ترجمة معاني سورة الشمس باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﭜﭝ
ﭞ
(Allāhu) búra pẹ̀lú òòrùn àti ìyálẹ̀ta rẹ̀.
آية رقم 2
ﭟﭠﭡ
ﭢ
Ó tún búra pẹ̀lú òṣùpá nígbà tí ó bá (yọ) tẹ̀lé (òòrùn).
آية رقم 3
ﭣﭤﭥ
ﭦ
Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí ó bá mú ìmọ́lẹ̀ bá òkùnkùn òru.
آية رقم 4
ﭧﭨﭩ
ﭪ
Ó tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá bo ọ̀sán mọ́lẹ̀.
آية رقم 5
ﭫﭬﭭ
ﭮ
Ó tún búra pẹ̀lú sánmọ̀ àti Ẹni tí Ó mọ ọ́n ?
____________________
Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni Ẹni tí Ó mọ àwọn sánmọ̀. Ó sì ń fi ara Rẹ̀ búra.
____________________
Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni Ẹni tí Ó mọ àwọn sánmọ̀. Ó sì ń fi ara Rẹ̀ búra.
آية رقم 6
ﭯﭰﭱ
ﭲ
Ó tún búra pẹ̀lú ilẹ̀ àti Ẹni tí Ó tẹ́ ẹ kalẹ̀.
آية رقم 7
ﭳﭴﭵ
ﭶ
Ó tún búra pẹ̀lú ẹ̀mí (ènìyàn) àti Ẹni tí Ó ṣe (oríkèé rẹ̀) dọ́gba.
آية رقم 8
ﭷﭸﭹ
ﭺ
Ó sì fi ẹ̀ṣẹ̀ (tí ẹ̀mí lè dá) àti ìbẹ̀rù rẹ̀ mọ̀ ọ́n.
آية رقم 9
ﭻﭼﭽﭾ
ﭿ
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣàfọ̀mọ́ (ẹ̀mí ara) rẹ̀ (níbi ẹ̀ṣẹ̀), ó mà ti jèrè.
آية رقم 10
ﮀﮁﮂﮃ
ﮄ
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi (ìwà ẹ̀ṣẹ̀) ba ẹ̀mí (ara) rẹ̀ jẹ́, ó mà ti pàdánù.
آية رقم 11
ﮅﮆﮇ
ﮈ
Ìjọ Thamūd pe òdodo nírọ́ nípa ìtayọ ẹnu-àlà wọn.
آية رقم 12
ﮉﮊﮋ
ﮌ
(Rántí) nígbà tí ẹni tí orí rẹ̀ burú jùlọ nínú wọn sáré dìde (láti gún ràkúnmí pa).
آية رقم 13
Nígbà náà, Òjíṣẹ́ Allāhu sọ fún wọn pé: "(Ẹ fi) abo ràkúnmí Allāhu àti omi rẹ̀ (sílẹ̀)."
آية رقم 14
Wọ́n pè é nírọ́. Wọ́n sì gún (ràkúnmí) pa. Nítorí náà, Olúwa wọn pa wọ́n rẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ó sì fi ìparun náà kárí wọn.
آية رقم 15
ﮝﮞﮟ
ﮠ
(Ẹni t’ó gún ràkúnmí pa) kò sì páyà ìkángun ọ̀rọ̀ wọn.
تقدم القراءة