ترجمة معاني سورة المطفّفين باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية
أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني
ﰡ
آية رقم 1
ﯖﯗ
ﯘ
Ègbé ni fún àwọn olùdín-òṣùwọ̀n-kù,
آية رقم 2
ﯙﯚﯛﯜﯝﯞ
ﯟ
àwọn (òǹtajà) t’ó jẹ́ pé nígbà tí wọ́n bá wọn n̄ǹkan lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn, wọ́n á gbà á ní ẹ̀kún,
____________________
“Àwọn ènìyàn” ní àyè yìí dúró fún bíi “ àwọn olóko”.
____________________
“Àwọn ènìyàn” ní àyè yìí dúró fún bíi “ àwọn olóko”.
آية رقم 3
ﯠﯡﯢﯣﯤ
ﯥ
nígbà tí àwọn (òǹtajà náà) bá sì lo ìwọ̀n fún àwọn (òǹrajà) tàbí lo òṣùwọ̀n fún wọn, wọn yóò dín in kù.
آية رقم 4
ﯦﯧﯨﯩﯪ
ﯫ
Ṣé àwọn wọ̀nyẹn kò mọ̀ dájú pé dájúdájú A máa gbé wọn dìde
آية رقم 5
ﭑﭒ
ﭓ
ní Ọjọ́ ńlá kan?
آية رقم 6
ﭔﭕﭖﭗﭘ
ﭙ
Ní ọjọ́ tí àwọn ènìyàn yóò dìde nàró fún Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 7
ﭚﭛﭜﭝﭞﭟ
ﭠ
Bẹ́ẹ̀ ni, dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni ibi kúkú wà nínú Sijjīn.
آية رقم 8
ﭡﭢﭣﭤ
ﭥ
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Sijjīn!
آية رقم 9
ﭦﭧ
ﭨ
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ aburú ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sínú ilẹ̀ keje ni Sijjīn).
آية رقم 10
ﭩﭪﭫ
ﭬ
Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo- nírọ́,
آية رقم 11
ﭭﭮﭯﭰ
ﭱ
àwọn t’ó ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́.
آية رقم 12
Kò sì sí ẹni t’ó ń pè é nírọ́ àfi gbogbo alákọyọ, ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 13
Nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa fún un, ó máa wí pé: "Àwọn àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́ (nìwọ̀nyí)."
آية رقم 14
Rárá kò rí bẹ́ẹ̀, àmọ́ ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́ ibi l’ó jọba lórí ọkàn wọn.
آية رقم 15
ﮍﮎﮏﮐﮑﮒ
ﮓ
Ní ti òdodo, dájúdájú wọn yóò wà nínú gàgá, wọn kò sì níí rí Olúwa wọn ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 16
ﮔﮕﮖﮗ
ﮘ
Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò wọ inú iná Jẹhīm.
آية رقم 17
Lẹ́yìn náà, wọ́n máa sọ (fún wọn) pe: "Èyí ni ohun tí ẹ̀ ń pè nírọ́."
آية رقم 18
ﮡﮢﮣﮤﮥﮦ
ﮧ
Bẹ́ẹ̀ ni. Dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni rere wà nínú ‘illiyyūn.
آية رقم 19
ﮨﮩﮪﮫ
ﮬ
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ ‘illiyyūn!
آية رقم 20
ﮭﮮ
ﮯ
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ rere ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sí òkè sánmọ̀ ni ‘illiyyūn).
آية رقم 21
ﮰﮱ
ﯓ
Àwọn (mọlāika) tí wọ́n súnmọ́ Allāhu ń jẹ́rìí sí i.
آية رقم 22
ﯔﯕﯖﯗ
ﯘ
Dájúdájú àwọn ẹni rere máa wà nínú ìgbádùn.
آية رقم 23
ﯙﯚﯛ
ﯜ
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
آية رقم 24
ﯝﯞﯟﯠﯡ
ﯢ
Ìwọ yóò dá ìtutù ojú ìgbádùn mọ̀ nínú ojú wọn.
آية رقم 25
ﯣﯤﯥﯦ
ﯧ
Wọn yóò máa fún wọn mu nínú ọtí onídèérí.
آية رقم 26
Àlùmísìkí ni (òórùn) ìparí rẹ̀. Kí àwọn alápàáǹtètè ṣàpáǹtètè nínú ìyẹn.
آية رقم 27
ﯰﯱﯲ
ﯳ
Tẹsnīm ni wọ́n yóò máa pòpọ̀ (mọ́ ọtí náà).
آية رقم 28
ﯴﯵﯶﯷ
ﯸ
(Tẹsnīm ni) omi ìṣẹ́lẹ̀rú kan, tí àwọn olùsúnmọ́ (Allāhu) yóò máa mu.
آية رقم 29
Dájúdájú àwọn t’ó dẹ́ṣẹ̀, wọ́n máa ń fi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo rẹ́rìn-ín.
آية رقم 30
ﰂﰃﰄﰅ
ﰆ
Nígbà tí wọ́n bá gba ẹ̀gbẹ́ wọn kọjá, (àwọn adẹ́ṣẹ̀) yóò máa ṣẹ́jú síra wọn ní ti yẹ̀yẹ́.
آية رقم 31
ﰇﰈﰉﰊﰋﰌ
ﰍ
Nígbà tí wọ́n bá sì padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wọn, wọ́n á padà tí wọn yóò máa ṣe fáàrí.
آية رقم 32
ﰎﰏﰐﰑﰒﰓ
ﰔ
Àti pé nígbà tí wọ́n bá rí (àwọn onígbàgbọ́ òdodo) wọ́n á wí pé: "Dájúdájú àwọn wọ̀nyí ni olùṣìnà."
آية رقم 33
ﰕﰖﰗﰘ
ﰙ
Àwa kò sì rán wọn níṣẹ́ olùṣọ́ sí wọn.
آية رقم 34
ﭑﭒﭓﭔﭕﭖ
ﭗ
Nítorí náà, ní òní àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo yóò fi àwọn aláìgbàgbọ́ rẹ́rìn-ín.
آية رقم 35
ﭘﭙﭚ
ﭛ
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
آية رقم 36
ﭜﭝﭞﭟﭠﭡ
ﭢ
Ṣebí wọ́n ti fi ohun tí àwọn aláìgbàgbọ́ ń ṣe níṣẹ́ san wọ́n lẹ́san (báyìí)?
تقدم القراءة