ترجمة معاني سورة النبأ باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Nípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
آية رقم 2
Nípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
آية رقم 4
Rárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
آية رقم 5
Lẹ́yìn náà, ní ti òdodo wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
آية رقم 6
Ǹjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
آية رقم 7
àti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
آية رقم 8
A sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
آية رقم 11
A tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
آية رقم 12
A tún mọ sánmọ̀ méje t’ó lágbára sókè yín.
آية رقم 13
A tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ t’ó ń tàn gbòlà.
آية رقم 14
Àti pé A sọ omi t’ó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
آية رقم 15
nítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
آية رقم 16
pẹ̀lú àwọn ọgbà t’ó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
آية رقم 17
Dájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
آية رقم 18
(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
آية رقم 19
Wọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
آية رقم 20
Wọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
آية رقم 21
Dájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
آية رقم 22
(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
آية رقم 23
Wọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
آية رقم 24
Wọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
آية رقم 25
àyàfi omi gbígbóná àti àwọyúnwẹ̀jẹ̀.
آية رقم 26
(Ó jẹ́) ẹ̀san t’ó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
آية رقم 27
Dájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
آية رقم 28
Wọ́n sì pe àwọn āyah Wa nírọ́ gan-an.
آية رقم 29
Gbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
آية رقم 30
Nítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fun yín bí kò ṣe ìyà.
آية رقم 31
Dájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
آية رقم 32
Àwọn ọgbà àti èso àjàrà,
آية رقم 33
àti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
آية رقم 34
àti ife ọtí t’ó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
آية رقم 35
Wọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
آية رقم 36
(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun t’ó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
Ọjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ t’ó ṣe wẹ́kú.
Ìyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
Dájúdájú A fi ìyà t’ó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fun yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: "Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà)."
تقدم القراءة