ترجمة معاني سورة المدّثر باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 2
Dìde kí o ṣèkìlọ̀.
آية رقم 3
Olúwa rẹ sì ni kí o gbé títóbi fún.
آية رقم 4
Aṣọ rẹ ni kí o fọ̀ mọ́.
آية رقم 5
Òrìṣà ni kí o jìnnà sí.
آية رقم 6
Má ṣe tọrẹ nítorí kí o lè rí púpọ̀ gbà.
آية رقم 7
Olúwa rẹ ni kí o ṣe sùúrù fún.
آية رقم 8
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún àjíǹde,
آية رقم 9
ìyẹn, ní ọjọ́ yẹn, ni ọjọ́ ìnira,
آية رقم 10
tí kò níí rọrùn fún àwọn aláìgbàgbọ́.
آية رقم 11
Fi Mí dá ẹni tí Mo dá ní òun nìkan.
آية رقم 12
Mo sì fún un ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ dúkìá
آية رقم 13
àti àwọn ọmọkúnrin t’ó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀.
آية رقم 14
Mo sì ṣe ayé nírọ̀rùn fún un gan-an.
آية رقم 15
Lẹ́yìn náà, ó tún ń jẹ̀rankàn pé kí N̄g ṣe àlékún.
آية رقم 16
Rárá o! Dájúdájú ó jẹ́ alátakò sí àwọn āyah Wa.
آية رقم 17
Èmi yóò la ìyà pọ́nkèpọ́nkè bọ̀ ọ́ lọ́rùn (nínú Iná).
____________________
Orúkọ àpáta ńlá kan nínú Iná ni Sọ‘ūd. Kèfèrí yóò máa pọ́n òkè náà láààrin àádọ́rin ọdún ní àpọ́njábọ́. Ìdí nìyí tí wọ́n fi pe ìyà náà ní ìyà pọ́nkèpọ́nkè.
آية رقم 18
Dájúdájú ó ronú (lódì nípa al-Ƙur’ān). Ó sì pinnu (ọ̀rọ̀ kan nínú ẹ̀mí rẹ̀).
آية رقم 19
Wọ́n sì ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
آية رقم 20
Lẹ́yìn náà, Wọ́n tún ṣẹ́bi lé e nípa bí ó ṣe pinnu.
آية رقم 21
Lẹ́yìn náà, ó wò sùn.
آية رقم 22
Lẹ́yìn náà, ó fajú ro, ó sì dijú mágbárí.
آية رقم 23
Lẹ́yìn náà, ó pẹ̀yìn dà, ó sì ṣègbéraga.
آية رقم 24
Ó sì wí pé: "Kí ni èyí bí kò ṣe idán àtọwọ́dọ́wọ́.
آية رقم 26
Èmi yóò fi sínú iná Saƙọr.
آية رقم 27
Kí l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ iná Saƙọr?
آية رقم 28
(Saƙọr) kò níí ṣẹ́ ẹ kù, kò sì níí pa á tì.
____________________
Ìyẹn ni pé, Iná náà yóò máa jó o lọ, kò sì níí gba ẹ̀mí rẹ̀.
آية رقم 29
Ó máa jó awọ ara di dúdú.
آية رقم 30
(Àwọn mọlāika) mọ́kàndínlógún ni ẹ̀ṣọ́ rẹ̀.
Àwa kò ṣe ẹnì kan ní ẹ̀ṣọ́ Iná àfi àwọn mọlāika. Àwa kò sì ṣe òǹkà wọn (bẹ́ẹ̀) bí kò ṣe (nítorí kí ó lè jẹ́) àdánwò fún àwọn t’ó ṣàì gbàgbọ́, àti nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà lè ní àmọ̀dájú àti nítorí kí àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ ní òdodo lè lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. (Ó rí bẹ́ẹ̀) nítorí kí àwọn tí A fún ní Tírà àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo má baà ṣeyèméjì àti nítorí kí àwọn tí àrùn wà nínú ọkàn wọn àti àwọn aláìgbàgbọ́ lè wí pé: "Kí ni Allāhu gbà lérò pẹ̀lú àpèjúwe yìí?" Báyẹn ni Allāhu ṣe ń ṣi ẹni tí Ó bá fẹ́ lọ́nà, Ó sì ń tọ́ ẹni tí Ó bá fẹ́ sọ́nà. Kò sì sí ẹni tí ó mọ àwọn ọmọ ogun Olúwa rẹ̀ àfi Òun náà. (Iná Saƙọr) kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe ìrántí fún abara.
آية رقم 32
Ẹ gbọ́! Allāhu búra pẹ̀lú òṣùpá.
آية رقم 33
Ó tún búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí ó bá lọ.
آية رقم 34
Ó tún búra pẹ̀lú òwúrọ̀ nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́.
آية رقم 35
Dájúdájú (iná Saƙọr) ni ọ̀kan nínú (àwọn àdánwò) t’ó tóbi.
آية رقم 36
(Ó jẹ́) ìkìlọ̀ fún abara.
آية رقم 37
Fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti tẹ̀ síwájú tàbí láti fà sẹ́yìn.
آية رقم 38
Ẹ̀mí kọ̀ọ̀kan ni onídùúró fún ohun t’ó ṣe níṣẹ́.
آية رقم 39
Àyàfi àwọn èrò ọwọ́ ọ̀tún.
آية رقم 40
Wọn yóò máa bira wọn léèrè ọ̀rọ̀ nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra
آية رقم 41
nípa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pé:
آية رقم 43
Wọn yóò wí pé: "Àwa kò sí nínú àwọn olùkírun ni.
آية رقم 44
Àwa kò sì sí nínú àwọn t’ó ń bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
آية رقم 45
Àwa sì máa ń sọ ìsọkúsọ pẹ̀lú àwọn onísọkúsọ.
آية رقم 46
Àti pé àwa máa ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́
آية رقم 48
Ìpẹ̀ àwọn olùṣìpẹ̀ kò sì níí ṣe wọ́n ní àǹfààní.
آية رقم 49
Kí ló mú wọn ná tí wọ́n ń gbúnrí kúrò níbi ìrántí
آية رقم 50
bí ẹni pé àwọn ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ t’ó ń sá lọ,
Rárá, ńṣe ni ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wọn ń fẹ́ kí Á fún òun náà ní Tírà tí ó máa ṣeé tẹ́ han àwọn ènìyàn (bíi ti al-Ƙur’ān).
آية رقم 54
Ẹ gbọ́! Dájúdájú al-Ƙur’ān ni ìrántí.
آية رقم 55
Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kó rántí rẹ̀.
Wọn kò sì níí rántí (al-Ƙur’ān) àfi tí Allāhu bá fẹ́. (Allāhu) Òun l’a gbọ́dọ̀ bẹ̀rù. Òun l’ó sì làforíjìn.
تقدم القراءة