ترجمة معاني سورة المطفّفين باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

الترجمة اليورباوية

أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني

آية رقم 1
Ègbé ni fún àwọn olùdín-òṣùwọ̀n-kù,
آية رقم 2
àwọn (òǹtajà) t’ó jẹ́ pé nígbà tí wọ́n bá wọn n̄ǹkan lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn, wọ́n á gbà á ní ẹ̀kún,
____________________
“Àwọn ènìyàn” ní àyè yìí dúró fún bíi “ àwọn olóko”.
آية رقم 3
nígbà tí àwọn (òǹtajà náà) bá sì lo ìwọ̀n fún àwọn (òǹrajà) tàbí lo òṣùwọ̀n fún wọn, wọn yóò dín in kù.
آية رقم 4
Ṣé àwọn wọ̀nyẹn kò mọ̀ dájú pé dájúdájú A máa gbé wọn dìde
آية رقم 5
ní Ọjọ́ ńlá kan?
آية رقم 6
Ní ọjọ́ tí àwọn ènìyàn yóò dìde nàró fún Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
آية رقم 7
Bẹ́ẹ̀ ni, dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni ibi kúkú wà nínú Sijjīn.
آية رقم 8
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ Sijjīn!
آية رقم 9
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ aburú ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sínú ilẹ̀ keje ni Sijjīn).
آية رقم 10
Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo- nírọ́,
آية رقم 11
àwọn t’ó ń pe Ọjọ́ ẹ̀san nírọ́.
آية رقم 12
Kò sì sí ẹni t’ó ń pè é nírọ́ àfi gbogbo alákọyọ, ẹlẹ́ṣẹ̀.
آية رقم 13
Nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa fún un, ó máa wí pé: "Àwọn àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́ (nìwọ̀nyí)."
Rárá kò rí bẹ́ẹ̀, àmọ́ ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́ ibi l’ó jọba lórí ọkàn wọn.
آية رقم 15
Ní ti òdodo, dájúdájú wọn yóò wà nínú gàgá, wọn kò sì níí rí Olúwa wọn ní ọjọ́ yẹn.
آية رقم 16
Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò wọ inú iná Jẹhīm.
آية رقم 17
Lẹ́yìn náà, wọ́n máa sọ (fún wọn) pe: "Èyí ni ohun tí ẹ̀ ń pè nírọ́."
آية رقم 18
Bẹ́ẹ̀ ni. Dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni rere wà nínú ‘illiyyūn.
آية رقم 19
Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun t’ó ń jẹ́ ‘illiyyūn!
آية رقم 20
Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ rere ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sí òkè sánmọ̀ ni ‘illiyyūn).
آية رقم 21
Àwọn (mọlāika) tí wọ́n súnmọ́ Allāhu ń jẹ́rìí sí i.
آية رقم 22
Dájúdájú àwọn ẹni rere máa wà nínú ìgbádùn.
آية رقم 23
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
آية رقم 24
Ìwọ yóò dá ìtutù ojú ìgbádùn mọ̀ nínú ojú wọn.
آية رقم 25
Wọn yóò máa fún wọn mu nínú ọtí onídèérí.
آية رقم 26
Àlùmísìkí ni (òórùn) ìparí rẹ̀. Kí àwọn alápàáǹtètè ṣàpáǹtètè nínú ìyẹn.
آية رقم 27
Tẹsnīm ni wọ́n yóò máa pòpọ̀ (mọ́ ọtí náà).
آية رقم 28
(Tẹsnīm ni) omi ìṣẹ́lẹ̀rú kan, tí àwọn olùsúnmọ́ (Allāhu) yóò máa mu.
آية رقم 29
Dájúdájú àwọn t’ó dẹ́ṣẹ̀, wọ́n máa ń fi àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo rẹ́rìn-ín.
آية رقم 30
Nígbà tí wọ́n bá gba ẹ̀gbẹ́ wọn kọjá, (àwọn adẹ́ṣẹ̀) yóò máa ṣẹ́jú síra wọn ní ti yẹ̀yẹ́.
آية رقم 31
Nígbà tí wọ́n bá sì padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wọn, wọ́n á padà tí wọn yóò máa ṣe fáàrí.
آية رقم 32
Àti pé nígbà tí wọ́n bá rí (àwọn onígbàgbọ́ òdodo) wọ́n á wí pé: "Dájúdájú àwọn wọ̀nyí ni olùṣìnà."
آية رقم 33
Àwa kò sì rán wọn níṣẹ́ olùṣọ́ sí wọn.
آية رقم 34
Nítorí náà, ní òní àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo yóò fi àwọn aláìgbàgbọ́ rẹ́rìn-ín.
آية رقم 35
Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
آية رقم 36
Ṣebí wọ́n ti fi ohun tí àwọn aláìgbàgbọ́ ń ṣe níṣẹ́ san wọ́n lẹ́san (báyìí)?
تقدم القراءة