ترجمة معاني سورة النبأ باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﭑﭒ
ﭓ
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
آية رقم 2
ﭔﭕﭖ
ﭗ
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
آية رقم 3
ﭘﭙﭚﭛ
ﭜ
èyí tí wọ́n ń yapa ẹnu sí.
آية رقم 4
ﭝﭞ
ﭟ
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
آية رقم 5
ﭠﭡﭢ
ﭣ
Lẹ́yìn náà, ní ti òdodo wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
آية رقم 6
ﭤﭥﭦﭧ
ﭨ
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
آية رقم 7
ﭩﭪ
ﭫ
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
آية رقم 8
ﭬﭭ
ﭮ
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
آية رقم 9
ﭯﭰﭱ
ﭲ
A ṣe oorun yín ní ìsinmi.
آية رقم 10
ﭳﭴﭵ
ﭶ
A tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
آية رقم 11
ﭷﭸﭹ
ﭺ
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
آية رقم 12
ﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
A tún mọ sánmọ̀ méje t’ó lágbára sókè yín.
آية رقم 13
ﮀﮁﮂ
ﮃ
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ t’ó ń tàn gbòlà.
آية رقم 14
ﮄﮅﮆﮇﮈ
ﮉ
Àti pé A sọ omi t’ó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
آية رقم 15
ﮊﮋﮌﮍ
ﮎ
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
آية رقم 16
ﮏﮐ
ﮑ
pẹ̀lú àwọn ọgbà t’ó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
آية رقم 17
ﮒﮓﮔﮕﮖ
ﮗ
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
آية رقم 18
ﮘﮙﮚﮛﮜﮝ
ﮞ
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
آية رقم 19
ﮟﮠﮡﮢ
ﮣ
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
آية رقم 20
ﮤﮥﮦﮧ
ﮨ
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
آية رقم 21
ﮩﮪﮫﮬ
ﮭ
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
آية رقم 22
ﮮﮯ
ﮰ
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
آية رقم 23
ﮱﯓﯔ
ﯕ
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
آية رقم 24
ﯖﯗﯘﯙﯚﯛ
ﯜ
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
آية رقم 25
ﯝﯞﯟ
ﯠ
àyàfi omi gbígbóná àti àwọyúnwẹ̀jẹ̀.
آية رقم 26
ﯡﯢ
ﯣ
(Ó jẹ́) ẹ̀san t’ó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
آية رقم 27
ﯤﯥﯦﯧﯨ
ﯩ
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
آية رقم 28
ﯪﯫﯬ
ﯭ
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa nírọ́ gan-an.
آية رقم 29
ﯮﯯﯰﯱ
ﯲ
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
آية رقم 30
ﯳﯴﯵﯶﯷ
ﯸ
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fun yín bí kò ṣe ìyà.
آية رقم 31
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
آية رقم 32
ﭕﭖ
ﭗ
Àwọn ọgbà àti èso àjàrà,
آية رقم 33
ﭘﭙ
ﭚ
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
آية رقم 34
ﭛﭜ
ﭝ
àti ife ọtí t’ó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
آية رقم 35
ﭞﭟﭠﭡﭢﭣ
ﭤ
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
آية رقم 36
ﭥﭦﭧﭨﭩ
ﭪ
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
آية رقم 37
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun t’ó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
آية رقم 38
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ t’ó ṣe wẹ́kú.
آية رقم 39
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
آية رقم 40
Dájúdájú A fi ìyà t’ó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fun yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: "Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà)."
تقدم القراءة