ترجمة معاني سورة النازعات باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﮢﮣ
ﮤ
Allāhu búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà èle gba ẹ̀mí àwọn aláìgbàgbọ́.
آية رقم 2
ﮥﮦ
ﮧ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń fi ọ̀nà ẹ̀rọ̀ gba ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo.
آية رقم 3
ﮨﮩ
ﮪ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń yára gágá níbi àṣẹ Rẹ̀.
آية رقم 4
ﮫﮬ
ﮭ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó máa ṣíwájú ẹ̀mí àwọn onígbàgbọ́ òdodo wọnú Ọgbà Ìdẹ̀ra tààrà.
آية رقم 5
ﮮﮯ
ﮰ
Ó tún búra pẹ̀lú àwọn mọlāika t’ó ń ṣètò ilé ayé.
آية رقم 6
ﮱﯓﯔ
ﯕ
Ní ọjọ́ tí ìfọn àkọ́kọ́ fún òpin ayé máa mi gbogbo ayé tìtì pẹ̀lú ohùn igbe.
آية رقم 7
ﯖﯗ
ﯘ
Ìfọn kejì fún Àjíǹde sì máa tèlé e.
آية رقم 8
ﯙﯚﯛ
ﯜ
Àwọn ọkàn yóò máa gbọ̀n pẹ̀pẹ̀ ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 9
ﯝﯞ
ﯟ
Ojú wọn yó sì wálẹ̀ ní ti ìyẹpẹrẹ.
آية رقم 10
ﯠﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Wọn yóò wí pé: "Ṣé Wọ́n tún máa dá wa padà sí ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀mí (bíi tayé ni)?
آية رقم 11
ﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
Ṣé nígbà tí a ti di eegun t’ó kẹfun tán?"
آية رقم 12
ﯫﯬﯭﯮﯯ
ﯰ
Wọ́n wí pé: "Ìdápadà òfò nìyẹn nígbà náà (fún ẹni t’ó pè é nírọ́.)"
آية رقم 13
ﯱﯲﯳﯴ
ﯵ
Nítorí náà, igbe ẹyọ kan sì ni.
آية رقم 14
ﯶﯷﯸ
ﯹ
Nígbà náà ni wọn yóò bára wọn lórí ilẹ̀ gban̄sasa.
آية رقم 15
ﯺﯻﯼﯽ
ﯾ
Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ (Ànábì) Mūsā ti dé ọ̀dọ̀ rẹ?
آية رقم 16
ﯿﰀﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ̀ pè é ní àfonífojì mímọ́, Tuwā.
آية رقم 17
ﭑﭒﭓﭔﭕ
ﭖ
Lọ bá Fir‘aon, dájúdájú ó ti tayọ ẹnu-àlà.
آية رقم 18
ﭗﭘﭙﭚﭛﭜ
ﭝ
Kí o sì sọ pé: "Ǹjẹ o máa ṣàfọ̀mọ́ ara rẹ (kúrò nínú àìgbàgbọ́) bí?
آية رقم 19
ﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Kí èmi sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́ dé ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ. Nítorí náà, kí o páyà (Rẹ̀)."
آية رقم 20
ﭣﭤﭥ
ﭦ
Ó sì fi àmì t’ó tóbi hàn án.
آية رقم 21
ﭧﭨ
ﭩ
(Àmọ́) ó pè é lópùrọ́. Ó sì yapa rẹ̀.
آية رقم 22
ﭪﭫﭬ
ﭭ
Lẹ́yìn náà, ó kẹ̀yìn sí i. Ó sì ń ṣiṣẹ́ (takò ó).
آية رقم 23
ﭮﭯ
ﭰ
Ó kó (àwọn ènìyàn) jọ, ó sì ké gbàjarì.
آية رقم 24
ﭱﭲﭳﭴ
ﭵ
Ó sì wí pé: "Èmi ni olúwa yín, ẹni gíga jùlọ."
آية رقم 25
ﭶﭷﭸﭹﭺ
ﭻ
Nítorí náà, Allāhu gbá a mú pẹ̀lú ìyà ìkẹ́yìn àti àkọ́kọ́ (nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ ìkẹ́yìn yìí àti àkọ́kọ́).
____________________
Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: "Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!" Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
____________________
Ọ̀rọ̀ àkọ́kọ́ náà nìyí, Fir‘aon wí pé: "Ẹ̀yin ìjòyè, èmi kò mọ̀ pé ọlọ́hun kan tún wà lẹ́yìn mi!" Sūrah al-Ƙọsọs; 28:38
آية رقم 26
ﭼﭽﭾﭿﮀﮁ
ﮂ
Dájúdájú àríwòye wà nínú ìyẹn fún ẹni t’ó ń páyà (Allāhu).
آية رقم 27
Ṣé ẹ̀yin lẹ lágbára jùlọ ní ìṣẹ̀dá ni tàbí sánmọ̀ tí Allāhu mọ?
آية رقم 28
ﮋﮌﮍ
ﮎ
Allāhu gbé àjà rẹ̀ ga sókè. Ó sì ṣe é ní pípé t’ó gún régé.
آية رقم 29
ﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Ó ṣe òru rẹ̀ ní dúdú. Ó sì fa ìyálẹ̀ta rẹ̀ yọ jáde.
آية رقم 30
ﮔﮕﮖﮗ
ﮘ
Àti ilẹ̀, Ó tẹ́ ẹ pẹrẹsẹ lẹ́yìn ìyẹn.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
____________________
Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ fún sūrah al-Baƙọrah; 2:29.
آية رقم 31
ﮙﮚﮛﮜ
ﮝ
Ó mú omi rẹ̀ àti irúgbìn rẹ̀ jáde láti inú rẹ̀.
آية رقم 32
ﮞﮟ
ﮠ
Àti àwọn àpáta, Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ ṣinṣin.
آية رقم 33
ﮡﮢﮣ
ﮤ
Ìgbádùn ni fun yín àti fún àwọn ẹran-ọ̀sìn yín.
آية رقم 34
ﮥﮦﮧﮨ
ﮩ
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìparun ńlá bá dé,
آية رقم 35
ﮪﮫﮬﮭﮮ
ﮯ
ní ọjọ́ tí ènìyàn yóò rántí ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
آية رقم 36
ﮰﮱﯓﯔ
ﯕ
Wọ́n sì máa fi Iná hàn kedere fún (gbogbo) ẹni t’ó ríran.
آية رقم 37
ﯖﯗﯘ
ﯙ
Nítorí náà, ní ti ẹni t’ó bá tayọ ẹnu-àlà,
آية رقم 38
ﯚﯛﯜ
ﯝ
tí ó tún gbé àjùlọ fún ìṣẹ̀mí ayé,
آية رقم 39
ﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
dájúdájú iná Jẹhīm, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
آية رقم 40
Ní ti ẹni tí ó bá páyà ìdúró níwájú Olúwa rẹ̀, tí ó tún kọ ìfẹ́-inú fún ẹ̀mí (ara rẹ̀),
آية رقم 41
ﯭﯮﯯﯰ
ﯱ
dájúdájú Ọgbà Ìdẹ̀ra, òhun ni ibùgbé (rẹ̀).
آية رقم 42
ﯲﯳﯴﯵﯶ
ﯷ
Wọ́n ń bi ọ́ léèrè nípa Àkókò náà pé: "Ìgbà wo l’ó máa ṣẹlẹ̀?"
آية رقم 43
ﯸﯹﯺﯻ
ﯼ
Ọ̀nà wo ni ìwọ lè fi ní (ìmọ̀) ìrántí rẹ̀ ná?
آية رقم 44
ﯽﯾﯿ
ﰀ
Ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ ni òpin ìmọ̀ nípa rẹ̀ wà.
آية رقم 45
ﰁﰂﰃﰄﰅ
ﰆ
Ìwọ kúkú ni olùkìlọ̀ fún ẹni t’ó ń páyà rẹ̀.
آية رقم 46
Ní ọjọ́ tí wọ́n máa rí i, wọn máa dà bí ẹni pé wọn kò lò tayọ ìrọ̀lẹ́ tàbí ìyálẹ̀ta (ọjọ́) kan lọ (nílé ayé).
تقدم القراءة