ترجمة معاني سورة الواقعة باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﮃﮄﮅ
ﮆ
Nígbà tí Ìṣẹ̀lẹ̀ (Àjíǹde) bá ṣẹlẹ̀,
آية رقم 2
ﮇﮈﮉ
ﮊ
- kò sí irọ́ kan nípa ìṣẹ̀lẹ̀ rẹ̀-E4983
آية رقم 3
ﮋﮌ
ﮍ
ó máa mú (àwọn kan) wálẹ̀ (sínú Iná), ó sì máa gbé (àwọn kan) sókè (nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra).
آية رقم 4
ﮎﮏﮐﮑ
ﮒ
Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní mímìtìtì,
آية رقم 5
ﮓﮔﮕ
ﮖ
àti nígbà tí Wọ́n bá fọ́ àwọn àpáta ní fífọ́ wómúwómú,
آية رقم 6
ﮗﮘﮙ
ﮚ
- wọ́n sì máa di eruku àfẹ́dànù - E4987
آية رقم 7
ﮛﮜﮝ
ﮞ
ẹ̀yin sì máa jẹ́ oríṣi mẹ́ta.
____________________
Àwọn kristiẹni lérò pé āyah t’ó pín ẹ̀dá sí mẹ́ta ní ọjọ́ Àjíǹde tako āyah t’ó pín wọn sí ìjọ méjì.
Èsì: Kò sí ìtakora láààrin wọn. Nínú sūrah yìí, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ pé oríṣi ìjọ mẹ́ta ni àwọn ẹ̀dá máa pín sí ní ọjọ́ Àjíǹde. Ìjọ ọ̀tún, ìjọ òsì àti ìjọ aṣíwájú. Àmọ́ nínú sūrah al-Balad; 90:18-19 àti sūrah az-Zalzalah; 99:6-8, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pín wọn sí ìjọ méjì. Ìjọ méjì kúkú ni gbogbo ẹ̀dá ní ọ̀run, ìjọ ọ̀tún àti ìjọ òsì nítorí pé, Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ nípa ìgbádùn ìjọ aṣíwájú láti āyah 10 sí āyah 26. Ó sọ nípa ìgbádùn ìjọ ọ̀tún láti āyah 27 sí āyah 40. Ó sì sọ nípa oníran-ànran ìyà ìjọ òsì láti āyah 41 sí āyah 56.
____________________
Àwọn kristiẹni lérò pé āyah t’ó pín ẹ̀dá sí mẹ́ta ní ọjọ́ Àjíǹde tako āyah t’ó pín wọn sí ìjọ méjì.
Èsì: Kò sí ìtakora láààrin wọn. Nínú sūrah yìí, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) sọ pé oríṣi ìjọ mẹ́ta ni àwọn ẹ̀dá máa pín sí ní ọjọ́ Àjíǹde. Ìjọ ọ̀tún, ìjọ òsì àti ìjọ aṣíwájú. Àmọ́ nínú sūrah al-Balad; 90:18-19 àti sūrah az-Zalzalah; 99:6-8, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) pín wọn sí ìjọ méjì. Ìjọ méjì kúkú ni gbogbo ẹ̀dá ní ọ̀run, ìjọ ọ̀tún àti ìjọ òsì nítorí pé, Ọgbà Ìdẹ̀ra wà fún ìjọ ọ̀tún, Ọgbà Iná sì wá fún ìjọ òsì. Àmọ́, Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ṣe àtúnpín ìjọ ọ̀tún sí ìjọ ọ̀tún àti ìjọ aṣíwájú nítorí pé, ìgbádùn ìkíní kejì yàtọ̀ gan-an síra wọn. Ìdí nìyí tí Allāhu fi sọ nípa ìgbádùn ìjọ aṣíwájú láti āyah 10 sí āyah 26. Ó sọ nípa ìgbádùn ìjọ ọ̀tún láti āyah 27 sí āyah 40. Ó sì sọ nípa oníran-ànran ìyà ìjọ òsì láti āyah 41 sí āyah 56.
آية رقم 8
ﮟﮠﮡﮢﮣ
ﮤ
Àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún?
آية رقم 9
ﮥﮦﮧﮨﮩ
ﮪ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
آية رقم 10
ﮫﮬ
ﮭ
Àwọn aṣíwájú sì ni àwọn aṣíwájú.
آية رقم 11
ﮮﮯ
ﮰ
Àwọn wọ̀nyẹn ni alásùn-únmọ́ (Allāhu)
آية رقم 12
ﮱﯓﯔ
ﯕ
nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
آية رقم 13
ﯖﯗﯘ
ﯙ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
آية رقم 14
ﯚﯛﯜ
ﯝ
Wọ́n sì kéré nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
آية رقم 15
ﯞﯟﯠ
ﯡ
(Wọn yóò wà) lórí ìtẹ́ tí wọ́n fi góòlù hun.
آية رقم 16
ﯢﯣﯤ
ﯥ
Wọn yóò rọ̀gbọ̀kú sórí rẹ̀, wọn sì máa dojú kọra wọn.
آية رقم 17
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tí kò níí darúgbó yó sì máa lọ bọ̀ láààrin wọn
آية رقم 18
ﭖﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
pẹ̀lú àwọn ife omi, ohun ìrọmi fẹ̀ǹfẹ̀ àti ife ọtí aládùn.
آية رقم 19
ﭜﭝﭞﭟﭠ
ﭡ
Kò níí fọ́ wọn lórí; kò sì níí mú wọn húnrìrà.
آية رقم 20
ﭢﭣﭤ
ﭥ
Èso tí wọn yóò máa ṣẹ̀ṣà nínú rẹ̀ (tún wà fún wọn).
آية رقم 21
ﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
Àti ẹran ẹyẹ, èyí tí wọ́n ń fẹ́ (yó wà fún wọn).
آية رقم 22
ﭫﭬ
ﭭ
Àwọn obìnrin ẹlẹ́yinjú ẹgẹ́ (tún wà fún wọn).
آية رقم 23
ﭮﭯﭰ
ﭱ
Wọ́n dà bí òkúta olówó-iyebíye tí wọ́n fi pamọ́.
آية رقم 24
ﭲﭳﭴﭵ
ﭶ
(Ìwọ̀nyí ni) ẹ̀san fún ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́.
آية رقم 25
ﭷﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra.
آية رقم 26
ﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Àyàfi ọ̀rọ̀ àlàáfíà, àlàáfíà.
آية رقم 27
ﮃﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
Àwọn èrò ọwọ́ ọtún, kí ni (ó máa ti dára tó fún) àwọn èrò ọwọ́ ọtún?
آية رقم 28
ﮉﮊﮋ
ﮌ
(Wọn yóò wà) ní ìdí igi tí kò ní ẹ̀gún,
آية رقم 29
ﮍﮎ
ﮏ
àti ọ̀gẹ̀dẹ̀ t’ó so jìgbìnnì,
آية رقم 30
ﮐﮑ
ﮒ
àti ibòji t’ó gbòòrò,
آية رقم 31
ﮓﮔ
ﮕ
àti omi t’ó ń ṣàn láì dáwọ́ dúró,
آية رقم 32
ﮖﮗ
ﮘ
àti ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ èso,
آية رقم 33
ﮙﮚﮛﮜ
ﮝ
tí kò níí já (ní ọ̀dọ̀ wọn), kò sì níí dèèwọ̀ (fún wọn).
آية رقم 34
ﮞﮟ
ﮠ
(Wọ́n máa wà lórí) ìtẹ́ tí wọ́n gbé sókè.
آية رقم 35
ﮡﮢﮣ
ﮤ
Dájúdájú Àwa tún (àwọn obìnrin wọn) dá ní ẹ̀dá ọ̀tun.
آية رقم 36
ﮥﮦ
ﮧ
A sì ṣe wọ́n ní wúńdíá,
آية رقم 37
ﮨﮩ
ﮪ
olólùfẹ́ ọkọ. Wọ́n sì dọ́gba ní ọjọ́ orí.
آية رقم 38
ﮫﮬ
ﮭ
(Wọ́n wà) fún àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
آية رقم 39
ﮮﮯﮰ
ﮱ
Wọ́n pọ̀ nínú àwọn ẹni àkọ́kọ́.
آية رقم 40
ﯓﯔﯕ
ﯖ
Wọ́n tún pọ̀ nínú àwọn ẹni Ìkẹ́yìn.
____________________
Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā (aleehim sọlātu wa salām). Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan (sollalāhu 'alayhi wa sallam).
____________________
Àwọn ẹni àkọ́kọ́ dúró fún àwọn ènìyàn láti àsìkò Ànábì Ādam títí di àsìkò Ànábì ‘Īsā (aleehim sọlātu wa salām). Àwọn ẹni Ìkẹ́yìn sì dúró fún ìjọ Ànábì wa nìkan (sollalāhu 'alayhi wa sallam).
آية رقم 41
ﯗﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Àwọn èrò ọwọ́ òsì, kí ni (ó máa ti burú tó fún) àwọn èrò ọwọ́ òsì?
آية رقم 42
ﯝﯞﯟ
ﯠ
(Wọn yóò wà) nínú atẹ́gùn gbígbóná àti omi gbígbóná,
آية رقم 43
ﯡﯢﯣ
ﯤ
àti ní abẹ́ ibòji eléèéfín dúdú,
آية رقم 44
ﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
kò tutù, kò sì dára.
آية رقم 45
ﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
Dájúdájú wọ́n ti jẹ́ onígbẹdẹmukẹ ṣíwájú ìyẹn.
آية رقم 46
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Wọ́n sì máa ń ṣoríkunkun lórí ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
آية رقم 47
Wọ́n sì máa ń wí pé: "Ṣé nígbà tí a bá di òkú, tí a sì di erùpẹ̀ àti egungun, ǹjẹ́ Wọn yóò tún gbé wa dìde ni?
آية رقم 48
ﰀﰁ
ﰂ
Ṣé àti àwọn bàbá wa, àwọn ẹni àkọ́kọ́?"
آية رقم 49
ﰃﰄﰅﰆ
ﰇ
Sọ pé: "Dájúdájú àwọn ẹni àkọ́kọ́ àti àwọn ẹni Ìkẹ́yìn,
آية رقم 50
ﰈﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
dájúdájú A óò kó wọn jọ papọ̀ ní àkókò ọjọ́ kan tí A ti mọ̀."
آية رقم 51
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú ẹ̀yin olùṣìnà, olùpe-òdodo-nírọ́,
آية رقم 52
ﭗﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
dájúdájú ẹ̀yin máa jẹ nínú igi zaƙƙūm (igi iwọ).
آية رقم 53
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Ikùn yín sì máa kún bámúbámú fún (jíjẹ) igi náà.
آية رقم 54
ﭡﭢﭣﭤ
ﭥ
Ẹ̀yin yó sì máa mu omi gbígbóná lé e lórí.
آية رقم 55
ﭦﭧﭨ
ﭩ
Ẹ̀yin yóò máa mu ún ní ìmumi ràkúnmí tí òǹgbẹ ń gbẹ.
آية رقم 56
ﭪﭫﭬﭭ
ﭮ
Èyí ni n̄ǹkan àlejò wọn ní Ọjọ́ ẹ̀san.
آية رقم 57
ﭯﭰﭱﭲ
ﭳ
Àwa l’A ṣẹ̀dá yín. Kí ni kò jẹ́ kí ẹ gbàgbọ́ lódodo!
آية رقم 58
ﭴﭵﭶ
ﭷ
Ẹ sọ fún Mi nípa àtọ̀ tí ẹ̀ ń dà jáde (sínú àpòlùkẹ́),
آية رقم 59
ﭸﭹﭺﭻﭼ
ﭽ
ṣé ẹ̀yin lẹ ṣẹ̀dá rẹ̀ ni tàbí Àwa l’A ṣẹ̀dá rẹ̀?
آية رقم 60
Àwa l’A yan kádàrá (ọjọ́) ikú fún gbogbo yín. Àwa kò sì lè kágara
آية رقم 61
láti fi irú yín pààrọ̀ yín, kí á sì tun yín dá sínú ohun tí ẹ kò mọ̀.
آية رقم 62
ﮐﮑﮒﮓﮔﮕ
ﮖ
Ẹ kúkú mọ ìṣẹ̀dá àkọ́kọ́, ẹ ò ṣe lo ìrántí?
آية رقم 63
ﮗﮘﮙ
ﮚ
Ẹ sọ fún Mi nípa n̄ǹkan tí ẹ̀ ń gbìn sínú ilẹ̀,
آية رقم 64
ﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń jẹ́ kí ó hù jáde ni tàbí Àwa l’À ń jẹ́ kí ó hù jáde?
آية رقم 65
ﮡﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá sọ ọ́ di gbígbẹ, ẹ̀yin yó sì máa ṣèèmọ̀ (tí ẹ óò máa ká àbámọ̀).
آية رقم 66
ﮨﮩ
ﮪ
(Ẹ̀yin yó sì wí pé:) "Dájúdájú àwa ti di onígbèsè."
آية رقم 67
ﮫﮬﮭ
ﮮ
(Àwọn mìíràn yó sì wí pé:) "Rárá o! Wọ́n ṣe ìkórè oko ní èèwọ̀ fún wa ni."
آية رقم 68
ﮯﮰﮱﯓ
ﯔ
Ẹ sọ fún mi nípa omi tí ẹ̀ ń mu,
آية رقم 69
ṣé ẹ̀yin l’ẹ̀ ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti inú ẹ̀ṣújò ni tàbí Àwa l’À ń sọ̀ ọ́ kalẹ̀?
آية رقم 70
ﯝﯞﯟﯠﯡﯢ
ﯣ
Tí A bá fẹ́ ni, Àwa ìbá ṣe é ní omi t’ó móró. Ẹ ò ṣe máa dúpẹ́?
آية رقم 71
ﯤﯥﯦﯧ
ﯨ
Ẹ sọ fún Mi nípa iná tí ẹ̀ ń dá,
آية رقم 72
ﯩﯪﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
ṣé ẹ̀yin l’ẹ ṣẹ̀dá igi rẹ̀ ni tàbí Àwa ni Aṣẹ̀dá?
آية رقم 73
ﯰﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Àwa ṣe iná ayé ní ìrántí (fún Iná ọ̀run) àti n̄ǹkan èlò fún àwọn onírìn-àjò.
آية رقم 74
ﯶﯷﯸﯹ
ﯺ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
آية رقم 75
ﯻﯼﯽﯾﯿ
ﰀ
Mò ń búra pẹ̀lú àwọn ibùsọ̀ ìràwọ̀.
آية رقم 76
ﰁﰂﰃﰄﰅ
ﰆ
Dájúdájú ìbúra ńlá ni, tí ẹ bá mọ̀.
آية رقم 77
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Dájúdájú (al-Ƙur’ān) ni n̄ǹkan kíké alápọ̀n-ọ́nlé,
آية رقم 78
ﭕﭖﭗ
ﭘ
(t’ó wà) nínú Tírà ààbò (nínú Laohul-Mahfūṭḥ).
آية رقم 79
ﭙﭚﭛﭜ
ﭝ
Kò sí ẹni tó lè fọwọ́ kàn án (ní ọ̀dọ̀ Allāhu) àfi àwọn ẹni mímọ́ (ìyẹn, àwọn mọlāika).
آية رقم 80
ﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Wọ́n sọ̀ al-Ƙur’ān kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 81
ﭣﭤﭥﭦ
ﭧ
Nítorí náà, ṣé ọ̀rọ̀ (al-Ƙur’ān) yìí l’ẹ̀ ń pè nírọ́?
آية رقم 82
ﭨﭩﭪﭫ
ﭬ
Ẹ sì ń sọ ìdúpẹ́ arísìkí yín di pé dájúdájú ẹ̀ ń pe òdodo nírọ́.
____________________
Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Irọ́ ni èyí àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu (subhānahu wa ta'ālā), Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, àwọn ọ̀ṣẹbọ ń dúpẹ́ fún ìràwọ̀ nítorí pé, wọ́n gbàgbọ́ pé òhun l’ó ń rọ̀jò lẹ́yìn Allāhu (subhānahu wa ta'ālā). Irọ́ ni èyí àti àìgbàgbọ́ nínú Allāhu (subhānahu wa ta'ālā), Ẹni t’Ó ń rọ̀jò fún ẹ̀dá Rẹ̀.
آية رقم 83
ﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
Kí ni ó máa ti rí (fun yín) nígbà tí ẹ̀mí (yín) bá dé ọ̀nà ọ̀fun,
آية رقم 84
ﭲﭳﭴ
ﭵ
tí ẹ̀yin yó sì máa wòran nígbà yẹn?
آية رقم 85
Àwa sì súnmọ́ ọn ju ẹ̀yin lọ, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò ríran.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mujādilah; 58:7.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Mujādilah; 58:7.
آية رقم 86
ﭾﭿﮀﮁﮂ
ﮃ
Ẹ̀yin kò ṣe jẹ́ ẹni tí A ò níí gbẹ̀san lára rẹ̀,
آية رقم 87
ﮄﮅﮆﮇ
ﮈ
kí ẹ sì dá (ẹ̀mí tí ó fẹ́ bọ́) padà, tí ẹ bá jẹ́ olódodo.
آية رقم 88
ﮉﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (Wa),
آية رقم 89
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
ìsinmi, èsè t’ó dára àti Ọgbà Ìdẹ̀ra (ni tirẹ̀).
آية رقم 90
ﮔﮕﮖﮗﮘﮙ
ﮚ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún,
آية رقم 91
ﮛﮜﮝﮞﮟ
ﮠ
àlàáfíà ni fún ọ láààrin àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
آية رقم 92
ﮡﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Ní ti ẹni tí ó bá wà nínú àwọn olùpe-òdodo-nírọ́, àwọn olùṣìnà,
آية رقم 93
ﮨﮩﮪ
ﮫ
n̄ǹkan àlejò (wọn) ni omi gbígbóná
آية رقم 94
ﮬﮭ
ﮮ
àti wíwọ inú iná Jẹhīm.
آية رقم 95
ﮯﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Dájúdájú èyí, òhun ni òdodo t’ó dájú.
آية رقم 96
ﯖﯗﯘﯙ
ﯚ
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa rẹ, Atóbi.
تقدم القراءة