ترجمة معاني سورة المدّثر باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﮪﮫ
ﮬ
Ìwọ olùdaṣọbora.
آية رقم 2
ﮭﮮ
ﮯ
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
آية رقم 3
ﮰﮱ
ﯓ
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
آية رقم 4
ﯔﯕ
ﯖ
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
آية رقم 5
ﯗﯘ
ﯙ
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
آية رقم 6
ﯚﯛﯜ
ﯝ
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
آية رقم 7
ﯞﯟ
ﯠ
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
آية رقم 8
ﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
آية رقم 9
ﯦﯧﯨﯩ
ﯪ
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
آية رقم 10
ﯫﯬﯭﯮ
ﯯ
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
آية رقم 11
ﯰﯱﯲﯳ
ﯴ
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan.
آية رقم 12
ﯵﯶﯷﯸ
ﯹ
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
آية رقم 13
ﯺﯻ
ﯼ
àti àwọn ọmọkúnrin t’ó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
آية رقم 14
ﯽﯾﯿ
ﰀ
Mo sì ṣe ayé nírọ̀rùn fún un gan-an.
آية رقم 15
ﰁﰂﰃﰄ
ﰅ
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
آية رقم 16
ﰆﰇﰈﰉﰊﰋ
ﰌ
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
آية رقم 17
ﰍﰎ
ﰏ
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná).
____________________
Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
____________________
Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
آية رقم 18
ﰐﰑﰒ
ﰓ
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
آية رقم 19
ﭑﭒﭓ
ﭔ
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
آية رقم 20
ﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
آية رقم 21
ﭚﭛ
ﭜ
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
آية رقم 22
ﭝﭞﭟ
ﭠ
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
آية رقم 23
ﭡﭢﭣ
ﭤ
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìn dà, ó sì ṣègbéraga.
آية رقم 24
ﭥﭦﭧﭨﭩﭪ
ﭫ
Ó sì wí pé: "Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
آية رقم 25
ﭬﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
Kí ni èyí bí kò ṣe ọ̀rọ̀ abara"
آية رقم 26
ﭲﭳ
ﭴ
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
آية رقم 27
ﭵﭶﭷﭸ
ﭹ
Kí l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ iná Saƙọr?
آية رقم 28
ﭺﭻﭼﭽ
ﭾ
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.
____________________
Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
____________________
Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
آية رقم 29
ﭿﮀ
ﮁ
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
آية رقم 30
ﮂﮃﮄ
ﮅ
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: "Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?" Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ̀ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
آية رقم 32
ﯥﯦ
ﯧ
Ẹ gbọ́! Allāhu búra pẹ̀lú òṣùpá.
آية رقم 33
ﯨﯩﯪ
ﯫ
Ó tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.
آية رقم 34
ﯬﯭﯮ
ﯯ
Ó tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́.
آية رقم 35
ﯰﯱﯲ
ﯳ
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) t’ó tóbi.
آية رقم 36
ﯴﯵ
ﯶ
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
آية رقم 37
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn.
آية رقم 38
ﯿﰀﰁﰂﰃ
ﰄ
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
آية رقم 39
ﰅﰆﰇ
ﰈ
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
آية رقم 40
ﰉﰊﰋ
ﰌ
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
آية رقم 41
ﰍﰎ
ﰏ
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
آية رقم 42
ﰐﰑﰒﰓ
ﰔ
"Kí ni ó mu yín wọ inú iná Saƙọr?"
آية رقم 43
ﰕﰖﰗﰘﰙ
ﰚ
Wọn yóò wí pé: "Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
آية رقم 44
ﰛﰜﰝﰞ
ﰟ
Àwa kò sì sí nínú àwọn t’ó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
آية رقم 45
ﰠﰡﰢﰣ
ﰤ
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
آية رقم 46
ﰥﰦﰧﰨ
ﰩ
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́
آية رقم 47
ﰪﰫﰬ
ﰭ
títí ikú fi dé bá wa."
آية رقم 48
ﭑﭒﭓﭔ
ﭕ
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
آية رقم 49
ﭖﭗﭘﭙﭚ
ﭛ
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
آية رقم 50
ﭜﭝﭞ
ﭟ
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ t’ó ń sá lọ,
آية رقم 51
ﭠﭡﭢ
ﭣ
t’ó sá fún kìnìhún?
آية رقم 52
Rárá, ńṣe ni ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
آية رقم 53
ﭮﭯﭰﭱﭲﭳ
ﭴ
Rárá. Wọn kò páyà ọ̀run ni.
آية رقم 54
ﭵﭶﭷ
ﭸ
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
آية رقم 55
ﭹﭺﭻ
ﭼ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kó rántí rẹ̀.
آية رقم 56
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì làforíjìn.
تقدم القراءة