹ wà? Tàbí àwọn ni olùborí?
آية رقم 38
Tàbí wọ́n ní àkàbà tí wọ́n ń fi gbọ́rọ̀ (nínú sánmọ̀ ni)? Kí olùgbọ́rọ̀ wọn mú ẹ̀rí pọ́nńbélé wá?
آية رقم 39
ﮏﮐﮑﮒﮓ
ﮔ
Tàbí àwọn ọmọbìnrin ni tiRẹ̀, àwọn ọmọkùnrin sì ni tiyín?
آية رقم 40
Tàbí ò ń bèèrè owó-ọ̀yà kan lọ́dọ̀ wọn, ni gbèsè fi wọ̀ wọ́n lọ́rùn?
آية رقم 41
ﮝﮞﮟﮠﮡ
ﮢ
Tàbí ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ wà lọ́dọ̀ wọn, tí wọ́n sì ń kọ ọ́ sílẹ̀?
آية رقم 42
Tàbí wọ́n ń gbèrò ète kan ni? Nígbà náà, àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, àwọn l’ó máa f’orí kó ète.
آية رقم 43
Tàbí wọ́n ní ọlọ́hun kan lẹ́yìn Allāhu ni? Mímọ́ ni fún Allāhu tayọ n̄ǹkan tí wọ́n ń fi ṣẹbọ sí I.
آية رقم 44
Tí wọ́n bá sì rí apá kan nínú sánmọ̀ t’ó ya lúlẹ̀, wọ́n á wí pé: "Ẹ̀ṣújò rẹgẹdẹ ni (wọn kò níí gbàgbọ́)."
آية رقم 45
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ títí wọn yóò fi bá ọjọ́ wọn tí wọn máa pa wọ́n sínú rẹ̀ pàdé.
آية رقم 46
Ọjọ́ tí ète wọn kò níí fi kiní kan rọ̀ wọ́n lọ́rọ̀. A ò sì níí ràn wọ́n lọ́wọ́.
آية رقم 47
Àti pé dájúdájú ìyà kan ń bẹ fún àwọn t’ó ṣàbòsí yàtọ̀ sí (ìyà ọ̀run) yẹn, ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn ni kò mọ̀.
آية رقم 48
Ṣe sùúrù fún ìdájọ́ Olúwa Rẹ, dájúdájú ìwọ wà ní ojútó Wa. Kí ó sì ṣe àfọ̀mọ́ pẹ̀lú ìdúpẹ́ fún Olúwa rẹ nígbà tí ó bá ń dìde nàró (fún ìrun kíkí).
آية رقم 49
ﰋﰌﰍﰎﰏ
ﰐ
Àti ní alẹ́ (nígbà tí) àwọn ìràwọ̀ bá kúrò níta tán, ṣàfọ̀mọ́ fún Un.
تقدم القراءة