ترجمة معاني سورة الإنفطار باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Nígbà tí sánmọ̀ bá fà ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
آية رقم 2
àti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,
آية رقم 3
àti nígbà tí àwọn ibúdò bá ṣàn jára wọn,
آية رقم 4
àti (nígbà tí A bá ta ilẹ̀ sókè), tí A sì mú àwọn òkú jáde (láàyè) láti inú àwọn sàréè,
آية رقم 5
(nígbà náà ni) ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan yóò mọ ohun tí ó tì síwájú (nínú iṣẹ́ rẹ̀) àti ohun tí ó fi sẹ́yìn (nínú orípa iṣẹ́ rẹ̀).
آية رقم 6
Ìwọ ènìyàn, kí ni ó tàn ọ́ jẹ nípa Olúwa rẹ, Alápọ̀n-ọ́nlé,
آية رقم 7
Ẹni t’Ó ṣẹ̀dá rẹ? Ó ṣẹ̀dá rẹ̀ ní pípé. Ó sì mú ọ dọ́gba jalẹ̀ léèyàn.
آية رقم 8
Ó to ẹ̀yà ara rẹ papọ̀ sínú èyíkéyìí àwòrán tí Ó fẹ́.
آية رقم 9
Ní ti òdodo, ńṣe l’ẹ̀ ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́.
آية رقم 10
Dájúdájú àwọn ẹ̀ṣọ́ sì wà ní ọ̀dọ̀ yín.
آية رقم 11
(Wọ́n jẹ́) alápọ̀n-ọ́nlé, òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá.
آية رقم 12
Wọ́n mọ ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́.
آية رقم 13
Dájúdájú àwọn ẹni rere yóò kúkú wà nínú ìgbádùn.
آية رقم 14
Dájúdájú àwọn ẹni ibi yó sì kúkú wà nínú iná Jẹhīm.
آية رقم 15
Wọn yóò wọ inú rẹ̀ ní Ọjọ́ ẹ̀san.
آية رقم 17
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
آية رقم 18
Lẹ́yìn náà, kí ni ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Ọjọ́ ẹ̀san?
(Ọjọ́ ẹ̀san ni) ọjọ́ tí ẹ̀mí kan kò níí kápá kiní kan fún ẹ̀mí kan. Gbogbo àṣẹ ọjọ́ yẹn sì ń jẹ́ ti Allāhu.
تقدم القراءة